< 2 Aikakirja 21 >

1 Ja Josaphat nukkui isäinsä kanssa ja haudattiin isäinsä tykö Davidin kaupunkiin. Ja hänen poikansa Joram tuli kuninkaaksi hänen siaansa.
Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
2 Ja hänellä oli veljiä Josaphatin poikia, Asaria, Jehiel, Sakaria, Asaria, Mikael ja Sephatia. Nämät kaikki olivat Josaphatin Israelin kuninkaan pojat.
Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
3 Ja heidän isänsä antoi heille monta lahjaa hopiasta, kullasta ja kalliista kappaleista, vahvain Juudan kaupunkein kanssa. Mutta Joramille antoi hän valtakunnan; sillä hän oli esikoinen.
Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
4 Kuin Joram korotettiin isänsä valtakuntaan ja tuli voimalliseksi, tappoi hän kaikki veljensä miekalla ja muutamia Israelin ylimmäisistä.
Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
5 Ja Joram oli kahden ajastajan vanha neljättäkymmentä tullessansa kuninkaaksi; ja hän hallitsi kahdeksan ajastaikaa Jerusalemissa,
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
6 Ja hän vaelsi Israelin kuningasten tiellä, niinkuin Ahabin huone teki; sillä Ahabin tytär oli hänen emäntänsä; ja hän teki pahaa Herran edessä.
Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
7 Mutta ei Herra tahtonut hukuttaa Davidin huonetta, sen liiton tähden, jonka hän tehnyt oli Davidin kanssa, ja niinkuin hän puhunut oli antaaksensa hänelle ja hänen lapsillensa valkeuden joka aika.
Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
8 Hänen aikanansa luopuivat Edomilaiset Juudan vallan alta ja tekivät itsellensä kuninkaan.
Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
9 Niin Joram meni ylitse ylimmäistensä kanssa, ja kaikki vaunut hänen kanssansa; ja hän valmisti itsensä yöllä ja löi kaikki Edomilaiset ympäristöltänsä, ja myös vaunuin päämiehet.
Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
10 Ja Edomilaiset luopuivat Juudan vallan alta tähän päivään asti; silloin luopui myös Libna hänestä; sillä hän hylkäsi Herran isäinsä Jumalan.
Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
11 Ja hän teki korkeuksia Juudan vuorilla, ja saatti Jerusalemin asuvaiset huorin tekemään ja vietteli Juudan.
Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
12 Ja kirjoitus tuli hänelle Elialta prophetalta, joka näin oli: näin sanoo Herra sinun isäs Davidin Jumala: ettes vaeltanut isäs Josaphatin teillä, etkä Aksan Juudan kuninkaan teillä;
Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
13 Mutta vaellat Israelin kuningasten tiellä, ja saatat Juudan ja Jerusalemin asuvaiset huorin tekemään Ahabin huoneen huoruuden jälkeen, ja olet tappanut veljes isäs huoneesta, jotka sinua paremmat olivat;
Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
14 Katso, niin Herra lyö sinua kovin ja sinun kansaas, lapsias, emäntiäs ja kaikkea hyvyyttäs.
Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
15 Ja sinun sisällyksissäs pitää oleman monta sairautta, siihenasti että sisällykses sinusta päivä päivältä sairauden tähden käyvät ulos.
Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
16 Niin Herra herätti Joramia vastaan Philistealaisten ja Arabialaisten hengen, jotka ovat Etiopialaisten tykönä.
Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
17 Ja he menivät ylös Juudaan, ja hävittivät sen ja veivät pois kaiken kalun, joka kuninkaan huoneessa oli, niin myös hänen poikansa ja emäntänsä; niin ettei hänelle yhtään poikaa jäänyt, paitsi Joahasta nuorinta poikaansa.
Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
18 Ja kaiken sen jälkeen rankaisi Herra häntä hänen sisällyksissänsä senkaltaisella taudilla, jota ei taidettu parantaa.
Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
19 Ja se tapahtui päivä päivältä, siihenasti kuin kahden vuoden aika kulunut oli, että hänen sisällyksensä kävivät ulos hänestä, hänen tautinsa kanssa; ja hän kuoli pahoista taudeista. Ja he ei tehneet yhtään suitsutusta hänelle, niin kuin he olivat tehneet hänen esi-isillensä.
Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
20 Hän oli kahden ajastajan vanha neljättäkymmentä tullessansa kuninkaaksi, ja hallitsi kahdeksan ajastaikaa Jerusalemissa, ja vaelsi kelvottomasti; ja he hautasivat hänen Davidin kaupunkiin, mutta ei kuningasten hautain sekaan.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.

< 2 Aikakirja 21 >