< 2 Kuninkaiden 3 >

1 Niin Joram Ahabin poika tuli Israelin kuninkaaksi Samariassa kahdeksantenatoistakymmenentenä Josaphatin Juudan kuninkaan vuonna, ja hallitsi kaksitoistakymmentä vuotta.
Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá.
2 Ja teki pahaa Herran edessä, vaan ei kuitenkaan niinkuin hänen isänsä ja äitinsä; sillä hän hävitti Baalin patsaan, jonka hänen isänsä tehnyt oli.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
3 Mutta kuitenkin hän pysyi Jerobeamin Nebatin pojan synneissä, joka Israelin saatti syntiä tekemään; ei hän luopunut niistä.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.
4 Mutta Mesalla Moabilaisten kuninkaalla oli paljo lampaita, ja hän antoi Israelin kuninkaalle veron, satatuhatta karitsaa ja satatuhatta oinasta villoinensa.
Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún àgbò.
5 Kuin Ahab oli kuollut, luopui Moabilaisten kuningas Israelin kuninkaasta.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli.
6 Siihen aikaan läksi kuningas Joram Samariasta ja luki kaiken Israelin,
Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà.
7 Ja meni ja lähetti Josaphatille Juudan kuninkaalle sanomaan: Moabilaisten kuningas on luopunut minusta, tuletkos sotimaan minun kanssani Moabilaisia vastaan? Hän sanoi: minä tulen, minä olen niinkuin sinä, ja minun kansani niinkuin sinun kansas, ja minun hevoseni niinkuin sinun hevoses.
Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?” Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
8 Ja sanoi: mitä tietä meidän pitää sinne vaeltaman? Hän vastasi: Edomin korven tietä.
“Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè. “Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.
9 Ja niin läksi Israelin kuningas ja Juudan kuningas ja Edomin kuningas. Ja koska he olivat vaeltaneet ympäri seitsemän päivän matkan, ja ei ollut vettä sotaväellä ja juhdilla, jotka heitä seurasivat,
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.
10 Niin sanoi Israelin kuningas: voi! Herra on kutsunut nämät kolme kuningasta antaaksensa heitä Moabilaisten käsiin.
“Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”
11 Mutta Josaphat sanoi: onko tässä yhtään Herran prophetaa, kysyäksemme hänen kauttansa neuvoa Herralta? Niin vastasi yksi Israelin kuninkaan palvelioista ja sanoi: tässä on Elisa Saphatin poika, joka kaasi vettä Elian kätten päälle.
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?” Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”
12 Josaphat sanoi: hänen tykönänsä on Herran sana. Ja Israelin kuningas, ja Josaphat ja Edomin kuningas menivät hänen tykönsä.
Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.
13 Niin sanoi Elisa Israelin kuninkaalle: mitä sinun on minun kanssani? mene pois isäs prophetain tykö ja äitis prophetain tykö! Israelin kuningas sanoi hänelle: ei, sillä Herra on kutsunut nämät kolme kuningasta antaaksensa heitä Moabilaisten käsiin.
Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.” Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”
14 Elisa sanoi: niin totta kuin Herra Zebaot elää, jonka edessä minä seison, jollen minä katsoisi Josaphatia Juudan kuningasta, en minä katsahtaisi sinun päälles enkä tottelisi sinua.
Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.
15 Niin tuokaat nyt minulle kanteleensoittaja! Ja kuin soittaja soitti, tuli Herran käsi hänen päällensä;
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.” Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa.
16 Ja hän sanoi: näin sanoo Herra: tehkäät kuoppia sinne ja tänne tähän ojaan!
Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’
17 Sillä näin sanoo Herra: ei teidän pidä tuulta eikä sadetta näkemän, ja kuitenkin pitää oja vedellä täytettämän: ja teidän pitää juoman, ja teidän karjanne ja teidän juhtanne.
Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu.
18 Ja tämä on vähä Herran edessä; sillä hän antaa myös Moabilaiset teidän käsiinne;
Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú.
19 Niin että te lyötte kaikki vahvat kaupungit ja kaikki valitut kaupungit, ja te kaadatte kaikki hyvät puut ja tukitsette kaikki vesilähteet, ja te turmelette kaikki hyvät pellot kivillä.
Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”
20 Ja tapahtui aamulla ruokauhrin ajalla, katso, silloin tuli vesi Edomin tietä myöten, ja maa täytettiin vedellä.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.
21 Kuin kaikki Moabilaiset kuulivat, että kuninkaat oli nousseet ylös sotimaan heitä vastaan, kutsuivat he kokoon kaikki, jotka itsensä ensin vyöllä vyöttivät, ja sitä vanhemmat, ja menivät rajoille.
Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀.
22 Mutta kuin he aamulla varhain nousivat, ja aurinko nousi veden yli, niin näkivät Moabilaiset, että vesi oli heitä vastaan punainen niinkuin veri,
Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀.
23 Ja sanoivat: se on veri; kuninkaat ovat tapelleet keskenänsä, ja yksi on lyönyt toisen kuoliaaksi: nyt siis, Moab, mene saaliille!
“Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”
24 Mutta kuin he tulivat Israelin leiriin, niin nousi Israel ja löi Moabilaisia; ja ne pakenivat heidän edellänsä; mutta he kiiruhtivat ja löivät Moabin,
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run.
25 Ja kukistivat kaupungit, ja itsekukin heitti kivensä kaikkiin hyviin peltoihin ja täyttivät ne, ja tukitsivat kaikki vesilähteet, ja kaasivat kaikki hyvät puut, siihenasti että he ainoasti Hasaretin muuriin kiviä jättivät; ja he piirittivät sen lingoilla ja löivät sen.
Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.
26 Kuin Moabilaisten kuningas näki sodan olevan ylen väkevän itsiänsä vastaan, otti hän seitsemänsataa miestä tykönsä, jotka vetivät miekan ulos, karataksensa Edomin kuninkaan päälle; vaan ei he voineet.
Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege.
27 Niin otti hän ensimäisen poikansa, joka hänen siaansa piti kuninkaaksi tuleman, ja uhrasi sen polttouhriksi muurin päällä. Silloin tuli Israel sangen vihaiseksi, niin että he menivät pois hänen tyköänsä ja palasivat omalle maallensa.
Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.

< 2 Kuninkaiden 3 >