< Hesekielin 37 >

1 Ja Herran käsi rupesi minuun, ja Herra vei minun hengessä ja asetti minun lakialle kedolle, joka oli luita täynnä.
Ọwọ́ Olúwa wà lára mi, ó sì mú mi jáde pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa, ó mú kí ń wà ní àárín àfonífojì; ti o kún fún àwọn egungun.
2 Ja hän johdatti minun niiden kautta aina ympärinsä; ja katso, siinä oli sangen paljo luita kedolla, ja katso, ne olivat peräti kuivettuneet.
Ó mú mi lọ síwájú àti sẹ́yìn láàrín wọn, èmi sì rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn egungun ní orí ilẹ̀ àfonífojì, àwọn egungun tí ó gbẹ gan.
3 Ja hän sanoi minulle: sinä ihmisen poika, luuletkos nämät luut jälleen eläväksi tulevan? Ja minä sanoin: sinä Herra, Herra sen tiedät.
Olúwa sì bi mí léèrè, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ àwọn egungun wọ̀nyí lè yípadà di àwọn ènìyàn bí?” Èmi sì wí pé, “Ìwọ Olúwa Olódùmarè, ìwọ nìkan ni o lè dáhùn sí ìbéèrè yìí.”
4 Ja hän sanoi minulle: ennusta näistä luista, ja sano heille: te kuivettuneet luut, kuulkaat Herran sanaa.
Nígbà náà ni ó wí fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí àwọn egungun kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin egungun gbígbẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
5 Näin sanoo Herra, Herra näistä luista: katso, minä annan tulla teihin hengen, ja teidän pitää eläväksi tuleman.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn egungun wọ̀nyí. Èmi yóò mú kí èémí wọ inú yín ẹ̀yin yóò sì wá di ààyè.
6 Ja annan teille suonet, ja kasvatan lihan teidän päällenne, ja vedän nahan teidän päällenne, ja annan teille hengen, että te jälleen eläväksi tulette; ja teidän pitää tietämän, että minä olen Herra.
Èmi yóò so iṣan ara mọ́ ọn yín, Èmi yóò sì mú kí ẹran-ara wá sí ara yín, Èmi yóò sì fi awọ ara bò yín, Èmi yóò sì fi èémí sínú yín, ẹ̀yin yóò sì wà ní ààyè. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
7 Ja minä ennustin niinkuin minulle käsketty oli. Niin tuli hyso, ne rupesivat liikkumaan, ja luut tulivat jälleen yhteen kukin jäseneensä.
Nítorí náà ni mo ṣe sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti pa á láṣẹ fún mi. Bí mo sì ti ń sọtẹ́lẹ̀, ariwo wá, ìró tí ó kígbe sókè, àwọn egungun sì wà papọ̀, egungun sí egungun.
8 Ja minä näin, ja katso, siihen tulivat suonet ja liha päälle, ja hän peitti ne nahalla; mutta ei niissä vielä henkeä ollut.
Mo wò ó, iṣan ara àti ẹran-ara farahàn lára wọn, awọ ara sì bò wọ́n, ṣùgbọ́n kò sí èémí nínú wọn.
9 Ja hän sanoi minulle: ennusta hengelle, ennusta sinä, ihmisen poika, ja sano hengelle: näin sanoo Herra, Herra: sinä henki, tule tähän neljästä tuulesta, ja puhalla näiden tapettuin päälle, että he jälleen eläväksi tulisivat.
Lẹ́yìn náà ni ó sọ fún mi pé, “Sọtẹ́lẹ̀ sí èémí; sọtẹ́lẹ̀, ọmọ ènìyàn, kí ó sì sọ fún un pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: wá láti atẹ́gùn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, ìwọ èémí, kí ó sì mí èémí sínú àwọn tí a pa wọ̀nyí, kí wọn kí ó lè wà ní ààyè.’”
10 Ja minä ennustin niinkuin hän oli minun käskenyt: niin tuli henki heihin, ja he tulivat eläväksi, ja seisoivat jaloillansa, ja heitä oli sangen suuri joukko.
