< Jeremian 23 >

1 Voi teitä paimenet, jotka turmelette ja hajoitatte minun laitumeni lauman! sanoo Herra.
“Ègbé ni fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń tú agbo ẹran mi ká tí ó sì ń pa wọ́n run!” ni Olúwa wí.
2 Sentähden näin sanoo Herra, Israelin Jumala, niistä paimenista, jotka minun kansaani kaitsevat: te olette hajoittaneet minun laumani ja ajaneet pois, ja ette etsineet sitä; katso, minä tahdon etsiä teitä teidän pahan elämänne tähden, sanoo Herra.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ ní ti àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń darí àwọn ènìyàn mi: “Nítorí tí ẹ̀yin tú agbo ẹran mi ká, tí ẹ lé wọn dànù tí ẹ̀yin kò sì bẹ̀ wọ́n wò. Èmi yóò jẹ yín ní yà nítorí nǹkan búburú tí ẹ ti ṣe,” ni Olúwa wí.
3 Ja minä tahdon koota laumani tähteet kaikista maakunnista, joihin minä heidät ajanut olen, ja tahdon saattaa heitä kotia jälleen heidän asuinsioihinsa, ja heidän pitää kasvaman ja enenemän.
“Èmi Olúwa tìkára mi yóò kó ìyókù agbo ẹran mi jọ láti inú gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti lé wọn, Èmi yóò mú wọn padà sínú pápá oko wọn, níbẹ̀ ni wọn ó ti bí sí i, tí wọn ó sì pọ̀ sí i.
4 Ja minä tahdon panna heille paimenet, joiden pitää heitä kaitseman, ettei heidän enään pidä pelkäämän eli vapiseman, eikä heitä pidä ahdistettaman, sanoo Herra.
Èmi ó wá olùṣọ́-àgùntàn fún wọn, tí yóò darí wọn, wọn kì yóò bẹ̀rù tàbí dààmú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan kì yóò sọnù,” ni Olúwa wí.
5 Katso, se aika tulee, sanoo Herra, että minä herätän Davidille vanhurskaan vesan, joka on kuninkaaksi tuleva, ja on hyvin hallitseva ja toimittava oikeuden ja vanhurskauden maan päällä.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi, ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.
6 Hänen aikanansa pitää Juudaa autettaman, ja Israel hyvässä turvassa asuman; ja tämä on hänen nimensä oleva kuin häntä kutsutaan: Herra meidän vanhurskautemme.
Ní ọjọ́ rẹ̀ ni a ó gba Juda là, Israẹli yóò sì máa gbé ní aláìléwu. Èyí ni orúkọ tí a ó fi máa pè é: Olúwa Òdodo wa.
7 Sentähden katso, se aika tulee, sanoo Herra, ettei heidän pidä enään sanoman: niin totta kuin Herra elää, joka Israelin lapset johdatti Egyptin maalta;
Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí ènìyàn kì yóò tún wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.’
8 Vaan niin totta kuin Herra elää, joka Israelin huoneen siemenen toi ulos ja johdatti pohjoisesta maasta ja kaikista maakunnista, joihin minä heidät ajanut olin; niin että he nyt saavat asua omassa maassansa.
Ṣùgbọ́n wọn yóò máa wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa ń bẹ tí ó mú irú-ọmọ ilé Israẹli wá láti ilẹ̀ àríwá àti láti àwọn ilẹ̀ ibi tí mo tí lé wọn lọ,’ wọn ó sì gbé inú ilẹ̀ wọn.”
9 Prophetaita vastaan: Minun sydämeni tahtoo haljeta minussa, kaikki minun luuni vapisevat. Minä olen niinkuin juopunut mies ja niinkuin se, joka viinasta horjuu, Herran edessä ja hänen pyhäin sanainsa edessä.
Nípa ti àwọn wòlíì èké. Ọkàn mi ti bàjẹ́ nínú mi, gbogbo egungun mi ni ó wárìrì. Èmi dàbí ọ̀mùtí ènìyàn, bí ọkùnrin tí ọtí wáìnì ń pa; nítorí Olúwa àti àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
10 Että maa on niin täynnä huorintekiöitä, että maa niin surkia on, että hän kirottu on, ja kedot metsissä kuivuvat; ja heidän elämänsä on paha, ja ei heidän hallituksensa mitään kelpaa.
Ilẹ̀ náà kún fún panṣágà ènìyàn; nítorí ègún, ilẹ̀ náà gbẹ, àwọn koríko orí aṣálẹ̀ ilẹ̀ náà rọ. Àwọn wòlíì tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọ́n sì ń lo agbára wọn lọ́nà àìtọ́.
11 Sillä sekä prophetat että papit ovat pahanilkiset; ja minä löydän heidän pahuutensa minun huoneessanikin, sanoo Herra.
“Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run; kódà nínú tẹmpili mi ni mo rí ìwà búburú wọn,” ni Olúwa wí.
