< 5 Mooseksen 21 >

1 Jos joku tapettu löydetään siinä maassa, jonka Herra sinun Jumalas sinun omakses antaa, ja se makaa kedolla, ja tietämätöintä on, kuka hänen tappoi;
Tí a bá rí ọkùnrin tí a pa, ní ìdùbúlẹ̀ ní pápá nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ láti jogún, tí a kò sì mọ ẹni tí ó pa á,
2 Niin käykään ulos vanhimpas ja tuomaris, ja mitatkaan sen tapetun tyköä kaupunkeihin, jotka tapetun ympärillä ovat.
àwọn àgbàgbà yín yóò jáde lọ láti wọn jíjìnnà ibi òkú sí ìlú tí ó wà nítòsí.
3 Joka kaupunki tapettua lähin on, sen vahimmat ottakaan nuoren lehmän karjasta, jolla ei ole työtä tehty ja joka ei ikeen alla ole ollut,
Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí òkú yóò mú ẹgbọrọ abo màlúù tí kò ì ṣiṣẹ́ rí àti tí kò sì fà nínú àjàgà rí,
4 Ja kaupungin vanhimmat taluttakaan nuoren lehmän kovaan laaksoon, jota ei kynnetä eikä kylvetä, ja leikatkaan lehmän kaulan siinä laaksossa.
kí àwọn àgbàgbà ìlú náà kí wọn mú ẹgbọrọ abo màlúù náà sọ̀kalẹ̀ wá sí àfonífojì tí ó ní omi ṣíṣàn kan, tí a kò ro, tí a kò sì gbìn, kí wọn kí ó sì ṣẹ́ ọrùn ẹgbọrọ màlúù náà níbẹ̀ ní àfonífojì náà.
5 Niin pitää papit, Levin pojat käymän edes; sillä Herra sinun Jumalas on heidät valinnut palvelemaan itseänsä, ja Herran nimeä ylistämään: ja heidän suunsa jälkeen pitää kaikki riidat ja kaikki vahingot selitettämän.
Àwọn àlùfáà, ọmọ Lefi yóò wá síwájú, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún un àti láti bùkún ní orúkọ Olúwa àti láti parí gbogbo ẹjọ́ àríyànjiyàn àti ọ̀rọ̀ ìlú.
6 Ja kaikki vanhimmat siitä kaupungista, joka tapettua lähinnä on, peskään kätensä nuoren lehmän päällä, jonka kaula laaksossa leikattiin,
Nígbà náà ni gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí yóò wẹ ọwọ́ wọn lórí ẹgbọrọ abo màlúù tí a ti kan ọrùn rẹ̀ ní àfonífojì,
7 Ja he vastatkaan ja sanokaan: ei meidän kätemme tätä verta vuodattaneet, eikä meidän silmämme sitä nähneet.
wọn yóò sì sọ pé, “Ọwọ́ wa kò ta ẹ̀jẹ̀ yìí sílẹ̀, tàbí kí ojú wa rí i ní títa sílẹ̀.”
8 Ole armollinen kansalles Israelille, jonka sinä Herra pelastit, ja älä tätä viatointa verta anna tulla kansas Israelin päälle; ja niin he ovat sovitetut siitä verestä.
Dáríjì, Olúwa, àwọn ènìyàn rẹ ni Israẹli, tí ìwọ ti dá sílẹ̀, àti kí ìwọ má ṣe gba ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ní àárín àwọn ènìyàn rẹ ní Israẹli. Ṣùgbọ́n kí a dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì.
9 Ja niin sinä eroitat tyköäs viattoman veren, ettäs teet sen mikä oikia on Herran silmän edessä.
Nígbà náà ni ìwọ wẹ̀ kúrò láàrín rẹ ẹ̀bi títa ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí o ti ṣe èyí tí ó tọ́ níwájú Olúwa.
10 Kuin menet sotaan vihollisias vastaan, ja Herra sinun Jumalas antaa heidät sinun käsiis, ja sinä viet heitä vankina pois.
Nígbà tí o bá lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá rẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ tí o sì mú àwọn ìgbèkùn,
11 Ja näet vankein seassa kauniin vaimon, ja himoitset häntä ottaa emännäkses:
tí o sì rí obìnrin tí ó dára lára àwọn ìgbèkùn, tí o sì ní ìfẹ́ sí i, o lè mu u gẹ́gẹ́ bí aya à rẹ.
12 Niin vie häntä huoneeses ja anna hänen keritä hiuksensa ja leikata kyntensä,
Mú u wá sí ilé e rẹ kí o sì jẹ́ kí ó fá irun orí rẹ̀, gé èékánná an rẹ̀,
13 Ja riisua vaatteensa, joissa hän vangittiin, ja anna hänen istua huoneessas, ja itkeä kuukauden isänsä ja äitiänsä: mene sitte hänen tykönsä ja ole hänen miehensä, ja hän olkoon sinun emäntäs.
kí o sì mú aṣọ tí ó wọ̀ nígbà tí ó di ìgbèkùn sí ẹ̀gbẹ́ kan. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ń gbé ilé rẹ tí ó sì ti ṣọ̀fọ̀ baba àti ìyá rẹ̀ fún odidi oṣù kan, nígbà náà ni o lè tọ̀ ọ́ lọ kí o sì ṣe ọkọ rẹ̀ kí ó jẹ́ aya rẹ.
