< 1 Mooseksen 32 >
1 Mutta Jakob meni tietänsä myöten, ja Jumalan enkelit tulivat häntä vastaan.
Jakọbu sì ń bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ, àwọn angẹli Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀.
2 Ja koska hän näki heidät, sanoi hän: Nämä ovat Jumalan sotajoukko. Ja hän kutsui sen paikan Mahanaim.
Nígbà tí Jakọbu rí wọn, ó wí pé, “Àgọ́ Ọlọ́run ni èyí!” Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ni Mahanaimu.
3 Niin Jakob lähetti sanansaattajat edellänsä veljensä Esaun tykö, Seirin maakuntaan, Edomin maalle.
Jakọbu sì rán àwọn oníṣẹ́ ṣáájú ara rẹ̀ sí Esau arákùnrin rẹ̀ ni ilẹ̀ Seiri ní orílẹ̀-èdè Edomu.
4 Ja käski heitä, sanoen: sanokaat näin minun herralleni Esaulle: näin sanoo sinun palvelias Jakob: minä olen ollut muukalainen Labanin tykönä, ja viipynyt tähän asti.
Ó pàṣẹ fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò wí fún Esau olúwa mi, Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, ‘Mo ti ṣe àtìpó lọ́dọ̀ Labani títí ó fi di àsìkò yìí.
5 Ja minulla on karjaa ja aaseja, lampaita, palvelioita ja piikoja: ja lähetin ilmoittamaan minun herralleni, löytääkseni armoa sinun edessäs.
Mo ní màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn àti ewúrẹ́. Mo tún ni àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin. Mo ń ránṣẹ́ yìí sí olúwa mi kí èmi le è rí ojúrere rẹ.’”
6 Sanansaattajat palasivat Jakobin tykö, sanoen: me tulimme Esaun sinun veljes tykö; ja hän tulee sinua vastaan, ja neljäsataa miestä hänen kanssansa.
Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà padà tọ Jakọbu wà, wọ́n wí pé “Esau arákùnrin rẹ ti múra láti wá pàdé rẹ pẹ̀lú irinwó ọkùnrin.”
7 Niin peljästyi Jakob kovin, ja ahdistus tuli hänen päällensä: ja jakoi väen, joka oli hänen kanssansa, ja lampaat, ja karjan ja kamelit kahteen joukkoon.
Pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìbànújẹ́ ni Jakọbu fi pín àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìpín méjì, ó sì pín àwọn ẹran ọ̀sìn, agbo ẹran àti ìbákasẹ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
8 Ja sanoi: jos Esau tulee yhden joukon päälle, ja lyö sen; niin jäänyt joukko pääsee.
Nítorí ó rò ó nínú rẹ̀ pé, “Bí Esau bá kọjú ogun sí ìpín kan, ìpín kejì yóò sá àsálà.”
9 Ja Jakob sanoi: minun isäni Abrahamin Jumala, ja minun isäni Isaakin Jumala, Herra joka sanoit minulle: palaja maalles ja sukuis tykö, ja minä teen sinulle hyvää.
Nígbà náà ni Jakọbu gbàdúrà pe, “Ọlọ́run Abrahamu baba mi, àti Ọlọ́run Isaaki baba mi, Olúwa tí ó wí fún mi pé, ‘Padà sí orílẹ̀-èdè rẹ àti sọ́dọ̀ àwọn ìbátan rẹ, èmi yóò sì ṣe ọ́ ní rere,’
10 Minä olen mahdotoin kaikkeen siihen armoon, ja kaikkeen siihen totuuteen, jonka sinä teit palvelialles. Sillä koska minä tämän Jordanin ylitse menin, ei minulla muuta ollut kuin minun sauvani; mutta nyt minulla on kaksi joukkoa.
èmi kò tilẹ̀ yẹ fún àánú àti òtítọ́ tí o ń fihàn fún ìránṣẹ́ rẹ. Nítorí pé, kìkì ọ̀pá mi ni mo mu kúrò ni ilé kọjá Jordani yìí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, èmi ti di ẹgbẹ́ méjì.
11 Pelasta siis nyt minua minun veljeni Esaun käsistä: sillä minä pekään hänen tulevan ja lyövän minun, ja äidin lapsinensa.
