< Joshua 19 >
1 And the second lot goeth out for Simeon, for the tribe of the sons of Simeon, for their families; and their inheritance is in the midst of the inheritance of the sons of Judah,
Kèké kejì jáde fún ẹ̀yà Simeoni, ní agbo ilé, ní agbo ilé. Ìní wọn sì wà ní àárín ilẹ̀ Juda.
2 and they have in their inheritance Beer-Sheba, and Sheba, and Moladah,
Lára ìpín wọn ní: Beerṣeba (tàbí Ṣeba), Molada,
3 and Hazar-Shual, and Balah, and Azem,
Hasari-Ṣuali, Bala, Esemu,
4 and Eltolad, and Bethul, and Hormah,
Eltoladi, Betuli, Horma,
5 and Ziklag, and Beth-Marcaboth, and Hazar-Susah,
Siklagi, Beti-Markaboti, Hasari Susa,
6 and Beth-Lebaoth, and Sharuhen; thirteen cities and their villages.
Beti-Lebaoti àti Ṣarueli, ìlú wọn jẹ́ mẹ́tàlá àti ìletò wọn.
7 Ain, Remmon, and Ether, and Ashan; four cities and their villages;
Aini, Rimoni, Eteri àti Aṣani, ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn,
8 also all the villages which [are] round about these cities, unto Baalath-Beer, Ramoth of the south. This [is] the inheritance of the tribe of the sons of Simeon, for their families;
àti gbogbo àwọn agbègbè ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Beeri (Rama ní gúúsù). Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Simeoni, agbo ilé, ní agbo ilé.
9 out of the portion of the sons of Judah [is] the inheritance of the sons of Simeon, for the portion of the sons of Judah hath been too much for them, and the sons of Simeon inherit in the midst of their inheritance.
A mú ogún ìní àwọn ọmọ Simeoni láti ìpín Juda, nítorí ìpín Juda pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Simeoni gba ìní wọn ní àárín ilẹ̀ Juda.
10 And the third lot goeth up for the sons of Zebulun, for their families; and the border of their inheritance is unto Sarid,
Kèké kẹta jáde fún Sebuluni, ní agbo ilé ní agbo ilé ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Saridi.
11 and their border hath gone up towards the sea, and Maralah, and come against Dabbasheth, and come unto the brook which [is] on the front of Jokneam,
Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Marala, ó sì dé Dabbeṣeti, ó sì lọ títí dé odo ní ẹ̀bá Jokneamu.
12 and turned back from Sarid eastward, at the sun-rising, by the border of Chisloth-Tabor, and gone out unto Daberath, and gone up to Japhia,
Ó sì yípadà sí ìlà-oòrùn láti Saridi sí ìhà ìlà-oòrùn dé ilẹ̀ Kisiloti-Tabori, ó sì lọ sí Daberati, ó sì gòkè lọ sí Jafia.
13 and thence it hath passed over eastward, to the east, to Gittah-Hepher, [to] Ittah-Kazin, and gone out [to] Rimmon-Methoar to Neah;
Nígbà náà ní o lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Gati-Heferi àti Eti-Kaṣini, ó sì jáde ní Rimoni, ó sì yí sí ìhà Nea.
14 and the border hath gone round about it, from the north to Hannathon; and its outgoings have been [in] the valley of Jiphthah-El,
Ní ibẹ̀, ààlà sì yíká ní ìhà àríwá lọ sí Hnatoni ó sì pín ní àfonífojì Ifita-Eli.
15 and Kattath, and Nahallal, and Shimron, and Idalah, and Beth-Lehem; twelve cities and their villages.
Lára wọn ni Katati, Nahalali, Ṣimroni, Idala àti Bẹtilẹhẹmu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
16 This [is] the inheritance of the sons of Zebulun, for their families, these cities and their villages.
Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní Sebuluni, ní agbo ilé agbo ilé.
17 For Issachar hath the fourth lot gone out, for the sons of Issachar, for their families;
Kèké kẹrin jáde fún Isakari, agbo ilé ní agbo ilé.
