< Psalms 54 >

1 To the Overseer with stringed instruments. — An instruction, by David, in the coming in of the Ziphim, and they say to Saul, 'Is not David hiding himself with us?' O God, by Thy name save me, and by Thy might judge me.
Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, “Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa?” Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ: dá mi láre nípa agbára rẹ.
2 O God, hear my prayer, Give ear to the sayings of my mouth,
Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run; fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
3 For strangers have risen up against me And terrible ones have sought my soul, They have not set God before them. (Selah)
Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí. Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa, àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.
4 Lo, God [is] a helper to me, The Lord [is] with those supporting my soul,
Kíyèsi i Ọlọ́run ni olùrànlọ́wọ́ mi; Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró, pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
5 Turn back doth the evil thing to mine enemies, In Thy truth cut them off.
Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi; pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
6 With a free will-offering I sacrifice to Thee, I thank Thy name, O Jehovah, for [it is] good,
Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ, èmi yóò yin orúkọ rẹ, Olúwa, nítorí tí ó dára.
7 For, from all adversity He delivered me, And on mine enemies hath mine eye looked!
Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.

< Psalms 54 >