12 Sentähden on heidän tiensä niinkuin liukastus pimiässä, jossa heidän pitää livistelemän ja lankeeman; sillä minä tahdon antaa onnettomuuden tulla heille heidän kuritusvuotenansa, sanoo Herra.
“Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́, a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn; níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú. Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn, ní ọdún tí a jẹ wọ́n ní ìyà,” ni Olúwa wí.
13 Ja Samarian prophetaissa olen minä nähnyt hulluuden; sillä he ennustivat Baalin kautta, ja hukuttelivat minun kansani Israelin.
“Láàrín àwọn wòlíì Samaria, Èmi rí ohun tí ń lé ni sá. Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Baali wọ́n sì mú Israẹli ènìyàn mi ṣìnà.
14 Mutta Jerusalemin prophetaissa näen minä kauhistuksen, kuinka he huorin tekevät ja valheessa vaeltavat, ja vahvistavat pahoja, ettei yhdenkään pitäisi pahuudestansa kääntymän; he ovat kaikki minun edessäni niinkuin Sodoma, ja sen asuvaiset niinkuin Gomorra.
Àti láàrín àwọn wòlíì Jerusalẹmu, èmi ti rí ohun búburú. Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké. Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára, tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀. Gbogbo wọn dàbí Sodomu níwájú mi, àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gomorra.”
15 Sentähden sanoo Herra Zebaot prophetaista näin: katso, minä tahdon syöttää heitä koiruoholla, ja antaa heidän juoda sappea; sillä Jerusalemin prophetaista tulee ulkokullaisuus koko maalle.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí ní ti àwọn wòlíì: “Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò, wọn yóò mu omi májèlé nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerusalẹmu ni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”
16 Näin sanoo Herra Zebaot: älkäät kuulko prophetain sanoja, jotka teille ennustavat; he pettävät teidät, sillä he saarnaavat sydämensä näkyjä, mutta ei Herran suusta.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ má ṣe fi etí sí àsọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín. Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán. Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn, kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.
17 He sanovat köykäisesti niille, jotka minua pilkkaavat: Herra on sen sanonut: teillä pitää rauha oleman; ja kaikille niille, jotka vaeltavat sydämensä ajatusten jälkeen, sanovat he: ei yksikään onnettomuus tule teidän päällenne.
Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé, ‘Olúwa ti wí pé, ẹ̀yin ó ní àlàáfíà.’ Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé, ‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’
18 Sillä kuka on Herran neuvossa ollut, joka hänen sanansa nähnyt ja kuullut on? kuka kuulteli ja kuuli hänen sanansa?
Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúró nínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí i tàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?
19 Katso, Herran tuuli on julmuuden kanssa tuleva, ja hirmuinen ilma on lankeeva jumalattomain pään päälle.
Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jáde pẹ̀lú ìbínú à fẹ́ yíká ìjì yóò fẹ́ sí orí àwọn olùṣe búburú.
20 Ei Herran viha lakkaa, siihenasti kuin hän tekee ja täyttää sen mikä hänen mielessänsä oli. Viimein pitää teidän sen kyllä ymmärtämän.
Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀ títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ, ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.
21 En minä lähettänyt prophetaita, kuitenkin he juoksivat; en minä puhunut heille, kuitenkin he ennustivat.
Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyí síbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn. Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
22 Sillä jos he olisivat pysyneet minun neuvossani, ja olisivat saarnanneet kansalleni minun sanaani, niin he olisivat heidät kääntäneet pahasta menostansa ja töidensä pahuudesta.
Ṣùgbọ́n ì bà ṣe pé wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi, wọn ìbá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi. Wọn ìbá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi fun àwọn ènìyàn wọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nà àti ìṣe búburú wọn.
23 Enkö minä Jumala, joka läsnä olen, sanoo Herra, ja en ole se Jumala, joka kaukana on?
“Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?” ni Olúwa wí, “kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jíjìn.
24 Luuletkos, että joku taitaa itsensä niin salaisesti kätkeä, etten minä häntä näe? sanoo Herra; enkö minä se ole, joka täytän taivaan ja maan? sanoo Herra.
Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan, kí èmi má ba a rí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi kò ha a kún ọ̀run àti ayé bí?” ni Olúwa wí.
25 Minä kuulen, että prophetat saarnaavat ja ennustavat valhetta minun nimeeni, ja sanovat: minä näin unta, minä näin unta.
“Mo ti gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’
26 Koska siis prophetat tahtovat lakata? ne jotka valhetta ennustavat, ja ennustavat oman sydämensä petoksia,
Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀síwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìtànjẹ ọkàn wọn?
27 Ja tahtovat, että minun kansani pitäis unhottaman minun nimeni heidän uniensa tähden, joita he toinen toisellensa saarnaavat, niinkuin heidän isänsäkin unhottivat minun nimeni Baalin tähden.
