< Hesekielin 22 >

1 Ja Herran sana tapahtui minulle ja sanoi:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Sinä, ihmisen poika, etkös tahdo nuhdella, etkös tahdo nuhdella murhakaupunkia ja hänelle näyttää kaikkia hänen kauhistuksiansa?
“Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
3 Sano: näin sanoo Herra, Herra: o sinä kaupunki, joka omais veren vuodatat, että sinun aikas tulis, ja sinä, joka epäjumalia tykönäs teet, ettäs itses saastuttaisit!
Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
4 Sinä teet itses vikapääksi siihen vereen, jota vuodatat, ja saastutat itses jumalissa, joita teet; näillä sinä joudutat sinun päiväs, ja saatat, että sinun vuotes tuleman pitää; sentähden tahdon minä sinun nauruksi tehdä pakanain seassa, ja saattaa pilkaksi kaikissa maakunnissa.
Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
5 Sekä läsnä että kaukana pitää heidän sinua sylkemän, että sinun häpiällisen sanoman ja suuren vaivan kärsimän pitää.
Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
6 Katso, Israelin päämiehet ovat kukin väkevä sinussa verta vuodattamaan.
“‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
7 Isänsä ja äitinsä he katsovat ylön sinussa: muukalaisille he väkivaltaa ja vääryyttä tekevät; orpoja ja leskiä he sortavat sinussa.
Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
8 Sinä katsot minun pyhyyteni ylön, ja turmelet minun sabbatini.
Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
9 Pettäjät ovat sinussa verta vuodattamaan; he syövät vuorilla, ja tekevät ylöllistä sinussa.
Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
10 He paljastavat isänsä hävyn sinussa, ja vaivaavat saastaisia vaimoja heidän taudissansa,
Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
11 Ja tekevät kauheutta lähimmäisensä vaimon kanssa: he häpäisevät omat miniänsä ilkivaltaisesti, he tekevät väkivaltaa omille sisarillensa, isäinsä tyttärille.
Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
12 He ottavat lahjoja sinussa, verta vuodattaaksensa; sinä otat koron ja voiton, ja ahnehdit lähimmäiseltäs väkivallalla, ja näin unohdat minun, sanoo Herra, Herra.
Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
13 Katso, minä lyön käsiäni yhteen sinun ahneutes tähden, jotas tehnyt olet, ja sen veren tähden, joka sinussa vuodatettu on.
“‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
14 Mutta luuletkos sinun sydämes voivan kärsiä, ja sinun kätes kestää niinä päivinä kuin minä sinulle tekevä olen? Minä Herra olen sen puhunut, minä myös teen sen.
Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
15 Ja tahdon sinun hajoittaa pakanain sekaan ja ajaa sinun maakuntiin, ja tahdon sinun saastaisuutes lopettaa;
Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
16 Niin että sinä pakanain seassa pitää kirottuna pidettämän, ja sinun pitää ymmärtämän minun olevan Herra.
Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
17 Ja Herran sana tapahtui minulle ja sanoi:
Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
18 Sinä, ihmisen poika, Israelin huone on minulle karreksi tullut; kaikki heidän vaskensa, tinansa, rautansa ja lyijynsä on ahjossa hopian karreksi tullut.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
19 Sentähden sanoo Herra, Herra näin: että te kaikki olette karreksi tulleet, sentähden katso, minä kokoon teidät Jerusalemiin.
Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
20 Niinkuin hopia, vaski, rauta, lyijy ja tina ahjoon kootaan, että tuli sen alle puhallettaisiin ja ne sulaisivat: niin tahdon minä vihassani ja hirmuisuudessani koota, panna sisälle ja sulata teitä.
Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
21 Ja minä tahdon koota teidät, ja minun vihani tulen teidän seassanne puhaltaa, että te siellä sulaisitte.
Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
22 Niinkuin hopia ahjossa sulaa, niin teidän pitää myös siinä sulaman; ja teidän pitää ymmärtämän, että minä Herra olen vuodattanut vihani teidän päällenne.
Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
23 Ja Herram sana tapahtui minulle ja sanoi:
Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
24 Sinä, ihmisen poika, sano heille: sinä olet se maa, joka ei ole puhdistettu, niinkuin se, joka ei sadetta saa vihan ajalla.
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
25 Prophetat, jotka siellä ovat, ovat vannoneet heitänsä yhteen, niinkuin kiljuva jalopeura, kuin se saaliin saa; he syövät sieluja, tempaavat tavaran ja rahan, ja tekevät sinne paljon leskiä.
Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
26 Heidän pappinsa rikkovat minun lakini, ja turmelevat minun pyhäni; ei he pidä pyhäin ja saastaisten välillä eroitusta, eikä opeta mikä puhdas ja saastainen on, eikä tottele minun sabbatiani, ja minä saastutetaan heidän seassansa.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
27 Heidän päämiehensä heidän seassansa ovat niinkuin raatelevaiset sudet, verta vuodattamaan ja sieluja surmaamaan ahneutensa tähden.
Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
28 Ja heidän prophetansa sivuvat heitä sekoittamattomalla kalkilla, saarnaavat turhuutta, ja ennustavat heille valheita, ja sanovat: näin sanoo Herra, Herra; vaikka ei Herra sitä puhunut olekaan.
Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
29 Maan kansa tekee väkivaltaa, ja he ryöstävät ryövyydellä ja sortavat köyhän ja raadollisen, ja tekevät muukalaiselle väkivaltaa ja vääryyttä.
Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
30 Minä etsin heidän seassansa sitä miestä, joka aidan panis ja seisois veräjällä minun edessäni, etten minä maata turmelisi; mutta en minä ketään löytänyt.
“Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
31 Sentähden vuodatan minä vihani heidän päällensä, ja hirmuisuuteni tulella minä lopetan heidät, ja annan heidän tiensä heidän päänsä päälle, sanoo Herra, Herra.
Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Hesekielin 22 >