< Numbers 34 >

1 And Jehovah speaketh unto Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 'Command the sons of Israel, and thou hast said unto them, When ye are coming in unto the land of Canaan — this [is] the land which falleth to you by inheritance, the land of Canaan, by its borders —
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
3 then hath the south quarter been to you from the wilderness of Zin, by the sides of Edom, yea, the south border hath been to you from the extremity of the Salt Sea, eastward;
“‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
4 and the border hath turned round to you from the south to the ascent of Akrabbim, and hath passed on to Zin, and its outgoings have been from the south to Kadesh-Barnea, and it hath gone out at Hazar-Addar, and hath passed on to Azmon;
kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
5 and the border hath turned round from Azmon to the brook of Egypt, and its outgoings have been at the sea.
Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
6 'As to the west border, even the great sea hath been to you a border; this is to you the west border.
Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
7 'And this is to you the north border: from the great sea ye mark out for yourselves mount Hor;
Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
8 from mount Hor ye mark out to go in to Hamath, and the outgoings of the border have been to Zedad;
àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
9 and the border hath gone out to Ziphron, and its outgoings have been at Hazar-Enan; this is to you the north border.
tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
10 'And ye have marked out for yourselves for the border eastward, from Hazar-Enan to Shepham;
Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
11 and the border hath gone down from Shepham to Riblah, on the east of Ain, and the border hath gone down, and hath smitten against the shoulder of the sea of Chinnereth eastward;
Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
12 and the border hath gone down to the Jordan, and its outgoings have been at the Salt Sea; this is for you the land by its borders round about.'
Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
13 And Moses commandeth the sons of Israel, saying, 'This [is] the land which ye inherit by lot, which Jehovah hath commanded to give to the nine tribes and the half of the tribe;
Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
14 for the tribe of the sons of Reuben have received, by the house of their fathers; and the tribe of the children of Gad, by the house of their fathers; and the half of the tribe of Manasseh have received their inheritance;
Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
15 the two tribes and the half of the tribe have received their inheritance beyond the Jordan, [near] Jericho, eastward, at the [sun] -rising.'
Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
16 And Jehovah speaketh unto Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
17 'These [are] the names of the men who give to you the inheritance of the land: Eleazar the priest, and Joshua son of Nun,
“Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
18 and one prince — one prince — for a tribe ye do take to give the land by inheritance.
Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
19 'And these [are] the names of the men: of the tribe of Judah, Caleb son of Jephunneh;
“Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
20 and of the tribe of the sons of Simeon, Shemuel son of Aminihud;
Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
21 of the tribe of Benjamin, Elidad son of Chislon;
Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
22 and of the tribe of the sons of Dan, the prince Bukki son of Jogli;
Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
23 of the sons of Joseph, of the tribe of the sons of Manasseh, the prince Hanniel son of Ephod;
Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
24 and of the tribe of the sons of Ephraim, the prince Kemuel son of Shiphtan;
Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
25 and of the tribe of the sons of Zebulun, the prince Elizaphan son of Parnach;
Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
26 and of the tribe of the sons of Issachar, the prince Paltiel son of Azzan;
Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
27 and of the tribe of the sons of Asher, the prince Ahihud son of Shelomi;
Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
28 and of the tribe of the sons of Naphtali, the prince Pedahel son of Ammihud.'
Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
29 These [are] those whom Jehovah hath commanded to give the sons of Israel inheritance in the land of Canaan.
Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.

< Numbers 34 >