< 2 Kuninkaiden 6 >

1 Ja prophetain pojat sanoivat Elisalle: katso, se sia, jossa me asumme sinun tykönäs, on meille ahdas;
Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
2 Anna meidän mennä Jordaniin asti, ja jokaisen tuoda sieltä yksi hirsi, että me rakentaisimme sinne sian asuaksemme. Ja hän sanoi: menkäät!
Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
3 Ja yksi sanoi: tule palveliais kanssa! Ja hän vastasi: minä tulen.
Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
4 Ja hän meni heidän kanssansa. Ja kuin he tulivat Jordanin tykö, hakkasivat he siinä puita.
Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
5 Ja kuin yksi heistä oli puun maahan hakannut, putosi rauta veteen, ja hän huusi ja sanoi: voi, herrani! senkin minä olen lainaksi ottanut.
Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
6 Mutta Jumalan mies sanoi: kuhunka se putosi? Ja kuin hän osoitti hänelle paikan, leikkasi hän yhden puun ja heitti sinne, ja saatti niin raudan uiskentelemaan.
Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
7 Ja hän sanoi: ota se ylös! ja hän ojensi kätensä ja otti sen.
Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
8 Ja Syrian kuningas soti Israelia vastaan, ja piti neuvoa palveliainsa kanssa ja sanoi: me tahdomme sioittaa itsemme sinne ja sinne.
Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
9 Mutta Jumalan mies lähetti Israelin kuninkaan tykö, ja käski hänelle sanoa: karta, ettes menisi siihen paikkaan; sillä Syrialaiset väijyvät siellä.
Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
10 Niin lähetti siis Israelin kuningas siihen paikkaan, josta Jumalan mies oli sanonut hänelle, ja varoittanut häntä siitä, ja piti siinä vartiat; ja ei tehnyt sitä ainoasti yhtä eli kahta kertaa.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
11 Niin Syrian kuninkaan sydän tuli surulliseksi siitä, ja kutsui palveliansa ja sanoi heille: ettekö te ilmoita minulle, kuka meistä on paennut Israelin kuninkaan tykö?
Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
12 Niin sanoi yksi hänen palvelioistansa: ei niin, herrani kuningas; mutta Elisa propheta, joka on Israelissa, sanoo Israelin kuninkaalle nekin asiat, joitas puhut makaushuoneessas.
Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
13 Hän sanoi: niin menkäät matkaan ja katsokaat, kussa hän on, että minä lähettäisin ja antaisin ottaa hänen kiinni. Ja he ilmoittivat hänelle ja sanoivat: katso, hän on Dotanissa.
Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
14 Niin hän lähetti sinne hevoset ja vaunut ja suuren joukon; ja kuin he sinne tulivat yöllä, piirittivät he kaupungin.
Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
15 Ja Jumalan miehen palvelia nousi varhain aamulla menemään ulos: ja katso, suuri sotajoukko piiritti kaupungin hevosten ja vaunuin kanssa. Niin hänen palveliansa sanoi hänelle: voi, herrani! mitä me nyt teemme?
Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
16 Ja hän sanoi: älä pelkää, sillä niitä on enempi jotka meidän kanssamme ovat, kuin niitä, jotka heidän kanssansa ovat.
“Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
17 Ja Elisa rukoili ja sanoi: Herra, avaa nyt hänen silmänsä, että hän näkis! Niin avasi Herra palvelian silmät, että hän näki, ja katso, vuori oli täynnä tulisia hevosia ja vaunuja, Elisan ympärillä.
Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
18 Ja kuin he tulivat alas hänen tykönsä, rukoili Elisa Herraa ja sanoi: lyö tätä kansaa sokeudella! Ja hän löi heidät sokeudella Elisan sanan jälkeen.
Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
19 Ja Elisa sanoi heille: ei tämä ole se tie ja se kaupunki: seuratkaat minua, minä vien teidät sen miehen tykö, jota etsitte; ja hän vei heidät Samariaan.
Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
20 Kuin he tulivat Samariaan, sanoi Elisa: Herra, avaa näiden silmät, että he näkisivät! Ja Herra avasi heidän silmänsä, että he näkivät, ja katso, niin he olivat keskellä Samariaa.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
21 Ja kuin Israelin kuningas näki heidät, sanoi hän Elisalle: isäni, lyönkö minä heitä?
Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
22 Ja hän sanoi: älä lyö! Pitääkö sinun lyömän niitä, jotka sinä vangiksi saat miekallas ja joutsellas? Anna heille leipää ja vettä, että he söisivät ja joisivat, ja anna heidän mennä Herransa tykö.
“Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
23 Niin valmistettiin heille suuri pito. Ja kuin he olivat syöneet ja juoneet, laski hän heidät menemään, ja he menivät herransa tykö. Ja ei Syriasta enää sotaparvia tullut Israelin maalle.
Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
24 Vaan senjälkeen tapahtui, että Benhadad Syrian kuningas kokosi kaikki sotaväkensä, meni ja piiritti Samarian.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
25 Ja suuri nälkä oli Samariassa, ja he ahdistivat kaupunkia, siihenasti että aasin pää maksoi kahdeksankymmentä hopiapenninkiä, ja neljäs osa kabia kyhkyläisen sontaa maksoi viisi hopiapenninkiä.
Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
26 Ja kuin Israelin kuningas kävi muurin päällä, huusi yksi vaimo häntä ja sanoi: auta minua, herrani kuningas!
Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
27 Ja hän sanoi: jollei Herra auta sinua, kusta minä sinua autan, luvastako eli viinakuurnasta?
Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
28 Ja kuningas sanoi hänelle: mikä sinun on? Hän sanoi: tämä vaimo sanoi minulle: tuo tänne poikas, että sen söisimme tänäpänä; syökäämme huomenna minun poikani.
Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
29 Ja me olemme keittäneet minun poikani ja syöneet sen. Ja minä sanoin toisena päivänä hänelle: tuo tänne sinun poikas, että me söisimme sen; mutta hän kätki poikansa.
Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
30 Kuin kuningas kuuli vaimon puheet, repäisi hän vaatteensa; ja kuin hän kävi ohitse muurin päällä, niin kansa näki, ja katso, hänen päällänsä oli säkki ihoa vasten.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
31 Ja hän sanoi: Jumala tehköön minulle sen ja sen, jos Elisan Zaphatin pojan pää tänäpänä pitää seisoman hänen päällänsä.
Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
32 Ja Elisa istui huoneessansa, ja vanhimmat istuivat hänen tykönänsä; mutta hän lähetti miehen edellänsä, mutta ennenkuin sanansaattaja tuli hänen tykönsä, sanoi hän vanhimmille: oletteko nähneet, kuinka se murhamiehen poika on lähettänyt ottamaan minun päätäni pois? Katsokaat, koska sanansaattaja tulee, että te oven suljette ja ovella hänen syöksette ulos: katso, hänen herransa jalkain töminä seuraa häntä.
Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
33 Kuin hän vielä heidän kanssansa puhui, katso, niin sanansaattaja tuli hänen tykönsä ja sanoi: katso, tämä paha tulee Herralta, mitä minä enään odotan Herraa?
Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”

< 2 Kuninkaiden 6 >