< 1 Kuninkaiden 14 >

1 Siihen aikaan sairasti Abia Jerobemin poika.
Ní àkókò náà Abijah ọmọ Jeroboamu sì ṣàìsàn,
2 Ja Jerobeam sanoi emännällensä: nouse ja muuta itses, niin ettei yksikään tuntisi sinua Jerobeamin emännäksi; ja mene Siloon. Katso siellä on propheta Ahia, joka minulle sanoi: että minä olen tuleva tämän kansan kuninkaaksi.
Jeroboamu sì wí fún aya rẹ̀ pé, “Lọ, sì pa ara rẹ dà, kí wọn kí ó má ba à mọ̀ ọ́n ní aya Jeroboamu. Nígbà náà ni kí o lọ sí Ṣilo. Ahijah wòlíì wà níbẹ̀; ẹni tí ó sọ fún mi pé, èmi yóò jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn yìí.
3 Ja ota kätees kymmenen leipää ja kyrsää, ja astia hunajaa, ja mene hänen tykönsä, että hän sanois sinulle, mitä nuorukaiselle tapahtuu.
Mú ìṣù àkàrà mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, àti àkàrà wẹ́wẹ́ àti ìgò oyin, kí o sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Òun yóò sì sọ fún ọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọkùnrin náà.”
4 Ja Jerobeamin emäntä teki niin, nousi ja meni Siloon, ja tuli Ahian huoneesen; mutta ei Ahia taitanut nähdä, sillä hänen silmänsä olivat pimenneet vanhuudesta.
Bẹ́ẹ̀ ni aya Jeroboamu sì ṣe bí ó ti wí, ó sì lọ sí ilé Ahijah ní Ṣilo. Ahijah kò sì ríran; ojú rẹ̀ ti fọ́ nítorí ogbó rẹ̀.
5 Mutta Herra sanoi Ahialle: katso Jerobeamin emäntä tulee kysymään sinulta yhtä asiaa pojastansa, sillä hän on sairas; niin puhu sinä hänelle niin ja niin. Ja kuin hän tuli sisälle, piti hän itsensä outona.
Ṣùgbọ́n Olúwa ti sọ fún Ahijah pé, “Kíyèsi i, aya Jeroboamu ń bọ̀ wá béèrè nípa ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí ó ṣàìsàn, báyìí báyìí ni kí ìwọ kí ó wí fún un. Nígbà tí ó bá dé, yóò ṣe ara rẹ̀ bí ẹlòmíràn.”
6 Kuin Ahia kuuli ovessa hänen jalkainsa töminän, sanoi hän: tule sisälle, sinä Jerobeamin emäntä: kuinkas itses niin outona pidät? Minä olen lähtetty sinun tykös kovan sanoman kanssa.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí, nígbà tí Ahijah sì gbọ́ ìró ẹsẹ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Wọlé wá, aya Jeroboamu. Kí ló dé tí ìwọ fi ṣe ara rẹ bí ẹlòmíràn? A ti fi iṣẹ́ búburú rán mi sí ọ.
7 Mene ja sano Jerobeamille: näin sanoo Herra Israelin Jumala: että minä olen korottanut sinun kansan seasta ja pannut sinun minun kansani Israelin ruhtinaaksi,
Lọ, sọ fún Jeroboamu pé báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi sì gbé ọ ga láti inú àwọn ènìyàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
8 Ja olen reväissyt valtakunnan Davidin huoneelta pois, ja antanut sen sinulle: mutta et sinä ole ollut niinkuin minun palveliani David, joka piti minun käskyni ja vaelsi minun jälkeeni kaikella sydämellä, ja teki ainoastaan mitä minulle kelvollinen oli;
Mo fa ìjọba náà ya kúrò ní ilé Dafidi, mo sì fi fún ọ ṣùgbọ́n, ìwọ kò dàbí Dafidi ìránṣẹ́ mi, tí ó pa àṣẹ mi mọ́, tí ó sì tọ̀ mí lẹ́yìn tọkàntọkàn rẹ̀, láti ṣe kìkì èyí tí ó tọ́ ní ojú mi.
