< Nehemiah 10 >

1 And over those sealed [are] Nehemiah the Tirshatha, son of Hachaliah, and Zidkijah,
Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
2 Seraiah, Azariah, Jeremiah,
Seraiah, Asariah, Jeremiah,
3 Pashhur, Amariah, Malchijah,
Paṣuri, Amariah, Malkiah,
4 Huttush, Shebaniah, Malluch,
Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
5 Harim, Meremoth, Obadiah,
Harimu, Meremoti, Obadiah,
6 Daniel, Ginnethon, Baruch,
Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
7 Meshullam, Abijah, Mijamin,
Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
8 Maaziah, Bilgai, Shemaiah; these [are] the priests.
Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
9 And the Levites: both Jeshua son of Azaniah, Binnui of the sons of Henadad, Kadmiel;
Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
10 and their brethren: Shebaniah, Hodijah, Kelita, Pelaiah, Hanan,
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
11 Micha, Rehob, Hashabiah,
Mika, Rehobu, Haṣabiah,
12 Zaccur, Sherebiah, Shebaniah,
Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
13 Hodijah, Bani, Beninu.
Hodiah, Bani àti Beninu.
14 Heads of the people: Parosh, Pahath-Moab, Elam, Zatthu, Bani,
Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
15 Bunni, Azgad, Bebai,
Bunni, Asgadi, Bebai.
16 Adonijah, Bigvai, Adin,
Adonijah, Bigfai, Adini,
17 Ater, Hizkijah, Azzur,
Ateri, Hesekiah, Assuri,
18 Hodijah, Hashum, Bezai,
Hodiah, Haṣumu, Besai,
19 Hariph, Anathoth, Nebai,
Harifu, Anatoti, Nebai,
20 Magpiash, Meshullam, Hezir,
Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
21 Meshezabeel, Zadok, Jaddua,
Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
22 Pelatiah, Hanan, Anaiah,
Pelatiah, Hanani, Anaiah,
23 Hoshea, Hananiah, Hashub,
Hosea, Hananiah, Haṣubu,
24 Hallohesh, Pilha, Shobek,
Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
25 Rehum, Hashabnah, Maaseiah,
Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
26 and Ahijah, Hanan, Anan,
Ahijah, Hanani, Anani,
27 Malluch, Harim, Baanah.
Malluki, Harimu, àti Baanah.
28 And the rest of the people, the priests, the Levites, the gatekeepers, the singers, the Nethinim, and every one who hath been separated from the peoples of the lands unto the law of God, their wives, their sons, and their daughters, every knowing intelligent one,
“Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
29 are laying hold on their brethren, their honourable ones, and coming in to an execration, and in to an oath, to walk in the law of God, that was given by the hand of Moses, servant of God, and to observe and to do all the commands of Jehovah our Lord, and His judgments, and His statutes;
gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
30 and that we give not our daughters to the peoples of the land, and their daughters we take not to our sons;
“A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
31 and the peoples of the land who are bringing in the wares and any corn on the sabbath-day to sell, we receive not of them on the sabbath, and on a holy day, and we leave the seventh year, and usury on every hand.
“Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
32 And we have appointed for ourselves commands, to put on ourselves the third of a shekel in a year, for the service of the house of our God,
“Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
33 for bread of the arrangement, and the continual present, and the continual burnt-offering of the sabbaths, of the new moons, for appointed seasons, and for holy things, and for sin-offerings, to make atonement for Israel, even all the work of the house of our God.
nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
34 And the lots we have caused to fall for the offering of wood, [among] the priests, the Levites, and the people, to bring in to the house of our God, by the house of our fathers, at times appointed, year by year, to burn on the altar of Jehovah our God, as it is written in the law,
“Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
35 and to bring in the first fruits of our ground, and the first fruits of all fruit of every tree, year by year, to the house of Jehovah,
“Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
36 and the firstlings of our sons, and of our cattle, as it is written in the law, and the firstlings of our herds and our flocks, to bring in to the house of our God, to the priests who are ministering in the house of our God.
“Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
37 And the beginning of our dough, and our heave-offerings, and the fruit of every tree, of new wine, and of oil, we bring in to the priests, unto the chambers of the house of our God, and the tithe of our ground to the Levites; and they — the Levites — have the tithes in all the cities of our tillage;
“Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
38 and the priest, son of Aaron, hath been with the Levites in the tithing of the Levites, and the Levites bring up the tithe of the tithe to the house of our God unto the chambers, to the treasure-house;
Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
39 for unto the chambers do they bring in — the sons of Israel and the sons of Levi — the heave-offering of the corn, the new wine, and the oil, and there [are] vessels of the sanctuary, and the priests, those ministering, and the gatekeepers, and the singers, and we do not forsake the house of our God.
Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”

< Nehemiah 10 >