< 5 Mooseksen 32 >
1 Kuulkaat te taivaat, minä puhun, ja maa kuulkaan minun suuni sanoja.
Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
2 Minun oppini tiukkukaan niinkuin sade, minun puheeni vuotakaan niinkuin kaste, niinkuin sade vihannon päälle ja niinkuin pisarat ruohon päälle.
Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
3 Sillä minä ylistän Herran nimeä: antakaat meidän Jumalallemme suuri kunnia.
Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
4 Hän on kallio, hänen työnsä ovat laittamattomat, sillä kaikki hänen tiensä ovat oikiat; vakaa on Jumala, ilman kaikkea vääryyttä, hän on vanhurskas ja oikia.
Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
5 Onko hän hänen turmellut? Ei, vaan hänen lapsensa ovat heidän häpiäpilkkunsa; se on nurja ja sekaseurainen suku.
Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
6 Niinköstä te Herralle maksatte, hullu ja tyhmä kansa? Eikö hän ole sinun Isäs ja sinun Lunastajas, joka sinun luonut ja valmistanut on?
Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
7 Muista muinaisia aikoja, ymmärrä vuosikaudet suvusta sukuun; kysy isältäs, ja hän ilmoittaa sinulle, ja vanhimmiltas, niin he sinulle sanovat.
Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
8 Kuin kaikkein korkein jakoi pakanat ja hajoitti ihmisten lapset, silloin hän laski kansain maan rajat, Israelin lasten luvun jälkeen.
Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
9 Sillä Herran osa on hänen oma kansansa, Jakob on hänen perimisensä nuora.
Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
10 Hän löysi hänen erämaassa ja hirmuisessa suuressa itkukorvessa. Hän vei hänen ympäri, hän opetti hänen ymmärtämään ja varjeli häntä niinkuin silmäteräänsä,
Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
11 Niinkuin kotka kehoittelee pesäänsä ja laukuilee poikainsa päällä, levittää siipensä, ottaa kunkin heistä ja kantaa siipeinsä päällä,
Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
12 Niin Herra yksinänsä talutti häntä, ja ei ollut hänen kanssansa muuta Jumalaa.
Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
13 Hän vei hänen hamaan maan korkeuteen, ja ruokki hänen pellon hedelmällä, ja antoi hänen imeä hunajaa kalliosta ja öljyä kovasta kivestä,
Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
14 Voita lehmistä, ja rieskaa lampaista, ynnä karitsain lihavuuden kanssa, ja Basanin oinaat, ja lihavat kauriit, ja parhaan nisun, ja juotti hänen parhaalla viinamarjan verellä.
Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
15 Ja Israel lihoi, tuli vikuriksi, lihavaksi, paksuksi ja väkeväksi, ja hylkäsi Jumalan, joka hänen teki, ja katsoi autuutensa kallion ylön.
Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
16 He yllyttivät hänen kiivauteen muukalaisten kautta, kauhistusten kautta vihoittivat he hänen.
Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
17 He uhrasivat perkeleille, eikä Jumalalle, jumalille, joita ei he tunteneet, vasta-uutisille, jotka ei ennen olleet, joita isänne ei peljänneet.
Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
18 Kallion, joka sinun siitti, sinä hyljäsit, ja unhotit Jumalan, joka sinun loi.
Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
19 Ja Herra näki sen, ja vihastui, poikainsa ja tyttäriensä kehoituksen tähden,
Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
20 Ja sanoi: minä peitän kasvoni heidän edestänsä, ja katson mitä heidän viimeiseltä tapahtuu; sillä se on nurja suku ja senkaltaiset lapset, joissa ei ole uskoa.
Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
21 He härsyttelivät minua sen kautta, joka ei ole jumala, epäjumaluutensa kautta ovat he minun vihoittaneet ja minä vihoitan heitä jälleen sen kautta, joka ei ole kansa, tyhmällä kansalla minä heitä vihoitan.
Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
22 Sillä tuli on syttynyt minun vihassani, ja polttaa hamaan alimaiseen helvettiin, ja kuluttaa maan, ynnä hänen hedelmänsä kanssa, ja polttaa vuorten perustukset. (Sheol )
Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol )
23 Minä kokoon kaiken onnettomuuden heidän päällensä, minä ammun kaikki nuoleni heihin.
“Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
24 Nälästä heidän pitää hiukahtuman ja poltetaudilla kulutettaman, ja äkillisellä kuolemalla; minä lähetän metsän petoin hampaat heidän keskellensä, ja kyykärmeen myrkyn.
Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
25 Ulkona pitää miekan heitä hävittämän ja sisällä huoneessa pelvon, sekä nuorukaiset että neitseet, imeväiset ja harmaapäät.
Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
26 Minä sanoin: minä hävittäisin heitä, minä lakkauttaisin heidän muistonsa ihmisistä,
Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
27 Ellen minä vihollisteni vihaa karttaisi, ettei heidän vainollisensa ylpeilisi, ja lähes sanoisi: meidän oikia kätemme on kaikki nämät tehnyt, eikä Herra.
nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
28 Sillä se on kansa, jossa ei mitään neuvoa ole, eikä ymmärrystä.
Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
29 Jospa he taitavaiset olisivat, niin he ymmärtäisivät ja huomaitsisivat, mitä heille viimeiseltä tapahtuu.
Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
30 Kuinka yksi ajais tuhatta takaa ja kaksi karkottaisi kymmenentuhatta heistä? Eikö sentähden, että heidän kallionsa on heidät myynyt? ja Herra on heidät sulkenut?
Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
31 Sillä ei ole meidän kalliomme niinkuin heidän kallionsa, ja meidän vihollisemme ovat meidän tuomarimme.
Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
32 Sillä heidän viinapuunsa on Sodoman viinapuusta ja Gomorran pelloista, heidän viinamarjansa myrkylliset viinamarjat, heillä ovat karvahimmat marjat.
Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
33 Heidän viinansa on lohikärmeen kiukkuvahto, ja kyykärmetten hirmullinen myrkky.
Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
34 Eikö se liene kätketty minun tykönäni? ja sinetillä lukittu minun tavaroissani?
“Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
35 Minun on kosto, minä kostan, heidän jalkansa pitää ajallansa kompastuman; sillä heidän kadotuksensa aika on läsnä, ja mikä heille tarjontelee, se rientää.
Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
36 Sillä Herra tuomitsee kansansa, ja armahtaa palveliaansa; sillä hän näkee, että käsi on poissa, ja ei ole mitään tallella pidetty eikä jätetty.
Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
37 Ja pitää sanottaman: kussa heidän Jumalansa ovat? heidän kallionsa, johonka he uskalsivat?
Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
38 Joiden lihavimmat uhrit he söivät, ja joivat viinan heidän juomauhristansa, nouskaan ne ja auttakaan teitä ja varjelkaan teitä.
ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
39 Nähkäät nyt, että minä itse olen, ja ei ole jumalia minun kanssani. Minä kuoletan ja teen eläväksi, minä lyön ja minä parannan, ja ei kenkään ole, joka minun käsistäni vapahtaa.
“Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
40 Sillä minä nostan käteni taivaasen ja sanon: minä elän ijankaikkisesti.
Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
41 Kuin minä hion miekkani niinkuin pitkäisen leimauksen, ja minun käteni rupee rangaistukseen, niin minä koston maksan minun vihollisilleni, ja niille palkitsen, jotka minua vihaavat.
nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
42 Minä juotan nuoleni verellä, ja miekkani pitää lihaa syömän tapettuiden verestä, ja vangittuiden ja vihollisten paljastetusta päästä.
Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
43 Riemuitkaat te kaikki, jotka olette hänen kansansa; sillä hän kostaa palveliainsa veren. Ja kostaa vihollisillensa, ja sovittaa maansa ja kansansa.
Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
44 Ja Moses tuli ja puhui kaikki nämät veisun sanat tämän kansan kuullen, hän ja Josua Nunin poika.
Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
45 Ja Moses päätti kaikki nämät sanat koko Israelille,
Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
46 Ja sanoi heille: pankaat sydämeenne kaikki ne sanat, jotka minä teille tänäpänä todistin, että te käskisitte teidän lapsianne, tekemään ja pitämään kaikki tämän lain sanat.
Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
47 Sillä ei siinä ole teille yhtään turhaa sanaa, vaan se on teidän elämänne; ja ne sanat pitentävät teidän ikänne maan päällä, johon te menette Jordanin ylitse, omistamaan sitä.
Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
48 Ja Herra puhui Mosekselle sinä päivänä, ja sanoi:
Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
49 Mene tälle Abarimin vuorelle, Nebon vuorelle, joka on Moabin maalla Jerihon kohdalla, ja katsele Kanaanin maata, jonka minä Israelin lapsille omaksi annan.
“Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
50 Sinun pitää kuoleman vuorella, johonkas menet, ja koottaman kansas tykö, niinkuin veljeskin Aaron kuoli Horin vuorella, ja koottiin kansan tykö,
Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
51 Että te olette rikkoneet minua vastaan Israelin lasten seassa, riitaveden tykönä Kadeksessa Sinin korvessa: ettette minua pyhittäneet Israelin lasten seassa.
Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
52 Sillä sinä näet maan kohdastansa; vaan ei sinun pidä siihen maahan tuleman, jonka minä Israelin lapsille annan.
Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”