Jọ̀wọ́ Olúwa gbà mí lọ́wọ́ Esau arákùnrin mi, nítorí ẹ̀rù ń bà mí pé yóò wá dojú ìjà kọ mí àti àwọn ìyàwó pẹ̀lú àwọn ọmọ mi.
12 Sinä olet kumminkin sanonut: minä teen kaiketi sinulle hyvää; ja lisään sinun siemenes niinkuin sannan meressä, joka paljouden tähden ei luettaa taideta.
Ṣùgbọ́n ìwọ ti ṣèlérí pé, ‘Èmi yóò mú ọ gbilẹ̀, èmi yóò sì mú kí àwọn ìran rẹ dà bì í yanrìn òkun tí ẹnikẹ́ni kò le è kà.’”
13 Ja hän yötyi sinne, ja otti niistä, kuin olivat käsillä, lahjoja lähettääksensä veljellensä Esaulle:
Ó sì lo òru ọjọ́ náà níbẹ̀. Ó mú ẹ̀bùn fún Esau arákùnrin rẹ̀ nínú ohun ìní rẹ̀.
14 Kaksisataa vuohta, ja kaksikymmentä kaurista: kaksisataa lammasta ja kaksikymmentä jäärää:
Igba ewúrẹ́, ogún òbúkọ, igba àgùntàn, ogún àgbò,
15 Imettäviä kameleja varsoinensa kolmekymmentä: neljäkymmentä lehmää ja kymmenen härkää, kaksikymmentä aasia ja kymmenen varsaa.
ọgbọ̀n abo ìbákasẹ pẹ̀lú ọmọ wọn, ogójì abo màlúù àti akọ màlúù mẹ́wàá, ogún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá.
16 Ja antoi ne palvelioittensa käsiin, itsekunkin lauman erinänsä; ja sanoi palvelioillensa: menkäät minun edelläni, ja pitäkäät väli jokaisen lauman vaiheella.
Ó sì fi wọ́n lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣáájú mi, kí ẹ sì jẹ́ kí àlàfo wà láàrín ọ̀wọ́ agbo ẹran kọ̀ọ̀kan sí èkejì.”
17 Ja käski ensimäiselle, sanoen: Koska minun veljeni Esau kohtaa sinun, ja kysyy sinulta, kenenkäs olet, ja kuhunkas menet? ja kenenkä nämät ovat, joitas ajat edelläs?
Ó pàṣẹ fún èyí tí ó ṣáájú pé, “Nígbà tí arákùnrin mi Esau bá pàdé rẹ tí ó sì béèrè ẹni tí ìwọ í ṣe àti ibi tí ìwọ ń lọ àti ẹni tí ó ni agbo ẹran tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ,
18 Niin sano: nämät ovat sinun palvelias Jakobin lahjat, lähetetyt minun herralleni Esaulle: ja katso, hän tulee myös itse meidän jälissämme.
nígbà náà ni ìwọ yóò wí pé, ‘Ti ìránṣẹ́ rẹ Jakọbu ni wọ́n. Ẹ̀bùn ni ó sì fi wọ́n ṣe fún Esau olúwa mi, òun pàápàá ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’”
19 Niin käski hän myös toiselle ja kolmannelle, ja kaikille niille, jotka kävivät lauman jälissä, sanoen: tämän minun sanani jälkeen puhukaat Esaulle, koska te hänen löydätte.
Jakọbu sì pàṣẹ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ fún ọ̀wọ́ kejì àti ẹ̀kẹta àti àwọn tókù tí ó tẹ̀lé agbo ẹran pé, “Ohun kan ṣoṣo yìí náà ni kí ẹ sọ fún Esau nígbà tí ẹ bá pàdé rẹ̀.
20 Ja sanokaat myös: katso, sinun palvelias Jakob on myös meidän jälissämme; sillä hän ajatteli: minä lepytän hänen lahjoilla, jotka minun edelläni menevät; sitte tahdon minä nähdä hänen kasvonsa, mitämaks, hän ottaa vastaan minun ystävällisesti.
Kí ẹ rí i dájú wí pé, ẹ sọ fún un pé, ‘Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’” Èrò Jakọbu ni láti fi àwọn ẹ̀bùn wọ̀nyí tu Esau lójú pé bóyá inú Esau yóò dùn sí òun nígbà tí àwọn bá pàdé.
