< 2 Mooseksen 31 >

1 Ja Herra puhui Mosekselle, sanoen:
Olúwa wí fún Mose pé,
2 Katso, minä kutsuin nimeltänsä Betsaleelin Urin pojan, Hurin pojanpojan, Juudan suvusta.
“Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
3 Ja täytin hänen Jumalan hengellä: viisaudella ja kaikkinaisella taidolla:
Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
4 Taitoja ylösajattelemaan, ja tekemään kullasta, ja hopiasta, ja vaskesta,
Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
5 Taitavasti leikkaamaan ja sisälle panemaan kivet, ja taitavasti tekemään puusta kaikkinaista työtä.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
6 Ja katso, minä annoin myös hänelle avuksi Oholiabin Ahisamakin pojan, Danin suvusta, ja itsekunkin taitavan sydämeen annoin minä taidon tekemään kaikkia, mitä minä olen sinulle käskenyt:
Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
7 Seurakunnan majan ja liiton arkin, ja armo-istuimen, joka sen päällä on, ja kaikki majan astiat,
“àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
8 Pöydän ja sen astiat, ja puhtaan kynttilänjalan, ja kaikki sen kalut, ja myös savu-alttarin.
tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
9 Polttouhri-alttarin ja kaikki sen kalut, ja myös pesoastian jalkoinensa,
pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
10 Ja virkavaatteet, ja papin Aaronin pyhät vaatteet, ja hänen poikainsa vaatteet, papin virkaan,
àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
11 Voidellusöljyn ja suitsutuksen hajavista kaluista, pyhään: kaiken sen jälkeen, kuin minä olen sinulle käskenyt, pitää heidän tekemän.
òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
12 Ja Herra puhui Mosekselle, sanoen:
Olúwa wí fún Mose pé,
13 Puhu Israelin lapsille, sanoen: teidän pitää kaiketi pitämän minun sabbatini; sillä se on merkki minun välilläni ja teidän, teidän suvuissanne, että te tietäisitte minun olevan Herran, joka teitä pyhitän.
“Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
14 Sentähden pitäkäät sabbati; sillä se on teillä pyhä. Joka sen rikkoo, hänen pitää totisesti kuoleman; sillä kuka ikänänsä silloin työtä tekee, sen sielu pitää hävitettämän kansansa seasta.
“‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
15 Kuusi päivää pitää työtä tehtämän, mutta seitsemäntenä päivänä on sabbatin lepo, pyhä Herralle: kuka ikänänsä työtä tekee sabbatin päivänä, hänen pitää totisesti kuoleman.
Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
16 Sentähden pitäkään Israelin lapset sabbatin, että he sen pyhittäisivät, sukukunnissansa ijankaikkiseksi liitoksi.
Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
17 Minun ja Israelin lasten välillä on se ijankaikkinen merkki; sillä kuutena päivänä teki Herra taivaan ja maan, mutta seitsemäntenä päivänä hän lepäsi, ja virvoitti itsensä.
Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
18 Ja sitte kuin Herra oli lopettanut puheensa Moseksen kanssa Sinain vuorella, antoi hän hänelle kaksi todistuksen taulua, jotka olivat kivestä, Jumalan sormella kirjoitetut.
Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.

< 2 Mooseksen 31 >