18 and their border is [at] Jezreel, and Chesulloth, and Shunem,
Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Jesreeli, Kesuloti, Ṣunemu,
19 and Haphraim, and Shihon, and Anaharath,
Hafraimu, Ṣihoni, Anaharati,
20 and Rabbith, and Kishion, and Abez,
Rabiti, Kiṣioni, Ebesi,
21 and Remeth, and En-Gannim, and En-Haddah, and Beth-Pazzez;
Remeti, Eni-Gannimu, Eni-Hada àti Beti-Pasesi.
22 and the border hath touched against Tabor, and Shahazimah, and Beth-Shemesh, and the outgoings of their border have been [at] the Jordan; sixteen cities and their villages.
Ààlà náà sì dé Tabori, Ṣahasuma, àti Beti-Ṣemeṣi, ó sì pin ní Jordani. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
23 This [is] the inheritance of the tribe of the sons of Issachar, for their families, the cities and their villages.
Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní ẹ̀yà Isakari, ní agbo ilé agbo ilé.
24 And the fifth lot goeth out for the tribe of the sons of Asher, for their families;
Kèké karùn-ún jáde fún ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
25 and their border is Helkath, and Hali, and Beten, and Achshaph,
Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Helikati, Hali, Beteni, Akṣafu,
26 and Alammelech, and Amad, and Misheal; and it toucheth against Carmel westward, and against Shihor-Libnath;
Allameleki, Amadi, àti Miṣali. Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ààlà náà dé Karmeli àti Ṣihori-Libinati.
27 and hath turned back, at the sun-rising, [to] Beth-Dagon, and come against Zebulun, and against the valley of Jiphthah-El toward the north of Beth-Emek, and Neiel, and hath gone out unto Cabul on the left,
Nígbà náà ni o yí sí ìhà ìlà-oòrùn Beti-Dagoni, dé Sebuluni àti àfonífojì Ifita-Eli, ó sì lọ sí àríwá sí Beti-Emeki àti Neieli, ó sì kọjá lọ sí Kabulu ní apá òsì.
28 and Hebron, and Rehob, and Hammon, and Kanah, unto great Zidon;
Ó sì lọ sí Abdoni, Rehobu, Hammoni àti Kana títí dé Sidoni ńlá.
29 and the border hath turned back to Ramah, and unto the fenced city Tyre; and the border hath turned back to Hosah, and its outgoings are at the sea, from the coast to Achzib,
Ààlà náà sì tẹ̀ sí ìhà Rama, ó sì lọ sí ìlú olódi Tire, ó sì yà sí Hosa, ó sì jáde ní Òkun Ńlá ní ilẹ̀ Aksibu,
30 and Ummah, and Aphek, and Rehob; twenty and two cities and their villages.
Uma, Afeki àti Rehobu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlélógún àti ìletò wọn.
31 This [is] the inheritance of the tribe of the sons of Asher, for their families, these cities and their villages.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
32 For the sons of Naphtali hath the sixth lot gone out, for the sons of Naphtali, for their families;
Ìpín kẹfà jáde fún Naftali, agbo ilé ní agbo ilé,
33 and their border is from Heleph, from Allon in Zaanannim, and Adami, Nekeb, and Jabneel, unto Lakkum, and its outgoings are [at] the Jordan;
ààlà wọn lọ láti Helefi àti igi ńlá ní Saananimu nímù; kọjá lọ sí Adami Nekebu àti Jabneeli dé Lakkumu, ó sì pín ní Jordani.
34 and the border hath turned back westward [to] Aznoth-Tabor, and gone out thence to Hukkok, and touched against Zebulun on the south, and against Asher it hath touched on the west, and against Judah [at] the Jordan, at the sun-rising;
Ààlà náà gba ìhà ìwọ̀-oòrùn lọ sí Asnoti-Tabori ó sì jáde ní Hukoki. Ó sì dé Sebuluni, ní ìhà gúúsù Aṣeri ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Juda ní Jordani ní ìhà ìlà-oòrùn.