21 Niin lahjat menivät hänen edellänsä; mutta hän oli itse siinä yötä joukkoinensa.
Nítorí náà ẹ̀bùn Jakọbu ṣáájú rẹ̀ lọ, Jakọbu pàápàá sì lo òru ọjọ́ náà nínú àgọ́.
22 Ja nousi yöllä ja otti kaksi emäntäänsä, ja ne kaksi piikaansa, ja yksitoistakymmentä lastansa: ja meni ylitse Jabbokin luotuspaikkaan.
Ó sì dìde ní òru ọjọ́ náà, ó mú àwọn aya rẹ̀ méjèèjì, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ méjèèjì, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mọ́kọ̀ọ̀kànlá, wọ́n sì kọjá ní ìwọdò Jabbok.
23 Ja otti ne ja vei heidät virran ylitse: ja vei myös ylitse kaikki, mitä hänellä oli.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti rán wọn kọjá odò tán sí òkè odò, ó sì rán àwọn ohun ìní rẹ̀ kọjá pẹ̀lú.
24 Mutta Jakob jäi sille puolelle yksinänsä. Silloin paineli yksi mies hänen kanssansa, siihenasti kuin aamurusko nousi.
Ó sì ku Jakọbu nìkan, ọkùnrin kan sì bá a ja ìjàkadì títí ó fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
25 Ja kuin hän näki, ettei hän voittanut häntä, rupesi hän hänen reiteensä, niin että Jakobin reisiluu horjahtui painellessa hänen kanssansa.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà rí i pé òun kò le borí Jakọbu, ó fọwọ́ kàn án ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀, egungun náà sì yẹ̀ kúrò lórí ike, bí ó ti ń ja ìjàkadì.
26 Ja hän sanoi: päästä minua, sillä aamurusko nousee. Mutta hän vastasi: en minä päästä sinua, jolles siunaa minua.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí fún un pé, “Jẹ́ kí ń máa lọ, nítorí ojúmọ́ ti mọ́.” Ṣùgbọ́n Jakọbu dá a lóhùn pé, “Èmi kò ní jẹ́ kí o lọ, àyàfi bí o bá súre fún mi.”
27 Ja hän sanoi hänelle: mikä sinun nimes on? hän vastasi: Jakob.
Ọkùnrin náà béèrè orúkọ rẹ̀. Ó sì wí fún un pé, “Jakọbu ni òun ń jẹ́.”
28 Ja hän sanoi: ei sinua sillen pidä kutsuttaman Jakob, vaan IsraEl: sillä sinä olet taistellut Jumalan ja ihmisten kanssa, ja olet voittanut.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí pé, “Orúkọ rẹ kì yóò jẹ́ Jakọbu mọ́ bí kò ṣe Israẹli, nítorí pé ìwọ ti bá Ọlọ́run àti ènìyàn jà, o sì borí.”
29 Ja Jakob kysyi häneltä, ja sanoi: sanos nyt sinun nimes. Mutta hän sanoi: miksis minun nimeäni kysyt? Ja hän siunasi häntä siinä paikassa.
Jakọbu sì bẹ ọkùnrin náà pé, “Sọ orúkọ rẹ fún mi.” Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà sá à dáhùn pé, “Èéṣe tí o ń béèrè orúkọ mi?” Lẹ́yìn náà ó súre fún Jakọbu níbẹ̀.
30 Ja Jakob kutsui sen paikan Pniel: sillä minä olen nähnyt Jumalan kasvosta kasvoon, ja minun sieluni on vapahdettu.
Jakọbu sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Penieli pé, “Mo rí Ọlọ́run ní ojúkojú, síbẹ̀ a dá ẹ̀mí mi sí.”
31 Ja aurinko nousi, koska hän Pnielin ohitse kävi, ja hän ontui reidestänsä.
Bí ó sì ti ń kọjá Penieli, oòrùn ràn bá a, ó sì ń tiro nítorí itan rẹ̀.
32 Sentähden ei syö Israelin lapset reisisuonta tähän päivään asti, että Jakobin reisiluu horjahtui.
Ìdí nìyí tí àwọn ọmọ Israẹli kì í fi í jẹ iṣan tí ó wà ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀ títí di òní olónìí, nítorí níbi iṣan náà ni a ti fọwọ́ kan ibi tí egungun itan Jakọbu ti bẹ̀rẹ̀.