< Esther 2 >
1 After these things, at the ceasing of the fury of the king Ahasuerus, he hath remembered Vashti, and that which she did, and that which hath been decreed concerning her;
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Ahaswerusi ọba sì dáwọ́ ìbínú un rẹ̀ dúró, ó rántí i Faṣti àti ohun tí ó ti ṣe àti àṣẹ tí ó pa nípa tirẹ̀.
2 and servants of the king, his ministers, say, 'Let them seek for the king young women, virgins, of good appearance,
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ ọba tí ó wà ní ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a wá ọmọbìnrin arẹwà tí kò ì ti mọ ọkùnrin rí fún ọba.
3 and the king doth appoint inspectors in all provinces of his kingdom, and they gather every young woman — virgin, of good appearance — unto Shushan the palace, unto the house of the women, unto the hand of Hege eunuch of the king, keeper of the women, and to give their purifications,
Àti pé kí ọba kí ó yan àwọn aláṣẹ ní gbogbo agbègbè ilẹ̀ ọba láti kó gbogbo àwọn arẹwà ọmọbìnrin wọ̀nyí jọ sí ilé àwọn obìnrin ní ilé ìṣọ́ Susa. Kí a kó wọn fún ìtọ́jú Hegai, ìwẹ̀fà ọba, ẹni tí ó ṣe olùtọ́jú àwọn obìnrin; kí a ṣe ìtọ́jú u wọn dáradára.
4 and the young woman who is good in the eyes of the king doth reign instead of Vashti;' and the thing is good in the eyes of the king, and he doth so.
Nígbà náà kí ọmọbìnrin tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn kí ó jẹ́ ayaba dípò Faṣti.” Ìmọ̀ràn yìí tẹ́ ọba lọ́rùn, ó sì tẹ̀lé e.
5 A man, a Jew, there hath been in Shushan the palace, and his name [is] Mordecai son of Jair, son of Shimei, son of Kish, a Benjamite —
Ó sì ṣe ní ìgbà náà ará a Júù kan wà ní ilé ìṣọ́ ti Susa, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mordekai ọmọ Jairi, ọmọ Ṣimei, ọmọ Kiṣi, ẹ̀yà Benjamini,
6 who had been removed from Jerusalem with the removal that was removed with Jeconiah king of Judah, whom Nebuchadnezzar king of Babylon removed —
ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti gbé lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu, lára àwọn tí wọ́n kó ní ìgbèkùn pẹ̀lú ọba Jekoniah ọba Juda.
7 and he is supporting Hadassah — she [is] Esther — daughter of his uncle, for she hath neither father nor mother, and the young woman [is] of fair form, and of good appearance, and at the death of her father and her mother hath Mordecai taken her to him for a daughter.
Mordekai ní arákùnrin kan ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Hadassa, ẹni tí ó tọ́ dàgbà nítorí tí kò ní baba bẹ́ẹ̀ sì ni kò ní ìyá. Obìnrin yìí, ẹni tí a tún mọ̀ sí Esteri, ó dára ó sì lẹ́wà, Mordekai mú u gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀ nígbà tí baba àti ìyá rẹ̀ ti kú.
8 And it cometh to pass, in the word of the king, even his law, being heard, and in many young women being gathered unto Shushan the palace, unto the hand of Hegai, that Esther is taken unto the house of the king, unto the hand of Hegai, keeper of the women,
Nígbà tí a ti kéde òfin àti àṣẹ ọba, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọbìnrin ni a kó wá sí ilé ti ìṣọ́ Susa, sí abẹ́ ìtọ́jú Hegai. A sì mú Esteri náà wá sí ààfin ọba pẹ̀lú, a fà á lé Hegai lọ́wọ́, ẹni tí ó jẹ́ alábojútó ilé àwọn obìnrin.
9 and the young woman is good in his eyes, and she receiveth kindness before him, and he hasteneth her purifications and her portions — to give to her, and the seven young women who are provided — to give to her, from the house of the king, and he changeth her and her young women to a good [place in] the house of the women.
Ọmọbìnrin náà sì wù ú, ó sì rí ojúrere rẹ̀, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ó pèsè àwọn ohun tí ó dára àti oúnjẹ pàtàkì fún un. Ó sì yan àwọn ìránṣẹ́bìnrin wúńdíá méje láti ààfin ọba òun àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin náà lọ sí ibi tí ó dára jù nínú ilé àwọn obìnrin.
10 Esther hath not declared her people, and her kindred, for Mordecai hath laid a charge on her that she doth not declare [it];
Esteri kò tí ì sọ nípa àwọn ènìyàn àti ìdílé e rẹ̀, nítorí Mordekai ti pàṣẹ fún un pé kí ó má ṣe sọ ọ́.
11 and during every day Mordecai is walking up and down before the court of the house of the women to know the welfare of Esther, and what is done with her.
Ní ojoojúmọ́ ni Mordekai máa ń rìn ní iwájú ilé àwọn obìnrin láti wo bí Esteri ṣe wà ní àlàáfíà àti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.
12 And in the drawing nigh of the turn of each young woman to come in unto the king Ahasuerus, at the end of there being to her — according to the law of the women — twelve months, for so they fulfil the days of their purifications; six months with oil of myrrh, and six months with spices, and with the purifications of women,
Kí àkókò tó tó fún obìnrin kọ̀ọ̀kan láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Ahaswerusi, ó ní láti lo ohun èlò tí ń mú ara lẹ́wà tí a yàn fún àwọn obìnrin fún oṣù méjìlá, yóò lo òróró òjìá fún oṣù mẹ́fà, yóò sì lo ohun èlò olóòórùn dídùn tùràrí àti ìpara fún oṣù mẹ́fà pẹ̀lú.
