< 1 Mooseksen 3 >

1 Ja kärme oli kavalin kaikkia eläimiä maan päällä, jotka Herra Jumala tehnyt oli, ja se sanoi vaimolle: sanoiko Jumala, älkäät syökö kaikkinaisista puista Paradisissa?
Ejò sá à ṣe alárékérekè ju àwọn ẹranko igbó yòókù tí Olúwa Ọlọ́run dá lọ. Ó sọ fún obìnrin náà pé, “Ǹjẹ́ òtítọ́ ha ni Ọlọ́run wí pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ èso èyíkéyìí lára àwọn igi tí ó wà nínú ọgbà’?”
2 Niin vaimo sanoi kärmeelle: me syömme niiden puiden hedelmistä, jotka ovat Paradisissa;
Obìnrin náà dá ejò lóhùn pé, “Àwa lè jẹ lára àwọn èso igi tí ó wà nínú ọgbà,
3 Mutta sen puun hedelmästä, joka on keskellä Paradisia, on Jumala sanonut: älkäät syökö siitä, ja älkäät ruvetko siihen, ettette kuolis.
ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ pé, ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ lára èso igi tí ó wà láàrín ọgbà, ẹ kò sì gbọdọ̀ fi ọwọ́ kàn án, bí ẹ̀yin bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin yóò kùú.’”
4 Niin kärme sanoi vaimolle: ei suinkaan pidä teidän kuolemalla kuoleman.
Ejò wí fún obìnrin náà pé, “Ẹ̀yin kì yóò kú ikúkíkú kan.”
5 Vaan Jumala tietää, että jona päivänä te syötte siitä, aukenevat teidän silmänne, ja te tulette niinkuin Jumala, tietämään hyvän ja pahan.
“Nítorí Ọlọ́run mọ̀ wí pé, bí ẹ̀yin bá jẹ nínú rẹ̀, ojú yín yóò là, ẹ̀yin yóò sì dàbí Ọlọ́run, ẹ̀yin yóò sì mọ rere yàtọ̀ sí búburú.”
6 Ja vaimo näki siitä puusta olevan hyvän syödä, ja että se oli ihana nähdä ja suloinen puu antamaan ymmärryksen: ja otti sen hedelmästä ja söi, ja antoi miehellensä siitä, ja hän söi.
Nígbà tí obìnrin náà rí i wí pé èso igi náà dára fún oúnjẹ àti pé, ó sì dùn ún wò, àti pé ó ń mú ni ní ọgbọ́n, ó mú díẹ̀ níbẹ̀, ó sì jẹ ẹ́. Ó sì mú díẹ̀ fún ọkọ rẹ̀, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, òun náà sì jẹ ẹ́.
7 Silloin aukenivat molempain heidän silmänsä, ja äkkäsivät, että he olivat alasti; ja sitoivat yhteen fikunalehtiä, ja tekivät heillensä peitteitä.
Nígbà náà ni ojú àwọn méjèèjì sì là, wọ́n sì mọ̀ pé àwọn wà ní ìhòhò; wọ́n sì rán ewé ọ̀pọ̀tọ́ pọ̀, wọ́n sì fi bo ara wọn.
8 Ja he kuulivat Herran Jumalan äänen, joka käyskenteli Paradisissa, kuin päivä viileäksi tuli. Ja Adam lymyi emäntinensä Herran Jumalan kasvoin edestä puiden sekaan Paradisissa.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà àti aya rẹ̀ gbọ́ ìró Olúwa Ọlọ́run bí ó ti ń rìn nínú ọgbà, nígbà tí ojú ọjọ́ tura, wọ́n sì fi ara pamọ́ kúrò níwájú Olúwa Ọlọ́run sí àárín àwọn igi inú ọgbà.
9 Ja Herra Jumala kutsui Adamin, ja sanoi hänelle: Kussas olet?
Ṣùgbọ́n Olúwa Ọlọ́run ké pe ọkùnrin náà pé, “Níbo ni ìwọ wà?”
10 Ja hän sanoi: minä kuulin sinun äänes Paradisissa, ja pelkäsin: sillä minä olen alasti, ja sen tähden minä lymyin.
Ó dáhùn pé, “Mo gbúròó rẹ̀ nínú ọgbà, ẹ̀rù sì bà mí, nítorí pé, mo wà ní ìhòhò, mo sì fi ara pamọ́.”
11 Ja hän sanoi: kuka sinulle ilmoitti, ettäs alasti olet? Etkös syönyt siitä puusta, josta minä sinua haastoin syömästä?
Ọlọ́run wí pé, “Ta ni ó wí fún ọ pé ìhòhò ni ìwọ wà? Ṣé ìwọ ti jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀ ni?”
12 Niin sanoi Adam: vaimo, jonkas annoit minulle, antoi minulle siitä puusta, ja minä söin.
Ọkùnrin náà wí pé, “Obìnrin tí ìwọ fi fún mi, ni ó fún mi nínú èso igi náà, mo sì jẹ ẹ́.”
13 Silloin sanoi Herra Jumala vaimolle: miksis sen teit? Ja vaimo sanoi: kärme petti minut, ja minä söin.
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe yìí?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Ejò ni ó tàn mí jẹ, mo sì jẹ ẹ́.”
