< Jeremian 24 >

1 Katso, Herra osoitti minulle kaksi fikunakoria, pantua Herran templin eteen, sittekuin Nebukadnetsar, Babelin kuningas, oli vienyt pois Jekonian Jojakimin pojan Juudan kuninkaan, ja Juudan päämiehet, työmiehet ja sepät Jerusalemista, ja tuonut Babeliin.
Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
2 Yhdessä korissa olivat aivan hyvät fikunat, niinkuin ensin kypsyneet fikunat; mutta toisessa korissa olivat aivan pahat fikunat, niin ettei niitä taidettu syödä, että he olivat niin pahat.
Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
3 Ja Herra sanoi minulle: Jeremia, mitäs näet? Minä sanoin: fikunia; hyvät fikunat ovat aivan hyvät, ja pahat ovat aivan pahat, ettei niitä taideta syödä, niin pahat ne ovat.
Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
4 Ja Herran sana tapahtui minulle ja sanoi:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
5 Näin sanoo Herra Israelin Jumala; niinkuin nämät fikunat ovat hyvät, niin minä tahdon myös armollisesti korjata Juudan vankeja, jotka minä tästä kaupungista olen lähettänyt Kaldean maalle hyväksi;
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
6 Ja tahdon armollisesti katsoa heidän puoleensa, ja tuoda heitä tähän maahan jälleen, ja rakentaa heitä ja en tahdo lyödä maahan, minä tahdon heitä istuttaa ja en repiä ylös,
Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
7 Ja antaa heille sydämen, että he minun tuntevat, että minä olen Herra; ja he ovat minun kansani, ja minä tahdon olla heidän Jumalansa; sillä heidän pitää kaikesta sydämestänsä minun tyköni itsensä kääntämän.
Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
8 Mutta niinkuin pahat fikunat ovat pahat, ettei kukaan niitä syödä taida, sanoo Herra, niin tahdon minä myös hyljätä Zedekian, Juudan kuninkaan, niin myös hänen päämiehensä, ja mitä Jerusalemiin jäänyt on, ja jotka tässä maassa vielä ovat, ja jotka Egyptin maassa asuvat.
“‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
9 Minä tahdon saattaa heille onnettomuuden ja en tahdo antaa heidän olla jossakussa valtakunnassa maan päällä, niin että heidän pitää häpiään tuleman, sananparreksi, jutuksi ja kiroukseksi joka paikassa, kuhunka minä heidät ajava olen.
Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
10 Ja tahdon lähettää miekan, nälän ja ruton heidän sekaansa, siihenasti kuin heidän pitää maasta hukkuman, jonka minä heille ja heidän isillensä antanut olen.
Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”

< Jeremian 24 >