< 5 Mooseksen 26 >

1 Kuin tulet siihen maahan jonka Herra sinun Jumalas sinulle perinnöksi antaa, ja sinä sen omistat, ja asut siinä,
Nígbà tí ìwọ bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìní tí ìwọ sì ti jogún, tí ìwọ sì ti ń gbé níbẹ̀,
2 Niin ota kaikkinaisista sinun maas kasvuista ensimäiset hedelmät, jotka maasta kasvavat, jotka Herra sinun Jumalas sinulle antaa, pane ne koriin, ja mene siihen siaan, jonka Herra sinun Jumalas valitsee nimensä asumasiaksi,
mú díẹ̀ nínú ohun tí o pèsè láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ, kó wọn sínú agbọ̀n. Nígbà náà kí o lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibi tí orúkọ rẹ̀ yóò máa gbé.
3 Ja mene papin tykö, joka siihen aikaan on, ja sano hänelle: minä tunnustan tänäpänä Herran sinun Jumalas edessä, että minä olen tullut siihen maahan, jonka Herra meidän isillemme vannoi, meille antaaksensa.
Kí o sì sọ fun àlùfáà tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní àsìkò náà, pé, “Mo sọ ọ́ di mí mọ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé mo ti wá sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba wa.”
4 Ja pappi ottakoon korin kädestäs ja laskekaan sen maahan, Herran sinun Jumalas alttarin eteen.
Àlùfáà yóò gbé agbọ̀n náà kúrò ní ọwọ́ rẹ, yóò sì gbé e kalẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ.
5 Niin lausu sinä, ja sano Herran sinun Jumalas edessä: minun raadollinen isäni oli Syrialainen, ja meni Egyptiin vähällä joukolla, ja oli siellä muukalainen, ja hän tuli siellä suureksi, väkeväksi ja monilukuiseksi kansaksi.
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní iwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Baba mi jẹ́ alárìnkiri ará Aramu, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti pẹ̀lú ènìyàn díẹ̀, ó sì ń gbé níbẹ̀, ó sì wá di orílẹ̀-èdè olókìkí, alágbára, tí ó kún fún ọ̀pọ̀ ènìyàn.
6 Mutta Egyptiläiset ahdistivat ja vaivasivat meitä, ja panivat kovan orjuuden meidän päällemme.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti ṣe àìdára sí wa, wọ́n jẹ wá ní yà, wọ́n fún wa ní iṣẹ́ líle ṣe.
7 Niin me huusimme Herran meidän isäimme Jumalan tykö, ja Herra kuuli meidän äänemme, ja katsoi meidän tuskaamme, työtämme ja ahdistustamme.
Nígbà náà ni a kégbe pe Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wa, Olúwa sì gbọ́ ohùn wa, ó sì rí ìrora, làálàá àti ìnira wa.
8 Ja Herra vei meidät ulos Egyptistä voimallisella kädellä, ja ojennetulla käsivarrella, suurella peljästyksellä, merkeillä ja ihmeillä.
Nígbà náà ni Olúwa mú wa jáde wá láti Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà, pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá àti iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu.
9 Ja johdatti meidät tähän paikkaan ja antoi meille tämän maan, maan, joka rieskaa ja hunajaa vuotaa.
Ó mú wa wá síbí, ó sì fún wa ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin;
10 Ja nyt katso, minä kannan tässä maan ensimäisiä hedelmiä, jonka sinä Herra minulle annoit. Ja niin pane ne Herran sinun Jumalas eteen, ja kumarra Herran sinun Jumalas edessä,
àti pé ní báyìí, mo mú àkọ́so ilẹ̀ tí ìwọ Olúwa ti fún mi wá.” Ìwọ yóò gbé agbọ̀n náà síwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì wólẹ̀ níwájú u rẹ̀.
11 Ja ole iloinen kaikesta hyvyydestä, minkä Herra sinun Jumalas sinulle antoi, ja sinun huoneelles: sinä ja Leviläinen ja muukalainen, joka sinun keskelläs on.
Ìwọ àti àwọn ọmọ Lefi àti àjèjì láàrín yín yóò máa yọ̀ nínú gbogbo oore tí Olúwa ti fi fún ọ àti fún àwọn ará ilé rẹ.
