< 1 Kuninkaiden 21 >

1 Sitte tapahtui, että Nabotilla Jisreeliläisellä oli viinamäki Jisreelissä, läsnä Ahabin Samarian kuninkaan huonetta.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
2 Ja Ahab puhui Nabotille ja sanoi: anna minulle viinamäkes kaalimaaksi, että se on niin läsnä huonettani, ja minä annan sinulle sen edestä paremman viinamäen: eli jos sinun niin kelpaa, niin minä annan sinulle hopiaa niin paljo kuin se maksaa.
Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
3 Mutta Nabot sanoi Ahabille: Herra varjelkoon minua antamasta sinulle isäini perintöä!
Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
4 Niin Ahab tuli kotiansa pahalla mielellä ja vihoissansa, sen sanan tähden minkä Nabot Jisreeliläinen hänelle puhunut oli, sanoen: en minä anna sinulle isäini perintöä; ja hän heittäysi vuoteesen, käänsi kasvonsa ja ei syönyt leipää.
Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
5 Niin tuli Isebel hänen emäntänsä hänen tykönsä ja sanoi hänelle: mikä se on, että henkes on niin murheellinen, ja et syö leipää?
Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
6 Niin hän sanoi hänelle: minä olen puhutellut Nabotia Jisreeliläistä ja sanonut: anna minulle viinamäkes rahan edestä, eli jos tahdot, niin minä annan sinulle toisen viinamäen sen edestä. Mutta hän sanoi: en minä anna sinulle viinamäkeäni.
Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
7 Niin Isebel hänen emäntänsä sanoi hänelle: sinä hallitset nyt Israelin valtakunnan. Nouse ja syö leipää ja ole hyvällä mielellä: minä saatan sinulle Nabotin Jisreeliläisen viinamäen.
Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
8 Ja hän kirjoitti kirjan Ahabin nimellä, ja lukitsi sen hänen sinetillänsä, ja lähetti sen kirjan vanhimpain ja ylimmäisten tykö, jotka hänen kaupungissansa asuivat Nabotin kanssa.
Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
9 Ja kirjoitti näin kirjaan, sanoen: kuuluttakaat paasto, ja asettakaat Nabot istumaan ylimmäiseksi kansan sekaan,
Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
10 Ja tuokaat kaksi pahanjuonista miestä häntä vastaan, jotka tunnustavat ja sanovat: sinä olet kironnut Jumalaa ja kuningasta: ja viekäät häntä ulos ja kivittäkäät häntä kuoliaaksi.
Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
11 Niin vanhimmat ja sen kaupungin ylimmäiset, jotka hänen kaupungissansa asuivat, tekivät niinkuin Isebel heidän käskenyt oli ja niinkuin kirjassa kirjoitettu oli, jonka hän heidän tykönsä lähettänyt oli:
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
12 Kuuluttivat paaston, ja antoivat Nabotin istua ylimmäiseksi kansan seassa.
Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
13 Niin tul kaksi pahanjuonista miestä ja istui hänen kohdallensa, ja tunnustivat Nabotia vastaan kansan edessä ja sanoivat: Nabot on kironnut Jumalaa ja kuningasta; niin veivät he hänen kaupungista ulos ja kivittivät hänen juuri kuoliaaksi.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
14 Ja he lähettivät Isebelin tykö, sanoen: Nabot on kivitetty ja kuollut.
Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
15 Kun isebel kuuli Nabotin kivitetyksi ja kuolleksi, sanoi hän Ahabille: nouse ja omista Nabotin Jisreeliläisen viinamäki, jonka hän sinulta on kieltänyt rahan edestä; sillä ei Nabot elä, vaan on kuollut.
Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
16 Kuin Ahab kuuli Nabotin kuolleeksi, nousi hän menemään ja omistamaan Nabotin Jisreeliläisen viinamäkeä.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
17 Mutta Herran sana tuli Elialle Tisbiläiselle ja sanoi:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
18 Nouse ja mene Ahabia Israelin kuningasta vastaan, joka on Samariassa, (katso, hän on Nabotin viinamäessä, jota hän on mennyt omistamaan.)
“Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
19 Ja puhu hänelle ja sano: näin sanoo Herra: pitikö sinun tappaman, ja vielä päälliseksi omistaman? Ja sinun pitää puhuman hänelle ja sanoman: näin sanoo Herra: siinä paikassa, jossa koirat nuoleskelivat Nabotin veren, pitää koirain sinunkin vertas nuoleskeleman.
Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
20 Ja Ahab saboi Elialle: löysitkös nyt minun, sinä minun vihamieheni? Hän sanoi: löysin, ettäs olet sinus myynyt pahaa tekemään Herran silmäin edessä.
Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
21 Katso, minä annan tulla pahuuden sinun päälles, ja otan sinun sukukuntas pois, ja hävitän Ahabilta sen, joka vettänsä seinään heittää, ja suljetun ja hyljätyn Israelissa.
‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
22 Ja teen sinun huonees niinkuin Jerobeaminkin Nebatin pojan huoneen, ja niinkuin Baesan Ahian pojan huoneen, sen vihoittamisen tähden, millä sinä minua vihoittanut olet, ja saattanut Israelin syntiä tekemään.
Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
23 Ja Herra puhui myös Isebelille ja sanoi: koirain pitää syömän Isebelin Jisreelin muurin tykönä.
“Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
24 Joka Ahabista kuolee kaupungissa, se pitää koirilta syötämän, ja jos joku kuolee kedolla, se pitää taivaan linnuilta syötämän.
“Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
25 Tosin ei yhtään ollut, joka niin oli itsensä myynyt pahaa tekemään Herran edessä kuin Ahab; sillä hänen emäntänsä Isebel vietteli hänen.
(Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
26 Ja teki aivan suuret kauhistukset, seuraten epäjumalia, kaiken sen jälkeen kuin Amorilaiset tehneet olivat, jotka Herra ajoi Israelin lasten edestä pois.
Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
27 Koska Ahab nämät sanat kuuli, repäisi hän vaatteensa, ja puki säkin ihollensa ja paastosi, ja makasi säkissä ja kävi suruissansa.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
28 Ja Herran sana tuli Elian Tisbiläisen tykö ja sanoi:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
29 Etkös nähnyt, kuinka Ahab nöyryytti itsensä minun edessäni? että hän itsensä niin nöyryyttää minun edessäni, en minä saata sitä pahaa hänen aikanansa; mutta hänen poikansa aikana saatan minä pahan hänen huoneensa päälle.
“Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”

< 1 Kuninkaiden 21 >