Nítorí náà, mo sọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹsẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.
11 Ja hän sanoi minulle: sinä ihmisen poika, nämät luut ovat koko Israelin huone; katso, he sanovat: meidän luumme ovat kuivuneet, meidän toivomme on kadonnut, ja me olemme hukkuneet.
Lẹ́yìn náà ó sọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Israẹli. Wọ́n sọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’
12 Sentähden ennusta ja sano heille: näin sanoo Herra, Herra: katso, minä avaan teidän hautanne ja tahdon teitä, minun kansani, sieltä tuoda ulos, ja saatan teitä Israelin maalle.
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò ṣí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Israẹli.
13 Ja teidän pitää tietämän, että minä olen Herra, koska minä olen teidän hautanne avannut, ja teitä, minun kansani, sieltä tuonut ulos.
Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti ṣí ibojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nínú ibojì yín.
14 Ja minä tahdon antaa minun henkeni teihin, että te jälleen virkootte, ja tahdon saattaa teitä teidän maallenne; ja teidän pitää ymmärtämän, että minä olen Herra. Minä sen puhun, ja minä myös sen teen, sanoo Herra.
Èmi yóò fi èémí mi sínú yín, ẹ̀yin yóò sì yè, èmi yóò sì mú kí ẹ fi lélẹ̀ ní ilẹ̀ ẹ̀yin tìkára yín. Nígbà náà ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi sì ti ṣe ni Olúwa wí.’”
15 Ja Herran sana tapahtui minulle ja sanoi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá:
16 Sinä ihmisen poika, ota sinulles yksi puu, ja kirjoita siihen Juudasta ja heidän kumppaneistansa Israelin lapsista; ja ota vielä sitte yksi puu, ja kirjoita siihen Josephin ja Ephraimin suku, ja koko Israelin huone, heidän kumppaninsa.
“Ọmọ ènìyàn, mú igi pátákó kan kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti Juda àti ti Israẹli tí ó ní àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’ Lẹ́yìn náà, kí ó mú igi pátákò mìíràn kí ó sì kọ̀wé sí ara rẹ̀, ‘Tí ó jẹ́ ti tí Josẹfu (tí ó túmọ̀ sí ti Efraimu) àti gbogbo ilé Israẹli tí ó ni àṣepọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.’
17 Ja liitä heitä molempia yhteen, sinulle yhdeksi puuksi, niin että se tulee kaikki yhdeksi kädessäs.
So wọ́n papọ̀ sí ara igi kan nítorí náà wọn yóò di ọ̀kan ní ọwọ́ rẹ.
18 Jos siis sinun kansas lapset puhuvat sinulle, sanoen: etkös tahdo meille ilmoittaa, mitäs sillä ajattelet?
“Nígbà tí àwọn ara ìlú rẹ bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, ‘Ṣé ìwọ kò ní sọ ohun tí èyí túmọ̀ sí fún wa?’
19 Niin sano heille: näin sanoo Herra, Herra: katso, minä otan Josephin puun, joka on Ephraimin tykönä, ynnä heidän kumppaneinsa Israelin sukuin kanssa, ja panen heidät Juudan puun tykö, ja teen heistä molemmista yhden puun minun kädessäni.
Sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gba igi Josẹfu—èyí tí ó wà ní ọwọ́ Efraimu—àti ti ẹ̀yà Israẹli tí ó parapọ̀ mọ́ ọn, kí ó sì só papọ̀ mọ́ igi Juda, láti sọ wọ́n di igi kan ṣoṣo, wọn yóò sì di ọ̀kan ní ọwọ́ mi.’
20 Ja sinun pitää ne puut, joihin sinä kirjoittanut olet, sinun kädessäs niin pitämän, että he sen näkevät.
Gbé igi pátákó tí ó kọ nǹkan sí i sókè ní iwájú wọn,
21 Ja sinun pitää heille sanoman: näin sanoo Herra, Herra: katso, minä tuon jälleen Israelin lapset pakanoista, joihin he menneet ovat, ja kokoon heidät joka paikasta, ja annan heidän tulla maallensa jälleen.
kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Israẹli jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti lọ. Èmi yóò ṣà wọ́n jọ pọ̀ láti gbogbo agbègbè, èmi yóò sì mú wọn padà sí ilẹ̀ ara wọn.