9 Mutta sinä olet tehnyt pahemmin kaikkia muita, jotka sinun edelläs olleet ovat, ja sinä olet mennyt ja tehnyt itselles vieraita jumalia ja valetuita kuvia kehoittaakses minua vihaan, ja olet heittänyt minun selkäs taa;
Ìwọ sì ti ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú rẹ lọ. Ìwọ sì ti ṣe àwọn ọlọ́run mìíràn fún ara rẹ, àwọn òrìṣà tí a gbẹ́; o sì ti mú mi bínú, o sì ti gbé mi sọ sí ẹ̀yìn rẹ.
10 Sentähden katso, minä annan tulla pahaa Jerobeamin huoneen päälle, ja hukutan Jerobeamista sen, joka vetensä seinään heittää, suljetun ja hyljätyn Israelissa, ja käväisen Jerobeamin huoneen sukukunnan, niinkuin tunkio käväistään, perikatoonsa asti.
“‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jeroboamu. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jeroboamu, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Israẹli. Èmi yóò mú ilé Jeroboamu kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.
11 Joka Jerobeamista kuolee kaupungissa, se pitää koirilta syötämän, mutta joka kuolee kedolla, se pitää taivaan linnuilta syötämän; sillä Herra on sen puhunut.
Ajá yóò jẹ ẹni Jeroboamu tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní igbó ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’
12 Niin nouse sinä ja mene kotias, ja kuin jalkas astuu kaupunkiin, niin pojan pitää kuoleman.
“Ní ti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.
13 Ja koko Israel itkee häntä ja hautaa hänen, sillä ainoastansa tämä tulee Jerobeamista hautaan, että jotakin hyvää on löydetty hänen tykönänsä, Herran Israelin Jumalan edessä, Jerobeamin huoneessa.
Gbogbo Israẹli yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jeroboamu, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní ilé Jeroboamu.
14 Ja Herra herättää itsellensä yhden Israelin kuninkaan, se on hävittävä Jerobeamin huoneen sinä päivänä: ja mitä jo on tapahtunut?
“Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fúnra rẹ̀ lórí Israẹli tí yóò ké ilé Jeroboamu kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsin yìí.
15 Ja Herra lyö Israelin niinkuin ruoko häälyy vedessä, ja repii Israelin tästä hyvästä maasta, jonka hän heidän isillensä antanut on, ja hajottaa heidät virran ylitse; että he ovat itsellensä tehneet metsistöitä, vihoittaksensa Herraa:
Olúwa yóò kọlu Israẹli, yóò sì dàbí koríko ti ń mì nínú omi. Yóò sì fa Israẹli tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò Eufurate, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère Aṣerah.
16 Ja hylkää Israelin, Jerobeamin synnin tähden, joka syntiä teki ja saatti Israelin syntiä tekemään.
Yóò sì kọ Israẹli sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀.”
17 Ja Jerobeamin emäntä nousi ja meni, ja tuli Tirtsaan; ja kuin hän astui huoneen kynnykseen, kuoli nuorukainen.
Nígbà náà ni aya Jeroboamu sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tirsa. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.
18 Ja he hautasivat hänen, ja koko Israel itki häntä, Herran sanan jälkeen, jonka hän palveliansa propheta Ahian kautta sanonut oli.
Wọ́n sì sin ín, gbogbo Israẹli sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ahijah wòlíì.
19 Mitä enempi Jerobeamista on sanomista, kuinka hän soti ja kuinka hän hallitsi: katso se on kirjoitettu Israelin kuningasten aikakirjassa.
Ìyókù ìṣe Jeroboamu, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jẹ ọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli.
20 Ja aika, jonka Jerobeam hallitsi, oli kaksikolmattakymmentä ajastaikaa; ja hän nukkui isäinsä kanssa; ja hänen poikansa Nadab tuli kuninkaaksi hänen siaansa.
