< Jeremian 14 >

1 Tämä on se sana, jonka Herra sanoi Jeremialle, kalliista ajasta:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Jeremiah nípa ti àjàkálẹ̀-ààrùn:
2 Juuda murehtii, ja hänen porttinsa ovat hyljätyt, maassa ollaan surullisesti, ja Jerusalemissa on valitus.
“Juda káàánú, àwọn ìlú rẹ̀ kérora wọ́n pohùnréré ẹkún fún ilẹ̀ wọn, igbe wọn sì gòkè lọ láti Jerusalẹmu.
3 Ylimmäiset lähettävät alamaisensa veden perään, mutta kuin he tulevat kaivolle, niin ei he löydä vettä, ja kantavat niin astiansa kotia tyhjänä jälleen; he käyvät surullisina ja häpeevät, ja peittävät päänsä,
Àwọn ọlọ́lá ènìyàn rán àwọn ìránṣẹ́ wọn lọ bu omi, wọ́n lọ sí ìdí àmù ṣùgbọ́n wọn kò rí omi. Wọ́n padà pẹ̀lú ìkòkò òfìfo; ìrẹ̀wẹ̀sì àti àìnírètí bá wọn, wọ́n sì bo orí wọn.
4 Että maa pakahteli, ettei sada maan päälle, peltomiehet käyvät suruissansa ja peittävät päänsä,
Ilẹ̀ náà sán nítorí pé kò sí òjò ní ilẹ̀ náà; ìrètí àwọn àgbẹ̀ di òfo, wọ́n sì bo orí wọn.
5 Sillä naaraspeurat, jotka kedolla poikivat, hylkäävät vasikkansa, ettei ruoho kasva.
Kódà, abo àgbọ̀nrín tí ó wà lórí pápá fi ọmọ rẹ̀ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bí sílẹ̀, torí pé kò sí koríko.
6 Ja metsä-aasit seisovat mäillä ja haistelevat tuulta niinkuin lohikärmeet, ja heidän silmänsä nääntyvät, ettei heinä kasva.
Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó dúró lórí òkè òfìfo wọ́n sì ń mí ẹ̀fúùfù bí ìkookò ojú wọn kò ríran nítorí pé kò sí koríko jíjẹ.”
7 Voi Herra, meidän pahat tekomme ovat sen kyllä ansainneet, mutta auta kuitenkin sinun nimes tähden; sillä meidän kovakorvaisuutemme on suuri, kuin me olemme sinua vastaan syntiä tehneet.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ wa jẹ́rìí lòdì sí wa, wá nǹkan kan ṣe sí i Olúwa, nítorí orúkọ rẹ. Nítorí ìpadàsẹ́yìn wa ti pọ̀jù, a ti ṣẹ̀ sí ọ.
8 Sinä olet Israelin turva ja auttaja hädässä; miksis olet niinkuin muukalainen maassa, ja niinkuin vieras, joka siihen ainoasti yötyy?
Ìrètí Israẹli; ìgbàlà rẹ lásìkò ìpọ́njú, èéṣe tí ìwọ dàbí àlejò ní ilẹ̀ náà bí arìnrìn-àjò tí ó dúró fún bí òru ọjọ́ kan péré?
9 Miksis olet niinkuin mies, joka on pelkuri, ja niinkuin väkevä, joka ei auttaa taida? Sinä olet kuitenkin meidän seassamme, Herra, ja me nimitetään sinun nimelläs; älä meitä hylkää.
Èéṣe tí ìwọ dàbí ẹni tí a dààmú, bí jagunjagun tí kò le ran ni lọ́wọ́? Ìwọ wà láàrín wa, Olúwa, orúkọ rẹ ni a sì ń pè mọ́ wa; má ṣe fi wá sílẹ̀.
10 Näin sanoo Herra tästä kansasta: he juoksevat mielellänsä sinne ja tänne, eikä pysy alallansa; sentähden ei he kelpaa Herralle, vaan hän muistaa kyllä heidän pahuutensa, ja tahtoo etsiä heidän syntejänsä.
Báyìí ni Olúwa sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí: “Wọ́n fẹ́ràn láti máa rìn kiri; wọn kò kó ọkàn wọn ní ìjánu. Nítorí náà Olúwa kò gbà wọ́n; yóò wá rántí ìwà búburú wọn báyìí, yóò sì fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn jẹ wọ́n.”
11 Ja Herra sanoi minulle: ei sinun pidä rukoileman tämän kansan edestä heidän hyväksensä.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe gbàdúrà fún àlàáfíà àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
12 Sillä jos he paastoavat, en minä sittekään kuule heidän rukoustansa, ja jos he polttouhria ja ruokauhria uhraavat, niin ei ne minulle kelpaa; vaan minä lopetan heidät miekalla, nälällä ja rutolla.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbààwẹ̀, èmi kò ní tẹ́tí sí igbe wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìyẹ̀fun, èmi ò nígbà wọ́n. Dípò bẹ́ẹ̀, èmi ó fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn pa wọ́n run.”
13 Niin minä sanoin: oi Herra, Herra, katso, prophetat sanovat heille: ei teidän pidä miekkaa näkemän, eikä saaman kallista aikaa, mutta minä annan teille hyvän rauhan tässä paikassa.
Ṣùgbọ́n mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè. Àwọn wòlíì ń sọ fún wọn pé, ‘Ẹ kò ni rí idà tàbí ìyàn. Dájúdájú èmi ó fún yín ní àlàáfíà tí yóò tọ́jọ́ níbí yìí?’”
