< 1 Mooseksen 14 >
1 Ja tapahtui Amraphelin Sinearin kuninkaan, Ariokin Elassarin kuninkaan, Kedorlaomerin Elamin kuninkaan, ja Tidealin pakanoitten kuninkaan aikana:
Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
2 Että he sotivat Bereaa Sodoman kuningasta, ja Birsaa Gomorran kuningasta, ja Sineabia Adaman kuningasta, ja Semeberiä Zeboimin kuningasta, ja Belan, se on Zoarin, kuningasta vastaan.
jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
3 Nämät kaikki tulivat yhteen Siddimin laaksossa; se on suolainen meri:
Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
4 Sillä he olivat olleet kaksitoistakymmentä ajastaikaa kuningas Kedorlaomerin alla; mutta kolmantenatoistakymmenentenä ajastaikana olivat he hänestä luopuneet.
Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
5 Neljäntenätoistakymmenentenä ajastaikana tuli Kedorlaomer, ja ne kuninkaat, kuin hänen kanssansa olivat, ja löivät ne Kalevan pojat Karnaimin Astarotissa, ja Susimin Hammissa; niin myös Emimin Sjaven Kirjataimissa:
Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
6 Ja Horilaiset Seirin vuorella; siihen lakiaan paikkaan Pharaniin asti, korpea liki.
àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
7 Ja he palasivat ja tulivat Mispatin lähteen tykö, se on Kades, ja löivät koko Amalekilaisten maan; niin myös Amorilaiset, jotka asuivat Hasesonin Tamarissa.
Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
8 Niin läksivät Sodoman kuningas, ja Gomorran kuningas, ja Adaman kuningas, ja Zeboimin kuningas, ja Belan, se on Zoarin kuningas: ja hankitsivat sotaan heitä vastaan Siddimin laaksossa:
Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
9 Kedorlaomeria Elamin kuningasta, ja Tibealia pakanoitten kuningasta, ja Amraphelia Sinearin kuningasta, ja Ariokia Elassarin kuningasta vastaan: neljä kuningasta viittä vastaan.
láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
10 Ja Siddimin laaksossa oli monta maanpihkakuoppaa. Mutta Sodoman ja Gomorran kuningas siinä pakoon ja maahan lyötiin, ja jääneet pakenivat vuorille.
Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
11 Ja he ottivat kaiken Sodoman ja Gomorran tavaran, ja kaiken heidän elatuksensa, ja menivät matkaansa.
Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
12 Ja ottivat myös Lotin Abramin veljen pojan kanssansa, ja hänen tavaransa, ja menivät matkaansa, sillä hän asui Sodomassa.
Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
13 Silloin tuli yksi joka päässyt oli, ja ilmoitti sen Abramille Hebrealaiselle, joka asui Mamren Amorilaisen lakeudella, joka Eskolin ja Anerin veli oli. Nämät olivat liitossa Abramin kanssa.
Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
14 Koska Abram kuuli veljensä otetuksi kiini, varusti hän omaa kotona syntynyttä palveliaansa kolmesataa ja kahdeksantoistakymmentä, ja ajoi takaa heitä Daniin asti.
Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
15 Jakoi itsensä ja karkasi heidän päällensä yöllä palvelioinensa, ja löi heitä: ja ajoi takaa hamaan Hobaan, joka on vasemmalla puolella Damaskua.
Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
16 Ja toi jällensä kaiken tavaran: ja myös veljensä Lotin ja hänen tavaransa toi hän jällensä, niin myös vaimot ja väen.
Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
17 Silloin meni Sodoman kuningas häntä vastaan, koska hän palasi lyömästä Kedorlaomeria, ja niitä kuninkaita hänen kanssansa: Sjaven lakeudella, joka kuninkaan laaksoksi kutsutaan.
Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
18 Mutta Melkisedek Salemin kuningas toi leivän ja viinan: ja hän oli ylimmäisen Jumalan pappi.
Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
19 Ja siunasi häntä, ja sanoi: siunattu ole sinä Abram sille kaikkein korkeimmalle Jumalalle, jonka taivas ja maa oma on.
Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
20 Ja kiitetty olkoon kaikkein korkein Jumala, joka sinun vihollises antoi sinun käsiis. Ja (Abram) antoi hänelle kymmenykset kaikista.
Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
21 Silloin Sodoman kuningas sanoi Abramille: anna minulle väki, ja pidä itse tavara.
Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
22 Ja Abram sanoi Sodoman kuninkaalle: Minä nostan minun käteni Herran kaikkein korkeimman Jumalan tykö, jonka taivas ja maa oma on:
Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
23 Etten minä ota kaikesta sinun omastas lankaakaan eli kengän rihmaa, ettes sanoisi: minä olen Abramin äveriääksi tehnyt:
pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
24 Ei suinkaan, paitsi sitä kuin nämät nuoret miehet syöneet ovat; ja niiden miesten osan, jotka minua seurasivat: Aner, Eskol ja Mamre, he saakoon osansa.
Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”