35 and the cities of defence [are] Ziddim, Zer, and Hammath, Rakkath, and Chinnereth,
Àwọn ìlú olódi sì Siddimu, Seri, Hamati, Rakàti, Kinnereti,
36 and Adamah, and Ramah, and Hazor,
Adama, Rama Hasori,
37 and Kedesh, and Edrei, and En-Hazor,
Kedeṣi, Edrei, Eni-Aṣọri,
38 and Iron, and Migdal-El, Horem, and Beth-Anath, and Beth-Shemesh; nineteen cities and their villages.
Ironi, Migdali-Eli, Horemu, Beti-Anati àti Beti-Ṣemeṣi. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mọ́kàndínlógún àti ìletò wọn.
39 This [is] the inheritance of the tribe of the sons of Naphtali, for their families, the cities and their villages.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Naftali, ní agbo ilé sí agbo ilé.
40 For the tribe of the sons of Dan, for their families, hath the seventh lot gone out;
Ìbò kéje jáde fún ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé ní agbo ilé.
41 and the border of their inheritance is Zorah, and Eshtaol, and Ir-Shemesh,
Ilẹ̀ ìní wọn nìwọ̀nyí: Sora, Eṣtaoli, Iri-Ṣemesi,
42 and Shalabbin, and Aijalon, and Jethlah,
Ṣaalabini, Aijaloni, Itila,
43 and Elon, and Thimnathah, and Ekron,
Eloni, Timna, Ekroni,
44 and Eltekeh, and Gibbethon, and Baalath,
Elteke, Gibetoni, Baalati,
45 and Jehud, and Bene-Barak, and Gath-Rimmon,
Jehudu, Bene-Beraki, Gati-Rimoni,
46 and Me-Jarkon, and Rakkon, with the border over-against Japho.
Me Jakoni àti Rakkoni, pẹ̀lú ilẹ̀ tí ó kọjú sí Joppa.
47 And the border of the sons of Dan goeth out from them, and the sons of Dan go up and fight with Leshem, and capture it, and smite it by the mouth of the sword, and possess it, and dwell in it, and call Leshem, Dan, according to the name of Dan their father.
(Ṣùgbọ́n àwọn ará Dani ní ìṣòro láti gba ilẹ̀ ìní wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ, wọ́n sì kọlu Leṣemu, wọ́n sì gbà á, wọ́n sì fi idà kọlù ú, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀. Wọ́n sì ń gbé ní Leṣemu, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dani orúkọ baba ńlá wọn).
48 This [is] the inheritance of the tribe of the sons of Dan, for their families, these cities and their villages.
Àwọn ìlú wọ́n yí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé agbo ilé.
49 And they finish to give the land in inheritance, by its borders, and the sons of Israel give an inheritance to Joshua son of Nun in their midst;
Nígbà tí wọ́n ti parí pínpín ilẹ̀ náà ní ìpín ti olúkúlùkù, àwọn ará Israẹli fún Joṣua ọmọ Nuni ní ìní ní àárín wọn,
50 by the command of Jehovah they have given to him the city which he asked, Timnath-Serah, in the hill-country of Ephraim, and he buildeth the city and dwelleth in it.
bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n fún un ni ìlú tí ó béèrè fún, Timnati Serah ní ìlú òkè Efraimu. Ó sì kọ́ ìlú náà, ó sì ń gbé ibẹ̀.
51 These [are] the inheritances which Eleazar the priest, and Joshua son of Nun, and the heads of the fathers of the tribes of the sons of Israel, have caused to inherit by lot, in Shiloh, before Jehovah, at the opening of the tent of meeting; and they finish to apportion the land.
Wọ̀nyí ni àwọn ilẹ̀ tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti àwọn olórí ẹ̀yà agbo ilé Israẹli fi ìbò pín ní Ṣilo ní iwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Báyìí ni wọ́n parí pínpín ilẹ̀ náà.