22 Ja teen kaikki yhdeksi kansaksi mmaalla, Israelin vuorilla; ja heillä kaikilla pitää oleman yksi kuningas, ja ei pidä enään kaksi kansaa eli kahteen valtakuntaan jaetut oleman.
Èmi yóò ṣe wọ́n ní orílẹ̀-èdè kan ní ilẹ̀ náà, ní orí òkè Israẹli, ọba kan ni yóò wà lórí gbogbo wọn, wọn kì yóò sì jẹ́ orílẹ̀-èdè méjì mọ́, tàbí kí a pín wọn sí ìjọba méjì.
23 Ei heidän myös pidä enään saastuttaman itsiänsä epäjumalistansa, kauhistuksissa ja kaikkinaisissa rikoksissa. Minä autan heitä kaikista paikoista, joissa he ovat rikkoneet, ja puhdistan heitä, ja heidän pitää oleman minun kanssani, ja minä tahdon olla heidän Jumalansa.
Wọn kì yóò sì tún fi àwọn òrìṣà wọn ba ara wọn jẹ́ mọ́, tàbí ohun ìríra wọn, tàbí ohun ìrékọjá wọn: ṣùgbọ́n èmi yóò gbà wọn là kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àgàbàgebè wọn, èmi yóò sì wẹ̀ wọn mọ́. Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
24 Ja minun palvelijani David pitää oleman heidän kuninkaansa, ja kaikkein heidän yksinäinen paimenensa; ja heidän pitää vaeltaman minun oikeudessani, ja pitämän minun säätyni, ja tekemän niiden jälkeen.
“‘Dafidi ìránṣẹ́ mi ni yóò jẹ ọba lórí wọn, gbogbo wọn yóò sì ní olùṣọ àgùntàn kan. Wọn yóò sì tẹ̀lé òfin mi, wọn yóò sì ṣe àníyàn láti pa àṣẹ mi mọ́.
25 Ja heidän pitää asuman sillä maalla, jonka minä palvelialleni Jakobille antanut olen, jossa teidän isänne asuneet ovat; heidän ja heidän lapsensa ja lastensa lapset pitää siellä ijankaikkisesti asuman; ja minun palvelijani David pitää oleman heidän ruhtinaansa ijankaikkisesti.
Wọn yóò gbé ní ilẹ̀ tí mo fún Jakọbu ìránṣẹ́ mi, ilẹ̀ tí àwọn baba yín ń gbé. Àwọn àti àwọn ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn ni yóò máa gbé ibẹ̀ láéláé, ìránṣẹ́ mi Dafidi ni yóò jẹ́ Ọmọ-aládé wọn láéláé.
26 Ja minä teen heidän kanssansa rauhan liiton, sen pitää heille ijankaikkisen liiton oleman; ja holhon heitä, ja enennän heitä, ja minun pyhäni pitää oleman heidän seassansa ijankaikkisesti.
Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, yóò sì jẹ́ májẹ̀mú títí ayérayé. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀, èmi yóò sì sọ wọ́n di púpọ̀ ní iye, èmi yóò sì gbé ilé mímọ́ mi kalẹ̀ ní àárín wọn títí láé.
27 Ja minun majani pitää oleman heidän seassansa, ja minä tahdon olla heidän Jumalansa; ja heidän pitää oleman minun kansani.
Ibùgbé mí yóò wà pẹ̀lú wọn, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.
28 Niin että pakanainkin pitää ymmärtämän, että minä Herra pyhitän Israelin; ja minun Pyhäni pitää oleman heidän tykönänsä ijankaikkisesti.
Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa sọ Israẹli di mímọ́, nígbà tí ibi mímọ́ mi bá wà ní àárín wọn títí ayérayé.’”

< Hesekielin 37 >