Jeroboamu sì jẹ ọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nadabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
21 Niin oli Rehabeam, Salomon poika kuningas Juudassa, ja oli yhdenviidettäkymmentä ajastaikainen tultuansa kuninkaaksi, ja hallitsi seitsemäntoistakymmentä ajastaikaa Jerusalemissa, siinä kaupungissa, jonka Herra valinnut on kaikista Israelin sukukunnista, pannaksensa siihen nimensä; ja hänen äitinsä nimi oli Naema Ammonilainen.
Rehoboamu ọmọ Solomoni sì jẹ ọba ní Juda. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jerusalẹmu, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama, ará Ammoni.
22 Ja Juuda teki pahaa Herran edessä; ja he saattivat hänen enempi kiivaaksi, kuin kaikki heidän esi-isänsä olivat tehneet synneillänsä, joita he tekivät.
Juda sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.
23 Sillä hekin rakensivat itsellensä korkeuksia, patsaita ja metsistöitä kaikille korkeille vuorille ja kaikkein viheriäisten puiden alle.
Wọ́n sì tún kọ́ ibi gíga fún ara wọn, àti ère òkúta àti òpó Aṣerah lórí gbogbo òkè gíga, àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
24 Ja maakunnassa oli huorintekijöitä; ja he tekivät kaikki pakanain kauhistukset, jotka Herra Israelin lasten edestä oli ajanut pois.
Àwọn tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà wà ní ilẹ̀ náà, àwọn ènìyàn náà sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde kúrò níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
25 Ja tapahtui viidennellä kuningas Rehabeamin ajastajalla, että Sisak Egyptin kuningas meni Jerusalemia vastaan,
Ó sì ṣe ní ọdún karùn-ún Rehoboamu, Ṣiṣaki ọba Ejibiti kọlu Jerusalẹmu.
26 Ja otti Herran huoneen tavarat, ja kuninkaan huoneen tavarat, ja kaiken mitä sieltä taidettiin ottaa, ja otti kaikki kultaiset kilvet, jota Salomo oli antanut tehdä,
Ó sì kó ìṣúra ilé Olúwa lọ àti ìṣúra ilé ọba. Gbogbo rẹ̀ ni ó kó lọ, pẹ̀lú asà wúrà tí Solomoni ti ṣe.
27 Joiden siaan kuningas Rehabeam antoi tehdä vaskisia kilpiä, ja antoi ne ylimmäisten vartioittensa haltuun, jotka kuninkaan huoneen ovea vartioitsivat.
Rehoboamu ọba sì ṣe asà idẹ ní ipò wọn, ó sì fi wọ́n sí ọwọ́ olórí àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlẹ̀kùn ilé ọba.
28 Ja niin usein kuin kuningas meni Herran huoneesen, kantoivat vartiat niitä, ja veivät ne vartiakamariin jälleen.
Nígbàkígbà tí ọba bá sì lọ sí ilé Olúwa, wọ́n á rù wọ́n, wọ́n á sì mú wọn padà sínú yàrá olùṣọ́.
29 Mitä enempi Rehabeamin asioista on sanomista ja kaikista mitä hän tehnyt oli: eikö se ole kirjoitettu Juudan kuningasten aikakirjassa?
Ní ti ìyókù ìṣe Rehoboamu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda bí?
30 Ja Rehabeamin ja Jerobeamin välillä oli sota kaikkina heidän päivinänsä.
Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní ọjọ́ wọn gbogbo.
31 Ja Rehabeam nukkui isäinsä kanssa ja haudattiin isäinsä tykö Davidin kaupunkiin. Ja hänen äitinsä nimi oli Naema Ammonilainen. Ja hänen poikansa Abiam tuli kuninkaaksi hänen siaansa.
Rehoboamu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama; ará Ammoni. Abijah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< 1 Kuninkaiden 14 >