14 Ja Herra Jumala sanoi kärmeelle: ettäs tämän teit, kirottu ole sinä kaikesta karjasta, ja kaikista eläimistä maalla: sinun pitää käymän vatsallas, ja syömän maata kaiken elinaikas.
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run wí fún ejò náà pé, “Nítorí tí ìwọ ti ṣe èyí, “Ègún ni fún ọ ju gbogbo ohun ọ̀sìn àti gbogbo ẹranko igbó tókù lọ! Àyà rẹ ni ìwọ yóò fi máa wọ́, ìwọ yóò sì máa jẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.
15 Ja minä panen vainon sinun ja vaimon välille, ja sinun siemenes ja hänen siemenensä välille; sen pitää rikki polkemaan sinun pääs, ja sinä olet pistävä häntä kantapäähän.
Èmi yóò sì fi ọ̀tá sí àárín ìwọ àti obìnrin náà, àti sí àárín irú-ọmọ rẹ àti irú-ọmọ obìnrin náà; òun yóò fọ́ orí rẹ, ìwọ yóò sì bù ú jẹ ní gìgísẹ̀.”
16 Ja vaimolle sanoi hän: Minä saatan sinulle paljon tuskaa, koskas raskaaksi tulet: sinun pitää synnyttämän lapsia kivulla, ja sinun tahtos pitää miehes alle annettu oleman, ja hänen pitää vallitseman sinua.
Ọlọ́run wí fún obìnrin náà pé, “Èmi yóò fi kún ìrora rẹ ní àkókò ìbímọ; ni ìrora ni ìwọ yóò máa bí ọmọ. Ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ ni ìfẹ́ rẹ yóò máa fà sí, òun ni yóò sì máa ṣe àkóso rẹ.”
17 Ja Adamille sanoi hän: ettäs kuulit emäntäs ääntä, ja söit puusta, josta minä kielsin sinua sanoen: ei sinun pidä siitä syömän: kirottu olkoon maa sinun tähtes; surulla pitää sinun elättämän itses hänestä kaiken elinaikas.
Ọlọ́run sì wí fún Adamu pé, “Nítorí pé ìwọ fetí sí aya rẹ, ìwọ sì jẹ nínú èso igi tí mo pàṣẹ fún ọ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀,’ “Ègún ni fún ilẹ̀ nítorí rẹ; nínú ọ̀pọ̀ làálàá ni ìwọ yóò jẹ nínú rẹ̀, ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ.
18 Orjantappuroita ja ohdakkeita pitää hänen kasvaman, ja sinun pitää maan ruohoja syömän.
Ilẹ̀ yóò sì hu ẹ̀gún àti èṣùṣú fún ọ, ewéko igbó ni ìwọ yóò sì máa jẹ.
19 Sinun otsas hiessä pitää sinun syömän leipää, siihen asti kuin sinä maaksi jällensä tulet, ettäs siitä otettu olet: sillä sinä olet maa, ja maaksi pitää sinun jällensä tuleman.
Nínú òógùn ojú rẹ ni ìwọ yóò máa jẹun títí tí ìwọ yóò fi padà sí ilẹ̀, nítorí inú ilẹ̀ ni a ti mú ọ jáde wá; erùpẹ̀ ilẹ̀ sá à ni ìwọ, ìwọ yóò sì padà di erùpẹ̀.”
20 Ja Adam kutsui emäntänsä nimen Heva, että hän on kaikkein elävitten äiti.
Adamu sì sọ aya rẹ̀ ní Efa nítorí òun ni yóò di ìyá gbogbo alààyè.
21 Ja Herra Jumala teki Adamille ja hänen emännällensä nahoista hameet, ja puetti heidän yllensä.
Olúwa Ọlọ́run, sì dá ẹ̀wù awọ fún Adamu àti aya rẹ̀, ó sì fi wọ̀ wọ́n.
22 Ja Herra Jumala sanoi: katso, Adam on ollut niin kuin yksi meistä, tietäen hyvän ja pahan; mutta nyt ettei hän ojentaisi kättänsä, ja ottaisi myös elämän puusta, söisi ja eläisi ijankaikkisesti:
Olúwa Ọlọ́run sì wí pé, “Ọkùnrin náà ti dàbí ọ̀kan lára wa, ó mọ rere àti búburú. A kò gbọdọ̀ jẹ́ kí ó na ọwọ́ rẹ̀ kí ó mú lára èso igi ìyè kí ó sì jẹ, kí ó sì wà láààyè títí láéláé.”
23 Niin Herra Jumala johdatti hänen ulos Edenin Paradisista maata viljelemään, josta hän otettu oli.
Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run lé e kúrò nínú ọgbà Edeni láti lọ máa ro ilẹ̀ nínú èyí tí a ti mú un jáde wá.
24 Ja ajoi Adamin ulos, ja pani idän puolelle Edenin Paradisia Kerubimin paljaalla, lyöväisellä miekalla elämän puun tietä vartioitsemaan.
Lẹ́yìn tí ó ti lé ènìyàn jáde tán, ó fi àwọn kérúbù àti idà iná tí ó ń kọ mọ̀nàmọ́ná síwájú àti sẹ́yìn láti ṣọ́ ọ̀nà tí ó lọ sí ibi igi ìyè, ní ìhà ìlà-oòrùn ọgbà Edeni.

< 1 Mooseksen 3 >