14 Ja jos tapahtuu, ettei hän sinulle kelpaa, niin anna hänen mennä kuhunka hän tahtoo, ja älä suinkaan myy häntä rahaan: älä myös pyydä itselles jotakin voittoa hänen kauttansa; sillä sinä alensit hänen.
Bí inú rẹ̀ kò bá sì dùn sí i, jẹ́ kí ó lọ sí ibikíbi tí ó bá fẹ́. O kò gbọdọ̀ tà á tàbí lò ó bí ẹrú, lẹ́yìn ìgbà tí o ti dójútì í.
15 Jos jollakin miehellä on kaksi emäntää, yksi, jota hän rakastaa, ja toinen, jota hän vihaa, ja ne synnyttävät hänelle lapsia, sekä se jota hän rakastaa, että se jota hän vihaa, niin että esikoinen on sen, jota hän vihaa;
Bí ọkùnrin kan bá ní ìyàwó méjì, tí ó sì fẹ́ ọ̀kan ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ èkejì, tí àwọn méjèèjì sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un ṣùgbọ́n tí àkọ́bí jẹ́ ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn.
16 Ja aika tulee, että hän lastensa välillä perimisen jakaa, niin ei hän taida tehdä rakkaamman poikaa esikoiseksensa vihattavan esikoisen edestä;
Nígbà tí ó bá ń pín ohun ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kò gbọdọ̀ fi ẹ̀tọ́ àkọ́bí fún ọmọ ìyàwó tí kò fẹ́ràn.
17 Vaan hänen pitää tunteman vihattavan pojan esikoiseksensa, niin että hän antaa hänelle kaksinkertaisesti kaikista niistä, mitä häneltä löydetään; sillä se on hänen ensimäinen voimansa, ja hänelle tulee esikoisen oikeus.
Ó ní láti fi ipò ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn fun un gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí i rẹ̀ nípa fífún un ní ìlọ́po ìpín gbogbo ohun tí ó ní. Ọmọ yẹn ni àmì àkọ́kọ́ agbára baba rẹ̀. Ẹ̀tọ́ àkọ́bí jẹ́ tirẹ̀.
18 Jos jollakin on itsevaltainen ja kovakorvainen poika, joka ei kuule isänsä ja äitinsä ääntä, ja kuin he kurittavat häntä, ei heitä tottele;
Bí ọkùnrin kan bá ní aláìgbọ́ràn tàbí ọlọ̀tẹ̀ ọmọ tí kò gbọ́rọ̀ sí baba àti ìyá rẹ̀ tí kò sì ní í gbà tí wọ́n bá ń bá a wí,
19 Niin pitää hänen isänsä ja äitinsä hänen ottaman kiinni, ja viemän kaupunkinsa vanhimpain ja portin eteen,
baba àti ìyá rẹ̀ yóò gbá a mú, wọn yóò mu wá fún àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú u rẹ̀.
20 Ja sanokaan kaupunkinsa vanhimmille: tämä meidän poikamme on itsevaltainen ja kovakorvainen, ei tottele meidän ääntämme, ja on syömäri ja juomari;
Wọn yóò sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ọmọ wa yìí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀. Kò ní gbọ́rọ̀ sí wa lẹ́nu. Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtípara ni.”
21 Niin pitää kaiken kaupungin kansan hänen kuoliaaksi kivittämän: ja niin sinä eroitat pahan sinustas, että koko Israel sen kuulis ja pelkäis.
Nígbà náà ni gbogbo ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò sọ ọ́ ní òkúta pa. Ìwọ yóò sì mú ìwà ibi kúrò láàrín yín, gbogbo Israẹli yóò gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n.
22 Jos joku on tehnyt jonkun synnin, joka kuoleman on ansainnut, ja hirsipuussa kuoletetaan,
Bí ọkùnrin kan tí ó jẹ̀bi ẹ̀sùn bá ní láti kú tí ó sì kú, tí a sì gbé òkú rẹ̀ kọ́ sára igi,
23 Niin ei pidä hänen ruumiinsa yötä puussa pidettämän, mutta haudatkaat häntä kohta sinä päivänä; sillä se on kirottu Jumalalta, joka hirtetty on, ettet sinä saastuttaisi sinun maatas, jonka Herra sinun Jumalas sinulle perimiseksi antaa.
o kò gbọdọ̀ fi òkú rẹ̀ sílẹ̀ sára igi ní gbogbo òru. Gbìyànjú láti sin ín ní ọjọ́ náà gan an, nítorí ẹni tí a bá gbé kọ́ sórí igi wà lábẹ́ ègún Ọlọ́run. Ìwọ kò gbọdọ̀ ba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún jẹ́.

< 5 Mooseksen 21 >