< 1 Kuninkaiden 17 >
1 Ja Elia Tisbiläinen Gileadin asuja sanoi Ahabille: niin totta kuin Herra Israelin Jumala elää, jonka edessä minä seison, ei pidä näillä vuorilla kastetta eikä sadetta tuleman, muutoin kuin minun sanani jälkeen.
Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
2 Ja Herran sana tuli hänen tykönsä sanoen:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
3 Mene tästä pois ja käännä itses itään päin, ja lymytä sinus Keritin ojan tykö, joka on Jordanin kohdalla.
“Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
4 Ja sinun pitää juoman ojasta: ja minä olen käskenyt kaarnetten elättää sinua siellä.
Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
5 Hän meni ja teki Herran sanan jälkeen, ja meni istui Keritin ojan tykönä, joka on Jordanin kohdalla.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
6 Ja kaarneet veivät hänelle leipää ja lihaa, huomeneltain ja ehtoona, ja hän joi ojasta.
Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
7 Ja monikahtain päiväin perästä kuivui oja; sillä ei ollut sadetta maakunnassa.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
8 Niin tuli Herran sana hänen tykönsä, sanoen:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
9 Nouse ja mene Sarpatiin, joka Sidonin tykönä on, ja pysy siellä: katso, minä olen käskenyt leskivaimon sinua siellä elättää.
“Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
10 Ja hän nousi ja meni Sarpatiin; ja kuin hän kaupungin porttiin tuli, katso, leskivaimo oli siellä ja haki puita, ja hän puhui hänelle, sanoen: tuo minulle vähä vettä astiassa juodakseni.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
11 Kuin hän meni tuomaan, huusi hän häntä ja sanoi: tuo myös minulle pala leipää kädessäs.
Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
12 Hän sanoi: niin totta kuin Herra sinun Jumalas elää, ei ole minulla leipää, mutta pivo jauhoja vakkaisessa ja vähä öljyä astiassa: ja katso, minä kokoon kaksi puuta ja menen valmistamaan itselleni ja pojalleni, syödäksemme ja sitte kuollaksemme.
Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
13 Ja Elia sanoi hänelle: älä pelkää, mene ja tee niinkuin sinä sanonut olet; kuitenkin leivo minulle vähä kyrsäinen siitä ensin ja tuo minulle; mutta itselles ja pojalles pitää myös sinun siitä sen jälkeen tekemän:
Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
14 Sillä näin sanoo Herra Israelin Jumala: Ei jauhot vakkaisesta pidä loppuman ja öljy astiasta ei pidä puuttuman, siihen päivään asti kuin Herra antaa sataa maan päälle.
Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
15 Ja hän meni ja teki niinkuin Elia puhunut oli. Ja hän söi ja myös vaimo perheinensä kauvan aikaa.
Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
16 Ei jauhot loppuneet vakkaisesta eikä öljy astiasta, Herran sanan jälkeen, jonka hän Elian kautta puhunut oli.
Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
17 Sen jälkeen tapahtui, että perheen emännän poika sairasti, ja hänen sairautensa oli niin raskas, ettei henkeä hänessä silleen ollut.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
18 Ja hän sanoi Elialle: mitä minulla on sinun kanssas, sinä Jumalan mies? Sinä olet tullut minun tyköni, että minun pahatekoni muistettaisiin ja minun poikani kuolis.
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
19 Hän sanoi hänelle: tuo minulle poikas. Ja hän otti hänet, hänen sylistänsä, ja vei hänen ylistupaan, kussa hän asui, ja pani hänen omaan vuoteesensa,
Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
20 Ja huusi Herran tykö ja sanoi: Herra minun Jumalani! oletkos niin pahoin tehnyt tätä leskeä vastaan, jonka tykönä minä holhotaan, ettäs tapat hänen poikansa?
Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
21 Ja hän ojensi itsensä kolmasti nuorukaisen päälle, ja huusi Herran tykö ja sanoi: Herra minun Jumalani, anna tämän nuorukaisen sielu tulla häneen jällensä!
Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
22 Ja Herra kuuli Elian äänen: ja hänen sielunsa tuli häneen jälleen, ja hän virkosi.
Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
23 Ja Elia otti pojan ja kantoi ylistuvasta alas huoneesen, ja antoi äidillensä, ja sanoi: katso, sinun poikas elää.
Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
24 Ja vaimo sanoi Elialle: nyt minä ymmärrän, ettäs olet Jumalan mies, Herran sana on tosi sinun suussas.
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”