< Proverbs 19 >

1 Better [is] the poor walking in his integrity, Than the perverse [in] his lips, who [is] a fool.
Ó sàn kí ènìyàn jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ kò lábùkù ju aláìgbọ́n tí ètè rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà.
2 Also, without knowledge the soul [is] not good, And the hasty in feet is sinning.
Kò dára láti ní ìtara láìní ìmọ̀, tàbí kí ènìyàn kánjú kí ó sì ṣìnà.
3 The folly of man perverteth his way, And against Jehovah is his heart wroth.
Ìwà òmùgọ̀ ènìyàn fúnra rẹ̀ a pa ẹ̀mí rẹ̀ run; síbẹ̀ ọkàn rẹ̀ yóò máa bínú sí Olúwa.
4 Wealth addeth many friends, And the poor from his neighbour is separated.
Ọrọ̀ máa ń fa ọ̀rẹ́ púpọ̀; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ tálákà tún kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
5 A false witness is not acquitted, Whoso breatheth out lies is not delivered.
Ajẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà, ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde kò ní lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
6 Many entreat the face of the noble, And all have made friendship to a man of gifts.
Ọ̀pọ̀ ń wá ojúrere olórí; gbogbo ènìyàn sì ni ọ̀rẹ́ ẹni tí ó lawọ́.
7 All the brethren of the poor have hated him, Surely also his friends have been far from him, He is pursuing words — they are not!
Gbogbo ará ilé e tálákà ni ó pa á tì, mélòó mélòó ni ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí ń sá fún un! Bí ó tilẹ̀ ń lé wọn kiri pẹ̀lú ẹ̀bẹ̀, kò tilẹ̀ le rí wọn rárá.
8 Whoso is getting heart is loving his soul, He is keeping understanding to find good.
Ẹni tí ó gba ọgbọ́n fẹ́ràn ọkàn ara rẹ̀; ẹni tí ó bá káràmáṣìkí òye yóò gbèrú.
9 A false witness is not acquitted, And whoso breatheth out lies perisheth.
Ajẹ́rìí èké kì yóò lọ láìjìyà ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde yóò parun.
10 Luxury is not comely for a fool, Much less for a servant to rule among princes.
Kò yẹ aláìgbọ́n láti máa gbé nínú ọláńlá, mélòó mélòó bí ó ti burú tó fún ẹrú láti jẹ ọba lórí ọmọ-aládé.
11 The wisdom of a man hath deferred his anger, And his glory [is] to pass over transgression.
Ọgbọ́n ènìyàn a máa fún un ní sùúrù; fún ògo rẹ̀ ni láti fojú fo àṣìṣe dá.
12 The wrath of a king [is] a growl as of a young lion, And as dew on the herb his good-will.
Ìbínú ọba dàbí kíké e kìnnìún, ṣùgbọ́n ojúrere rẹ̀ dàbí ìrì lára koríko.
13 A calamity to his father [is] a foolish son, And the contentions of a wife [are] a continual dropping.
Aṣiwèrè ọmọ jẹ́ ìparun baba rẹ̀, aya tí ó máa ń jà sì dàbí ọ̀ṣọ̀ọ̀rọ̀ òjò.
14 House and wealth [are] the inheritance of fathers, And from Jehovah [is] an understanding wife.
A máa ń jogún ilé àti ọrọ̀ lọ́dọ̀ òbí, ṣùgbọ́n aya olóye láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni.
15 Sloth causeth deep sleep to fall, And an indolent soul doth hunger.
Ọ̀lẹ ṣíṣe máa ń fa oorun sísùn fọnfọn, ebi yóò sì máa pa ènìyàn tí ó lọ́ra.
16 Whoso is keeping the command is keeping his soul, Whoso is despising His ways dieth.
Ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́ ẹ̀kọ́ pa ẹnu rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá kẹ́gàn ọ̀nà rẹ̀ yóò kú.
17 Whoso is lending [to] Jehovah is favouring the poor, And his deed He repayeth to him.
Ẹni tí ó ṣàánú tálákà, Olúwa ní ó yá, yóò sì pín in lérè ohun tí ó ti ṣe.
18 Chastise thy son, for there is hope, And to put him to death lift not up thy soul.
Bá ọmọ rẹ wí nítorí nínú ìyẹn ni ìrètí wà; àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ lọ́wọ́ nínú ìparun un rẹ̀.
19 A man of great wrath is bearing punishment, For, if thou dost deliver, yet again thou dost add.
Ènìyàn onínú-fùfù gbọdọ̀ gba èrè ìwà rẹ̀; bí ìwọ bá gbà á là, ìwọ yóò tún ní láti ṣe é lẹ́ẹ̀kan sí i.
20 Hear counsel and receive instruction, So that thou art wise in thy latter end.
Fetí sí ìmọ̀ràn kí o sì gba ẹ̀kọ́, ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín ìwọ yóò di ọlọ́gbọ́n.
21 Many [are] the purposes in a man's heart, And the counsel of Jehovah it standeth.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ète inú ọkàn ènìyàn, ṣùgbọ́n ìfẹ́ Olúwa ní ó máa ń borí.
22 The desirableness of a man [is] his kindness, And better [is] the poor than a liar.
Ohun tí ènìyàn ń fẹ́ ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀; ó sàn láti jẹ́ tálákà ju òpùrọ́ lọ.
23 The fear of Jehovah [is] to life, And satisfied he remaineth — he is not charged with evil.
Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ìyè wá; nígbà náà ọkàn ń balẹ̀, láìsí ewu.
24 The slothful hath hidden his hand in a dish, Even unto his mouth he bringeth it not back.
Ọ̀lẹ ki ọwọ́ rẹ̀ bọ inú àwo oúnjẹ; kò tilẹ̀ ní mú u padà wá sí ẹnu rẹ̀.
25 A scorner smite, and the simple acts prudently, And give reproof to the intelligent, He understandeth knowledge.
Na ẹlẹ́gàn, òpè yóò sì kọ́gbọ́n; bá olóye ènìyàn wí, yóò sì ní ìmọ̀ sí i.
26 Whoso is spoiling a father causeth a mother to flee, A son causing shame, and bringing confusion.
Ẹni tí ó ṣìkà sí baba rẹ̀, tí ó sì lé ìyá rẹ̀ jáde òun ni ọmọ tí ń ṣe ìtìjú, tí ó sì mú ẹ̀gàn wá.
27 Cease, my son, to hear instruction — To err from sayings of knowledge.
Ọmọ mi, dẹ́kun láti tẹ́tí sí ẹ̀kọ́, tí í mú ni ṣìnà kúrò nínú ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
28 A worthless witness scorneth judgment, And the mouth of the wicked swalloweth iniquity.
Ẹlẹ́rìí búburú fi ìdájọ́ ṣẹ̀sín, ẹnu ènìyàn búburú sì ń gbé ibi mì.
29 Judgments have been prepared for scorners, And stripes for the back of fools!
A ti pèsè ìjìyà sílẹ̀ fún ẹlẹ́gàn; àti pàṣán fún ẹ̀yìn àwọn aṣiwèrè.

< Proverbs 19 >