< Hesekielin 23 >
1 Ja Herran sana tapahtui minulle ja sanoi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Sinä, ihmisen poika, kaksi vaimoa oli yhden äidin tytärtä:
“Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
3 Nämät tekivät huorin Egyptissä, he tekivät huorin nuoruudessansa; siellä antoivat he pidellä rintojansa, ja taputellla neitsyytensä nisiä.
Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
4 Suuremman nimi oli Ohola, ja hänen sisarensa Oholiba. Ja minä otin heidät aviokseni, ja he synnyttivät poikia ja tyttäriä. Ja Ohola kutsuttiin Samariaksi ja Oholiba Jerusalemiksi.
Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
5 Ohola teki huorin, kuin minä hänen ottanut olin, ja rakasti värtämiehiänsä Assyrialaisia, jotka hänen tykönsä tulivat:
“Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
6 Silkillä vaatetettuja päämiehiä ja esimiehiä, kaikkia nuoria ihanaisia miehiä, hevosmiehiä, jotka hevosilla ajoivat;
Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
7 Ja makasi kaikkein nuorten miesten kanssa Assyriasta, ja saastutti itsensä kaikkiin heidän jumaliinsa, kussa ikänä hän jonkun osasi.
O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
8 Vielä sitte ei hän hyljännyt huoruuttansa Egyptin kanssa; että he hänen kanssansa maanneet olivat hänen nuoruudessansa, ja jotka hänen neitsyytensä nisiä taputtelleet, ja suuressa huoruudessa hänen kanssansa olleet olivat.
kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
9 Sentähden minä hylkäsin hänet värtämiestensä käsiin, Assurin lasten käsiin, joita hän himostansa rakasti.
“Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
10 He paljastivat hänen häpynsä, ja ottivat hänen poikansa ja tyttärensä pois, mutta hänen he miekalla tappoivat. Ja sanoma kuului vaimoin seassa, että tämä rangaistus oli.
Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
11 Mutta kuin Oholiba, hänen sisarensa, sen näki, syttyi se rakkaudesta pahemmin kuin toinen, ja teki enemmin huorin kuin hänen sisarensa huoruus oli.
“Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
12 Ja rakasti Assurin lapsia, päämiehiä ja esimiehiä, jotka hänen tykönsä tulivat kauniisti vaatetettuna, hevosmiehiä, jotka hevosilla ajoivat, kaikkia nuoria ihanaisia miehiä.
Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
13 Silloin minä näin, että he molemmat yhdellä tavalla itsensä saastuttaneet olivat.
Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
14 Mutta tämä teki vielä enemmin huorin; sillä kuin hän näki punaisella maalilla maalatuita miehiä seinissä, Kaldealaisten kuvia,
“Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
15 Kupeista vyötetyitä ja kirjavat lakit heidän päässänsä, jotka kaikki olivat nähdä niinkuin päämiehet, niinkuin Babelin lapset ja Kaldealaiset pitävät isänsä maalla,
pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
16 Syttyi hän heihin niin pian kuin hän näki heidät, ja hän lähetti sanansaattajat heidän tykönsä Kaldeaan.
Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
17 Kuin nyt Babelin lapset hänen tykönsä tulivat, häntä makaaman hekumassansa, saastuttivat he hänen huoruudellansa; ja se saastutti itsensä heidän kanssansa, niin että hän heihin suuttui.
Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
18 Ja kuin hänen huoruutensa ja häpiänsä niin peräti ilmituli, suutuin minä myös häneen, niinkuin minä hänen sisareensa suuttunut olin.
Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
19 Mutta hän teki aina enemmän huorin ja muisti nuoruutensa aikaa, jona hän Egyptissä huorin tehnyt oli.
Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
20 Ja syttyi himoon heidän jalkavaimoinsa kanssa, joiden liha on niinkuin aasien liha, ja heidän himonsa niinkuin hevosten himo.
Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
21 Ja sinä teit häpiäs, niinkuin nuoruudessas, kuin Egyptissä sinun rintaas pideltiin, ja sinun nuoruutes nisiä taputeltiin.
Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
22 Sentähden, Oholiba, näin sanoo Herra, Herra: katso, minä tahdon sinun värtämiehes, joihinkas suuttunut olet, kehoittaa sinua vastaan, ja tahdon heitä tuoda joka taholta sinua vastaan:
“Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
23 Babelin lapset ja kaikki Kaldealaiset, päämiehet, herrat ja valtamiehet, ja kaikki Assyrialaiset heidän kanssansa, kauniit, nuoret miehet, kaikki päämiehet ja esimiehet, valtamiehet, ja ylimmäiset, ja kaikkinaiset hevosmiehet.
àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
24 Ja he tulevat valmistettuna sinun päälles vaunuilla ja rattailla ja suurella väen joukolla, ja piirittävät sinun keihäillä, kilvillä ja rautalakeilla joka taholta. Niiden haltuun minä oikeuden annan, että he sinun tuomitsevat lakinsa jälkeen.
Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
25 Minä annan minun kiivauteni tulla sinun päälles, että he armottomasti sinun kanssas toimittavat; heidän pitää sinun nenäs ja korvas leikkaaman, ja mitä jää, pitää miekalla lankeeman. Heidän pitää sinun poikas ja tyttäres ottaman pois, ja tähteet pitää poltettaman tulella.
Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
26 Heidän pitää sinun vaattees riisuman, ja sinun kaunistukses ottaman pois.
Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
27 Näin minä tahdon sinun haureutes ja sinun huoruutes Egyptin maasta lopettaa, ettes enää silmiäs nosta heidän peräänsä, etkä Egyptiä enää muistaman pidä.
Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
28 Sillä näin sanoo Herra, Herra: katso, minä tahdon sinun niiden haltuun antaa, joita vihaat, ja joihin suuttunut olet.
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
29 Ne pitää sinulle tekemän niinkuin viholliset, ja ottaman kaikki, mitäs koonnut olet, ja sinut alastomaksi ja paljaaksi jättämän, että sinun saastainen häpiäs ilmi tulis sinun haureutes ja huoruutes kanssa.
Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
30 Näitä pitää heidän sinulle tekemän sinun huoruutes tähden, jota sinä pakanain kanssa tehnyt olet, joiden jumalissa sinä itses saastuttanut olet.
Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
31 Sinä olet käynyt sisares tietä, sentähden annan minä myös hänen maljansa sinun kätees.
Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
32 Näin sanoo Herra, Herra: sinun pitää juoman sisares maljan, syvän ja leviän; sinun pitää niin suureksi nauruksi ja pilkaksi tuleman, että se on ylönpalttinen.
“Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
33 Sinun pitää siitä väkevästä juomasta ja vaivasta itses juovuksiin juoman; sillä sinun sisares Samarian malja on vaivan ja hävityksen malja.
Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
34 Sen sinun pitää puhtaaksi juoman, ja lyömän sen kappaleiksi, ja sinun rintas repimän rikki; sillä minä olen sen puhunut, sanoo Herra, Herra.
Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
35 Sentähden näin sanoo Herra, Herra: ettäs minun unhottanut ja minun selkäs taa heittänyt olet, niin kanna nyt sinun haureuttas ja huoruuttas.
“Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
36 Ja Herra sanoi minulle: sinä ihmisen poika, etkö sinä Oholaa ja Oholibaa nuhdella tahdo? näytä heille heidän kauhistuksensa,
Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
37 Kuinka he ovat huoruudessa olleet ja verta vuotaneet, ja avionsa rikkoneet epäjumalainsa kanssa; niin myös lapsensa, jotka he minulle synnyttäneet olivat, polttivat he niille uhriksi.
nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
38 Päällisiksi ovat he sen minulle tehneet, että he ovat silloin minun pyhäni saastuttaneet, ja minun sabbatini rikkoneet.
Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
39 Sillä kuin he lapsensa epäjumalille tappaneet olivat, menivät he sinä päivänä minun pyhääni, sitä saastuttamaan; katso, niin ovat he minun huoneessani tehneet.
Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
40 He ovat myös lähettäneet miesten perään, jotka kaukaisilta mailta tuleman piti; kuin sana oli lähetetty heidän tykönsä, niin katso, he tulivat; ja sinä pesit itse heidän tähtensä, ja voitelit silmäs ja kaunistit sinus kaunistuksella,
“Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
41 Ja istuit kauniilla vuoteella, jonka edessä pöytä oli valmistettu; ja sinä suitsutit ja uhrasit minun öljyni sen päällä.
Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
42 Siellä oli suruttoman kansan ääni; ja paitsi niitä miehiä yhteisestä kansasta, tuotiin myös sinne Sabealaisia korvesta, jotka antoivat renkaita heidän käsiinsä ja kauniita seppeleitä heidän päähänsä.
“Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
43 Mutta minä ajattelin: se on tottunut huoruuteen vanhuudesta, ei se taida lakata huoruudestansa.
Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
44 Sillä hänen tykönsä mennään niikuin huoran tykö; juuri niin mennään Oholan ja Oholiban, hävyttömäin vaimoin tykö.
Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
45 Sentähden hurskaat miehet rankaisevat heitä, niinkuin avionsa rikkojat ja veren vuodattajat rangaistaman pitää; sillä he ovat huorat, ja heidän kätensä on verta täynnä.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
46 Näin sanoo Herra, Herra: vie suuri joukko heidän päällensä, ja anna heitä ryöstöksi ja saaliiksi,
“Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
47 Jotka heidät kivittäisivät ja heidät miekoillansa pistäisivät lävitse, ja heidän poikansa ja tyttärensä surmaisivat, ja heidän huoneensa tulella polttaisivat.
Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
48 Näin minä tahdon huoruuden maalta lopettaa; että kaikki vaimot pitää oppiman, eikä tekemän senkaltaista haureutta.
“Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
49 Ja teidän haureutenne pannaan teidän päällenne, ja teidän pitää epäjumalainne syntiä kantaman, tietääksenne minun olevan Herran, Herran.
Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”