13 and with this the young woman hath come in unto the king, all that she saith is given to her, to go in with her, out of the house of the women, unto the house of the king;
Báyìí ni yóò ṣe lọ síwájú ọba: ohunkóhun tí ó bá béèrè ni wọ́n fi fún un láti inú ilé àwọn obìnrin lọ sí ààfin ọba.
14 in the evening she hath gone in, and in the morning she hath turned back unto the second house of the women, unto the hand of Shaashgaz eunuch of the king, keeper of the concubines; she cometh not in any more unto the king except the king hath delighted in her, and she hath been called by name.
Ní alẹ́ ni yóò lọ síbẹ̀, tí ó bá sì di òwúrọ̀ yóò padà sí ilé kejì nínú ilé àwọn obìnrin ní abẹ́ ìtọ́jú Ṣaaṣigasi ìwẹ̀fà ọba ẹni tí ó máa ń ṣe ìtọ́jú àwọn àlè. Òun kò ní lọ sí ọ̀dọ̀ ọba mọ́ àyàfi tí inú ọba bá dùn sí i, tí ó sì ránṣẹ́ pé ó ní orúkọ obìnrin.
15 And in the drawing nigh of the turn of Esther — daughter of Abihail, uncle of Mordecai, whom he had taken to him for a daughter — to come in unto the king, she hath not sought a thing except that which Hegai eunuch of the king, keeper of the women, saith, and Esther is receiving grace in the eyes of all seeing her.
Nígbà tí ó kan Esteri (ọmọbìnrin tí Mordekai gbà ṣe ọmọ, ọmọbìnrin arákùnrin rẹ̀ tí ó ń jẹ́ Abihaili) láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba, wọn kò béèrè fún ohunkóhun ju èyí tí Hegai, ìwẹ̀fà ọba ẹni tí ó jẹ́ olùtọ́jú ilé àwọn obìnrin sọ pé kí ó ṣe lọ. Esteri sì rí ojúrere lọ́dọ̀ gbogbo àwọn tí ó rí i.
16 And Esther is taken unto the king Ahasuerus, unto his royal house, in the tenth month — it [is] the month of Tebeth — in the seventh year of his reign,
A mú Esteri lọ síwájú ọba Ahaswerusi ní ibùgbé ọba ní oṣù kẹwàá, tí ó jẹ́ oṣù Tebeti, ní ọdún keje ìjọba rẹ̀.
17 and the king loveth Esther above all the women, and she receiveth grace and kindness before him above all the virgins, and he setteth a royal crown on her head, and causeth her to reign instead of Vashti,
Esteri sì wu ọba ju àwọn obìnrin tókù lọ, Ó sì rí ojúrere àti oore-ọ̀fẹ́ gbà ju ti àwọn wúńdíá tókù lọ. Nítorí náà ó fi adé ọba dé e ní orí ó sì fi ṣe ayaba dípò Faṣti.
18 and the king maketh a great banquet to all his heads and his servants — the banquet of Esther — and a release to the provinces hath made, and giveth gifts as a memorial of the king.
Ọba sì ṣe àsè ńlá, àsè Esteri, fún gbogbo àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè e rẹ̀. Ó sì kéde ìsinmi jákèjádò ìgbèríko ó sì pín ẹ̀bùn fún wọn pẹ̀lú bí ọba ṣe lawọ́ tó.
19 And in the virgins being gathered a second time, then Mordecai is sitting in the gate of the king;
Nígbà tí àwọn wúńdíá tún péjọ ní ìgbà kejì, Mordekai jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba.
20 Esther is not declaring her kindred and her people, as Mordecai hath laid a charge upon her, and the saying of Mordecai Esther is doing as when she was truly with him.
Ṣùgbọ́n Esteri pa àṣírí ìdílé e rẹ̀ àti ibi tí ó ti wá mọ́ gẹ́gẹ́ bí Mordekai ṣe sọ fún un pé kí ó ṣe, nítorí tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ tí Mordekai fún un gẹ́gẹ́ bí ó ṣe máa ń ṣe nígbà tí ó wà ní ọ̀dọ̀ Mordekai.
21 In those days, when Mordecai is sitting in the gate of the king, hath Bigthan been wroth, and Teresh, (two of the eunuchs of the king, the keepers of the threshold, ) and they seek to put forth a hand on king Ahasuerus,
Ní àsìkò tí Mordekai jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba, Bigitana àti Tereṣi, àwọn ìjòyè ọba méjì tí wọ́n máa ń ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà, wọ́n bínú, wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa ọba Ahaswerusi.
22 and the thing is known to Mordecai, and he declareth [it] to Esther the queen, and Esther speaketh to the king in the name of Mordecai,
Ṣùgbọ́n Mordekai sì mọ̀ nípa ọ̀tẹ̀ náà, ó sọ̀ fún ayaba Esteri, Esteri sì sọ fún ọba, wọ́n sì fi ọlá fún Mordekai.
23 and the thing is sought out, and found, and they are hanged both of them on a tree, and it is written in the book of the Chronicles before the king.
Nígbà tí wọ́n sì wádìí ọ̀rọ̀ náà tí ó sì jásí òtítọ́, a sì so àwọn ìjòyè méjèèjì náà kọ́. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni a kọ sínú ìwé ìtàn ní iwájú ọba.