14 Ja Herra sanoi minulle: prophetat ennustavat valhetta minun nimeeni, en ole minä heitä lähettänyt enkä käskenyt, elikkä puhunut heidän kanssansa; he saarnaavat teille vääriä näkyjä, noituutta, turhuutta ja sydämensä petosta.
Nígbà náà Olúwa sọ fún mi pé, “Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Èmi kò rán wọn, tàbí yàn wọ́n tàbí bá wọn sọ̀rọ̀. Ìran èké ni wọ́n ń rí sí i yín. Àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín nípa ìran ìrírí, àfọ̀ṣẹ, ìbọ̀rìṣà àti ìtànjẹ ọkàn wọn.
15 Sentähden näin sanoo Herra niistä prophetaista, jotka minun nimeeni ennustavat: vaikka en minä heitä ole lähettänyt, ja kuitenkin he sanovat: ei miekan ja kalliin ajan pidä tähän maahan tuleman; ne prophetat pitää kuoleman miekalla ja nälällä.
Nítorí náà, èyí ni Olúwa sọ nípa àwọn wòlíì tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ mi. Èmi kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n sì ń sọ pé, ‘Idà kan tàbí ìyàn, kì yóò dé ilẹ̀ yìí.’ Àwọn wòlíì kan náà yóò parẹ́ nípa idà àti ìyàn.
16 Ja kansa, jolle he ennustavat, pitää nälästä ja miekasta siellä ja täällä Jerusalemin kaduilla makaavan, ja ei heillä pidä yhtään oleman, joka heitä hautaa, heitä ja heidän vaimojansa, poikiansa ja tyttäriänsä; ja minä tahdon kaataa heidän pahuutensa heidän päällensä.
Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún ni a ó lé sí òpópónà Jerusalẹmu torí idà àti ìyàn. Wọn kò ní i rí ẹni tí yóò sìn wọ́n tàbí ìyàwó wọn, àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn. Èmi yóò mú ìdààmú tí ó yẹ bá ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
17 Ja sinun pitää sanoman heille tämän sanan: minun silmäni vuotavat kyyneleitä yli yötä ja päivää, ja ei lakkaa; sillä neitsy, minun kansani tytär, on hirmuisesti vaivattu ja surkiasti lyöty.
“Kí ìwọ kí ó sì sọ ọ̀rọ̀ yìí fún wọn pé: “‘Jẹ́ kí ojú mi kí ó sun omijé ní ọ̀sán àti ní òru láìdá; nítorí tí a ti ṣá wúńdíá, ọmọ ènìyàn mi ní ọgbẹ́ ńlá pẹ̀lú lílù bolẹ̀.
18 Jos minä menen kedolle, niin katso, siellä makaavat miekalla lyödyt; jos minä tulen kaupunkiin, niin katso, siellä makaavat nälästä nääntyneet; sillä prophetat ja papit pitää myös menemän pois siihen maahan, jota ei he tunne.
Bí mo bá lọ sí orílẹ̀-èdè náà, Èmi yóò rí àwọn tí wọ́n fi idà pa. Bí mo bá lọ sí ìlú ńlá, èmi rí àwọn tí ìyàn ti sọ di aláàrùn. Wòlíì àti Àlùfáà ti lọ sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.’”
19 Oletkos Juudan peräti hyljännyt, eli ilvottaako sielus Zionia? miksi sinä olet niin meitä lyönyt, ettei kenkään parantaa taida? Me toivoimme rauhaa, mutta ei tule mitään hyvää: parantamisen aikaa, ja katso, tässä on vielä nyt enempi vahinkoa.
Ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ pátápátá ni? Ṣé o ti ṣá Sioni tì? Èéṣe tí o fi pọ́n wa lójú tí a kò fi le wò wá sàn? A ń retí àlàáfíà ṣùgbọ́n ohun rere kan kò tí ì wá, ní àsìkò ìwòsàn ìpayà là ń rí.
20 Herra, me tunnemme jumalattoman menomme, ja isäimme pahat teot; sillä me olemme syntiä tehneet sinua vastaan.
Olúwa, a jẹ́wọ́ ìwà ibi wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa; lóòótọ́ ni a ti ṣẹ̀ sí ọ.
21 Mutta sinun nimes tähden älä anna meitä häväistyksi tulla, älä kunnias istuinta anna pilkatuksi tulla; muista siis, ja älä anna liittos meidän kanssamme lakata.
Nítorí orúkọ rẹ má ṣe kórìíra wa; má ṣe sọ ìtẹ́ ògo rẹ di àìlọ́wọ̀. Rántí májẹ̀mú tí o bá wa dá kí o má ṣe dà á.
22 Ei ole kuitenkaan pakanain epäjumalain seassa, joka sateen antaa taitaa, ei taida taivas myöskään sataa; sinä ainoa olet Herra meidän Jumalamme, jonka päälle me toivomme, sillä sinä olet kaikki nämät tehnyt.
Ǹjẹ́ èyíkéyìí àwọn òrìṣà yẹ̀yẹ́ tí àwọn orílẹ̀-èdè le ṣe kí òjò rọ̀? Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ fúnra rẹ̀ rọ òjò bí? Rárá, ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run wa. Torí náà, ìrètí wa wà lọ́dọ̀ rẹ, nítorí pé ìwọ lo ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.

< Jeremian 14 >