Wọ́n rò wí pé àlá tí wọ́n ń sọ fún ara wọn yóò mú kí àwọn ènìyàn mi gbàgbé orúkọ mi, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé orúkọ mi nípa sí sin òrìṣà Baali.
28 Propheta, jolla unia on, hän saarnatkaan unia; mutta jolla on minun sanani, hän saarnatkaan minun sanaani oikein. Mitä akanat ovat nisujen suhteen? sanoo Herra.
Jẹ́ kí wòlíì tí ó bá lá àlá sọ àlá rẹ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mí sọ ọ́ ní òtítọ́. Kí ni koríko gbígbẹ ní í ṣe nínú ọkà?” ni Olúwa wí.
29 Eikö minun sanani ole niinkuin tuli, sanoo Herra, ja niinkuin vasara, joka vuoren murentaa?
“Ọ̀rọ̀ mi kò ha a dàbí iná?” ni Olúwa wí, “àti bí òòlù irin tí ń fọ́ àpáta túútúú?
30 Sentähden katso, minä tahdon tehdä niitä prophetaita vastaan, sanoo Herra, jotka minun sanani toinen toiseltansa varastavat.
“Nítorí náà, èmi lòdì sí àwọn wòlíì ni,” Olúwa wí, “Tí ń jí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ó ti ọ̀dọ̀ mi wá lò lọ́dọ̀ ara wọn.
31 Katso, minä tahdon niitä prophetaita vastaan tehdä, sanoo Herra, jotka omia puheitansa puhuvat ja sanovat: hän on sen sanonut.
Bẹ́ẹ̀,” ni Olúwa wí, “Èmi lòdì sí àwọn wòlíì tí wọ́n lo ahọ́n wọn káàkiri, síbẹ̀ tí wọ́n ń sọ wí pé, ‘Olúwa wí.’
32 Katso, minä tahdon tehdä niitä vastaan, jotka pettäväisiä unia ennustavat, sanoo Herra, ja saarnaavat niitä, vietellen minun kansani valheillansa ja turhilla jutuillansa, vaikka en minä ole heitä lähettänyt, enkä heitä käskenyt, ei myös he tälle kansalle ole ensinkään hyödylliset, sanoo Herra.
Nítòótọ́, mo lòdì sí àwọn tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àlá èké,” ni Olúwa wí. “Wọ́n ń sọ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà nípa onírúurú èké wọn, síbẹ̀ èmi kò rán wọn tàbí yàn wọ́n. Wọn kò sì ran àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ́wọ́ bí ó ti wù kí ó kéré mọ,” ni Olúwa wí.
33 Jos tämä kansa, eli joku propheta, taikka pappi kysyy sinulta ja sanoo: Mikä on Herran kuorma? niin sinun pitää vastaaman heille: mikä kuorma? Minä tahdon heittää teidät pois, sanoo Herra.
“Nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, tàbí wòlíì tàbí àlùfáà bá bi ọ́ léèrè wí pé, ‘Kí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa?’ Sọ fún wọn wí pé, ‘Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ wo? Èmi yóò pa yín tì ni Olúwa wí.’
34 Ja jos joku propheta, taikka pappi, elikkä kansa on sanova: tämä on Herran kuorma; sitä tahdon minä kurittaa ja hänen huonettansa.
Bí wòlíì tàbí àlùfáà tàbí ẹnikẹ́ni bá sì gbà wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’ Èmi yóò fi ìyà jẹ ọkùnrin náà àti gbogbo agbo ilé rẹ̀.
35 Mutta näin pitää kukin puhuman toisellensa ja sanoman keskenänsä: mitä Herra vastaa? ja mitä Herra sanoo?
Èyí ni ohun tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ọ̀rẹ́ àti ará ilé rẹ̀: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa sọ?’
36 Ja älkäät sitä enään kutsuko Herran kuormaksi; sillä kullekin pitää oma sanansa oleman kuormaksi, että te niin elävän Jumalan, Herran Zebaotin, meidän Jumalamme sanan käännätte.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run wa padà.
37 Sentähden pitää sinun sanoman prophetalle näin: mitä Herra vastaa? ja mitä Herra sanoo?
Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’
38 Että te sanotte: Herran kuorma, sentähden sanoo Herra näin: että te kutsutte sanan Herran kuormaksi, niin minä olen lähettänyt teidän tykönne ja antanut sanoa, ettei teidän pitänyt sitä kutsuman Herran kuormaksi.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ, Ẹ̀yin ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe lò ó mọ́, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’
39 Sentähden katso, minä tahdon teidät peräti unhottaa, ja heittää teitä pois ynnä kaupunkinne kanssa, jonka minä teille ja teidän isillenne antanut olen, minun kasvoini edestä;
Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn ìlú tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.
40 Ja tahdon saattaa teitä ijankaikkiseksi pilkaksi ja ijankaikkiseksi häpiäksi, jota ei ikänä pidä unhotettaman.
Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”

< Jeremian 23 >