< Jeremian 30 >

1 Tämä on se sana, joka tapahtui Herralta Jeremialle, sanoen:
Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
2 Näin sanoo Herra Israelin Jumala, sanoen: kirjoita itselles kirjaan kaikki ne sanat, jotka minä puhun sinulle.
“Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
3 Sillä katso, se aika tulee, sanoo Herra, että minä tahdon kääntää kansani vankiuden, sekä Israelin että Juudan, sanoo Herra, ja annan heidän tulla jälleen siihen maahan, jonka minä heidän isillensä antanut olen, että he sen omistaman pitää.
Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
4 Ja nämät ovat ne sanat, jotka Herra puhui Israelista ja Juudasta.
Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
5 Sillä näin sanoo Herra: me kuulemme pelvon äänen, siellä on sula pelko ja ei yhtään rauhaa.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
6 Kysykäät nyt ja katsokaat, taitaako miehenpuoli synnyttää? Kuinkasta siis minä näen kaikkein miesten kädet lanteissansa niinkuin lapsensynnyttäjän, ja että kaikki kasvot ovat niin valjut?
Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
7 Voi! se on suuri päivä, ja ei ole senkaltaista ollut; ja murheen aika on Jakobissa, kuitenkin pitää heitä siitä autettaman.
Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
8 Mutta sen pitää tapahtuman siihen aikaan, sanoo Herra Zebaot, että minä taitan hänen ikeensä rikki kaulastas, ja repäisen sinun sitees, niin ettei heidän enään siellä pidä muukalaisia palveleman;
“‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
9 Vaan heidän pitää palveleman Herraa Jumalaansa ja Davidia kuningastansa, jonka minä heille herättänyt olen.
Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
10 Sentähden älä pelkää palveliani Jakob, sanoo Herra, ja Israel älä hämmästy! sillä katso, minä tahdon auttaa sinua kaukaa, ja sinun siementäs vankiutensa maasta, niin että Jakobin pitää tuleman jällensä, elämän rauhassa ja oleman hyvässä levossa, ja ei kenenkään pidä häntä peljättämän.
“‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
11 Sillä minä olen sinun tykönäs, sanoo Herra, auttamassa sinua; ja teloitan kaikki pakanat, joihin minä olen sinut hajoittanut; mutta en minä sinua lopeta, vaan tahdon sinua kurittaa kohtuudella, ja en tahdo sinua peräti viattomana pitää.
Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
12 Sillä näin sanoo Herra: sinun haavas on kuoleman haava, ja sinun kipus juuri paha.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
13 Ei toimita kenkään sinun asias sortajaa vastaan; ei kenkään taida sinua parantaa.
Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
14 Kaikki sinun rakastajas unhottavat sinun, ja ei kysy sinua; sillä minä olen lyönyt sinua, niinkuin vihollista armottomalla kurituksella, suurten pahaintekois tähden ja raskasten synteis tähden.
Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
15 Mitäs huudat haavais tähden ja suuresta kivustas? Minä olen tämän tehnyt sinulle suurten pahaintekois ja raskasten synteis tähden.
Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
16 Sentähden kaikki, jotka sinua ovat syöneet, heitä pitää taas syötämän, ja kaikki sinun vihollises pitää vangiksi tuleman; jotka sinua ovat ryöstäneet, pitää jälleen ryöstettämän, ja kaikki ne, jotka sinun ovat ryövänneet, tahdon minä saaliiksi antaa.
“‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
17 Mutta sinun minä jälleen parannan, ja teen terveeksi haavas, sanoo Herra, sillä he ovat sinun kutsuneet ulosajetuksi ja Zionin siksi, jota ei kenkään kysy.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
18 Näin sanoo Herra: katso, minä käännän Jakobin majan vankiuden, ja armahdan hänen asumistansa; ja kaupunki pitää jälleen mäelle rakennettaman, ja kirkon pitää oleman entisellä muodollansa.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
19 Ja kiitoksen ja riemun äänen pitää siitä kuuluman; sillä minä tahdon heitä enentää ja en vähentää, minä tahdon heitä kunnioittaa, ja ei heidän pidä huonoksi tuleman.
Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
20 Hänen poikansa pitää oleman niinkuin ennenkin, ja hänen yhteinen kansansa pitää menestymän minun edessäni; sillä minä tahdon rangaista kaikki ne, jotka heitä vaivaavat.
Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
21 Ja hänen ruhtinaansa pitää itse hänestä syntymän, ja hänen hallitsiansa tuleman itse hänestä. Ja minä tahdon antaa hänen lähestyä ja tulla minun eteeni; sillä kuka on se, joka minua niin sydämellisesti lähestyy? sanoo Herra.
Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
22 Ja teidän pitää oleman minun kansani, ja minä olen teidän Jumalanne.
‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
23 Katso, Herran ilma on tuleva julmuudella, kauhia rajuilma on lankeeva jumalattomain pään päälle.
Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
24 Herran julma viha ei ole taukoava, siihenasti kuin hän tekee ja toimittaa, mitä hänen mielessänsä on. Viimein pitää teidän sen kyllä ymmärtämän.
Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.

< Jeremian 30 >