< 1 Kuninkaiden 19 >

1 Ja Ahab ilmoitti Isebelille kaikki mitä Elia tehnyt oli, ja kuinka hän oli tappanut prophetat miekalla.
Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
2 Niin lähetti Isebel sanansaattajat Elialle, sanoen: jumalat minun niin ja niin tehköön, jollen minä huomenna tällä aikaa tee sinun sielulles, niinkuin yhdelle näiden sielulle.
Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
3 Kuin hän sen näki, nousi hän ja meni kuhunka hän tahtoi, ja tuli Bersebaan, joka oli Juudassa, ja jätti sinne palveliansa.
Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
4 Mutta itse hän meni korpeen päiväkunnan matkan; ja kuin hän tuli sinne, istui hän katavan alla, rukoillen sieluansa kuolemaan, ja sanoi: jo kyllä on, Herra, ota nyt sieluni; sillä en minä ole parempi isiäni.
nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
5 Ja hän pani maata ja nukkui katavan alle; ja katso, enkeli tarttui häneen ja sanoi hänelle: nouse ja syö!
Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
6 Mutta kuin hän katsahti ympärillensä, katso, niin oli hänen päänsä takana hiilillä kypsytetty leipä ja astia vettä; ja koska hän syönyt ja juonut oli, niin hän pani maata jälleen ja nukkui.
Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
7 Ja Herran enkeli palasi hänen tykönsä toisen kerran, tarttui häneen ja sanoi: nouse ja syö! sillä sinulla on pitkä matka.
Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
8 Ja hän nousi, söi ja joi, ja matkusti sen ruan voimalla neljäkymmentä päivää ja neljäkymmentä yötä Herran vuoreen Horebiin asti,
Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
9 Ja tuli siellä luolaan, ja oleskeli siellä yötä; ja katso, Herran sana sanoi hänelle: mitäs tässä Elia teet?
Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
10 Hän vastasi: minä olen kiivauksella kiivannut Herran Jumalan Zebaotin tähden; sillä Israelin lapset ovat hyljänneet sinun liittos, ja sinun alttaris kukistaneet ja tappaneet sinun prophetas miekalla, ja minä yksinäni jäin, ja he etsivät minun henkeäni, ottaaksensa sitä pois.
Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
11 Hän sanoi: mene tästä ulos ja astu vuorelle Herran eteen. Ja katso, Herra meni ohitse, ja suuri ja väkevä tuuli kävi, joka vuoret halkasi ja mäet särki Herran edellä; mutta ei Herra ollut tuulessa; ja tuulen perästä tuli maanjäristys, ja ei Herra ollut maanjäristyksessä;
Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
12 Ja maanjäristyksen perästä tuli tulta, ja ei Herra ollut tulessa; tulen perästä tuli hieno tuulen hyminä.
Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
13 Kuin Elia sen kuuli peitti hän kasvonsa hameellansa, ja meni ulos ja seisoi luolan ovella, ja katso, ääni sanoi hänelle: mitä sinulla tässä on (tekemistä), Elia?
Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
14 Hän vastasi: minä olen kiivauksella kiivannut Herran Jumalan Zebaotin tähden; sillä Israelin lapset ovat hyljänneet sinun liittos, kukistaneet sinun alttaris ja tappaneet sinun prophetas miekalla, ja minä ainoasti jäin, ja he etsivät minun henkeäni, ottaaksensa sitä pois.
Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
15 Mutta Herra sanoi hänelle: palaja tietäs myöten Damaskun korpeen: mene ja voitele Hasael Syrian kuninkaaksi.
Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
16 Ja voitele Jehu Nimsin poika Israelin kuninkaaksi; ja Elisa Saphatin poika, AbelMeholasta, voitele prophetaksi sinun siaas.
Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
17 Ja tapahtuu, että joka välttää Hasaelin miekan, se tapetaan Jehulta, ja joka välttää Jehun miekan, se tapetaan Elisalta.
Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
18 Mutta minä jätän seitsemäntuhatta Israeliin: kaikki polvet, jotka ei kumartaneet Baalia, ja kaikki suut, jotka ei hänen suuta antaneet.
Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
19 Ja hän läksi sieltä ja kohtasi Elisan Saphatin pojan, joka kynti kahdellatoistakymmenellä parilla härkiä, ja hän itse oli niiden kahdentoistakymmenen seassa; ja Elia meni hänen tykönsä ja heitti hameensa hänen päällensä.
Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
20 Ja hän jätti härjät ja juoksi Elian perässä, ja sanoi: anna minun suuta antaa minun isälleni ja äidilleni, niin minä seuraan sinua; hän sanoi hänelle: mene ja tule jälleen; sillä mitä minä sinulle tein?
Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
21 Ja hän palasi hänen tykönsä, ja otti parin härkiä ja uhrasi sen, ja keitti lihan härkäin kaluilla, ja antoi kansalle syödä; ja hän nousi ja seurasi Eliaa, ja palveli häntä.
Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.

< 1 Kuninkaiden 19 >