< Aamoksen 1 >

1 Tämä on se, minkä Amos, joka paimenien seassa Tekoassa oli, näki Israelissa, Ussian Juudan kuninkaan ajalla, ja Jerobeamin Joaksen pojan, Israelin kuninkaan ajalla, kahta vuotta ennen maan järistystä.
Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
2 Ja sanoi: Herra on Zionista kiljuva, ja Jerusalemista antaa hän äänensä kuulla, että paimenien laidun surkiana oleman pitää, ja Karmeli ylhäältä kuivuman.
Ó wí pé, “Olúwa yóò bú jáde láti Sioni, ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá; ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀, orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
3 Näin sanoo Herra: kolmen ja neljän Damaskun vian tähden en tahdo minä häntä säästää, että he Gileadin rautaisilla vaunuilla runtelivat.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi. Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,
4 Vaan minä lähetän tulen Hasaelin huoneesen; sen pitää Benhadadin huoneet kuluttaman.
Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli, èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
5 Ja rikon Damaskun salvat, ja hävitän Avenin laakson asuvaiset, ja sen, joka valtikkaa pitää, siitä kauniista huoneesta; niin että Syrian kansa pitää Kiriin vietämän, sanoo Herra.
Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku; Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni. Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,” ni Olúwa wí.
6 Näin sanoo Herra: kolmen ja neljän Gatsan vian tähden en minä tahdo häntä säästää, että he ovat vangitut vielä vanginneet, ja heidät Edomiin ajaneet.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú, ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn. Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
7 Vaan minä lähetän tulen Gatsan muuriin, joka heidän huoneensa pitää kuluttaman.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.
8 Ja tahdon Asdodin asuvaiset, ja sen, joka valtikkaa pitää, Askalonista hävittää; ja minun käteni on oleva Akronia vastaan, niin että hukkuman pitää, mitä Philistealaisista jäänyt on, sanoo Herra, Herra.
Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò, ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú. Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Näin sanoo Herra: kolmen ja neljän Tyron vian tähden en tahdo minä häntä säästää, että he ovat vangit edemmä Edomin maata ajaneet, ja ei ole muistaneet veljesten liittoa.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu. Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,
10 Vaan minä tahdon tulen Tyron muuriin lähettää, jonka pitää kuluttaman hänen huoneensa.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire, tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
11 Näin sanoo Herra: kolmen ja neljän Edomin vian tähden en tahdo minä häntä säästää, että hän on veljeänsä miekalla vainonnut, ja turmellut halunsa, ja on ollut aina hänelle paha vihoillansa ja alati hirmuisuutensa näyttänyt.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀, Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù, ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí, ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,
12 Vaan minä lähetän tulen Temaniin, jonka pitää kuluttaman Botsran huoneet.
Èmi yóò rán iná sí orí Temani, tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
13 Näin sanoo Herra: kolmen ja neljän Ammonin lasten vian tähden en tahdo minä heitä säästää, että he ovat raskaat vaimot halki leikanneet Gileadissa, levittääksensä rajojansa.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni, àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14 Vaan minä sytytän tulen Rabban muuriin; sen pitää kuluttaman hänen huoneensa. Niinkuin sodan aikana parutaan, ja niinkuin tuuli tulee tuulispään aikana:
Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun, pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15 Niin pitää myös heidän kuninkaansa ja päämiehensä ynnä vietämän pois vangittuina, sanoo Herra.
Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn, òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,” ni Olúwa wí.

< Aamoksen 1 >