12 Kuin olet koonnut kaikki kymmenykset sinun vuotes kasvusta kolmantena vuonna, joka on kymmenysten vuosi, niin anna Leviläisille, muukalaisille, orvoille ja leskille, että he söisivät sinun porteissas ja ravittaisiin,
Nígbà tí ìwọ bá ṣetán láti ya ìdámẹ́wàá gbogbo ohun tí o ti mú jáde ní ọdún kẹta sọ́tọ̀ sí apá kan. Ọdún ìdámẹ́wàá, ìwọ yóò fi fún ọmọ Lefi, àjèjì, aláìní baba àti opó, kí wọn kí ó lè jẹ ní àwọn ìlú rẹ, kí wọn sì yó.
13 Ja sano Herran sinun Jumalas edessä: minä olen tuonut huoneestani sen, mikä pyhitetty on, ja annoin Leviläisille, muukalaisille, orvoille ja leskille, kaiken sinun käskys jälkeen jonka olet minulle käskenyt: en minä harhaillut sinun käskyistäs, enkä niitä unhottanut.
Nígbà náà ní kí o wí fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Èmi ti mú ohun mímọ́ kúrò nínú ilé mi, èmi sì ti fi fún àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ohun gbogbo tí ìwọ ti pàṣẹ. Èmi kò yípadà kúrò nínú àṣẹ rẹ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbàgbé ọ̀kankan nínú wọn.
14 En minä siitä ole syönyt minun surussani, enkä ottanut siitä saastaisuudesta, en myös niistä mitään antanut kuolleille: minä olen ollut Herran minun Jumalani äänelle kuuliainen, ja tehnyt kaiken sen jälkeen, minkä sinä minulle käskenyt olet.
Èmi kò jẹ lára ohun mímọ́ ní ìgbà tí mo ń ṣọ̀fọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu nínú wọn ní ìgbà tí mo wà ní àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi nínú wọn fún òkú. Èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run mi, èmi sì ti ṣe gbogbo ohun tí ó pàṣẹ fún mi.
15 Katsahda tänne pyhästä asumasiastas taivaasta, ja siunaa sinun kansaas Israelia ja maata, jonka sinä meille antanut olet, niinkuin sinä vannoit isillemme, maata, joka rieskaa ja hunajaa vuotaa.
Wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, ibùgbé mímọ́ rẹ, kí o sì bùkún fún àwọn ènìyàn Israẹli, àti fún ilẹ̀ náà tí ìwọ ti fi fún wa, bí ìwọ ti búra fún àwọn baba ńlá wa, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin.”
16 Tänäpänä Herra sinun Jumalas käskee sinua tekemään näiden säätyin ja oikeutten jälkeen, niin ettäs pidät ne ja teet niiden jälkeen kaikesta sydämestäs ja kaikesta sielustas.
Olúwa Ọlọ́run rẹ pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa tẹ̀lé àwọn ìlànà àti òfin, kí o sì máa ṣe wọ́n pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo àyà rẹ.
17 Herran edessä olet sinä sen luvannut tänäpänä, että hän pitää oleman sinun Jumalas, ja sinä tahdot vaeltaa hänen teissänsä, ja pitää hänen säätynsä, käskynsä ja oikeutensa, ja olla kuuliainen hänen äänellensä.
Ìwọ jẹ́wọ́ Olúwa ní òní pé Olúwa ni Ọlọ́run rẹ, àti pé ìwọ yóò máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, àti pé ìwọ yóò máa pa ìlànà rẹ̀, àṣẹ rẹ̀ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti pé ìwọ yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i.
18 Ja Herra on sinulle tänäpänä luvannut, että sinun pitää oleman hänen kansansa, niinkuin hän sinulle on puhunut, että sinun pitää kaikki hänen käskynsä pitämän.
Ní òní ni Olúwa jẹ́wọ́ rẹ pé ìwọ ni ènìyàn òun, ilé ìṣúra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí, àti pé ìwọ yóò máa pa gbogbo àṣẹ rẹ̀ mọ́.
19 Ja hän korottaa sinua kaikkein kansain ylitse, minkä hän tekee ylistykseksi, kiitokseksi ja kunniaksi, ettäs olisit Herralle sinun Jumalalles pyhä kansa, niinkuin hän sanonut on.
Òun sì jẹ́wọ́ pé, òun yóò gbé ọ sókè ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí òun ti dá lọ, ní ìyìn, ní òkìkí àti ní ọlá; kí ìwọ kí ó le jẹ́ ènìyàn mímọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí.

< 5 Mooseksen 26 >