< 1 Chronicles 2 >

1 These [are] sons of Israel: Reuben, Simeon, Levi, and Judah, Issachar, and Zebulun,
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
2 Dan, Joseph, and Benjamin, Naphtali, Gad, and Asher.
Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
3 Sons of Judah: Er, and Onan, and Shelah, three have been born to him of a daughter of Shua the Canaanitess. And Er, first-born of Judah, is evil in the eyes of Jehovah, and He putteth him to death.
Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
4 And Tamar his daughter-in-law hath borne to him Pharez and Zerah. All the sons of Judah [are] five.
Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
5 Sons of Pharez: Hezron, and Hamul.
Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
6 And sons of Zerah: Zimri, and Ethan, and Heman, and Calcol, and Dara; all of them five.
Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
7 And sons of Carmi: Achar, troubler of Israel, who trespassed in the devoted thing.
Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
8 And sons of Ethan: Azariah.
Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
9 And sons of Hezron who were born to him; Jerahmeel, and Ram, and Chelubai.
Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
10 And Ram begat Amminadab, and Amminadab begat Nahshon, prince of the sons of Judah;
Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
11 and Nahshon begat Salma, and Salma begat Boaz,
Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
12 and Boaz begat Obed, and Obed begat Jesse;
Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
13 and Jesse begat his first-born Eliab, and Abinadab the second, and Shimea the third,
Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
14 Nethaneel the fourth, Raddai the fifth,
ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
15 Ozem the sixth, David the seventh,
ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
16 and their sisters Zeruiah and Abigail. And sons of Zeruiah: Abishai, and Joab, and Asah-El — three.
Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
17 And Abigail hath borne Amasa, and the father of Amasa [is] Jether the Ishmeelite.
Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
18 And Caleb son of Hezron hath begotten Azubah, Isshah, and Jerioth; and these [are] her sons: Jesher, and Shobab, and Ardon.
Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
19 And Azubah dieth, and Caleb taketh to him Ephrath, and she beareth to him Hur.
Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
20 And Hur begat Uri, and Uri begat Bezaleel.
Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
21 And afterwards hath Hezron gone in unto a daughter of Machir father of Gilead, and he hath taken her, and he [is] a son of sixty years, and she beareth to him Segub.
Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
22 And Segub begat Jair, and he hath twenty and three cities in the land of Gilead,
Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
23 and he taketh Geshur and Aram, the small villages of Jair, from them, with Kenath and its small towns, sixty cities — all these [belonged to] the sons of Machir father of Gilead.
(Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
24 And after the death of Hezron in Caleb-Ephratah, then the wife of Hezron, Abijah, even beareth to him Asshur, father of Tekoa.
Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
25 And sons of Jerahmeel, first-born of Hezron, are: the first-born Ram, and Bunah, and Oren, and Ozem, Ahijah.
Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
26 And Jerahmeel hath another wife, and her name [is] Atarah, she [is] mother of Onam.
Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
27 And sons of Ram, first-born of Jerahmeel, are Maaz, and Jamin, and Eker.
Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
28 And sons of Onam are Shammai and Jada. And sons of Shammai: Nadab and Abishur.
Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
29 And the name of the wife of Abishur [is] Abihail, and she beareth to him Ahban and Molid.
Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
30 And sons of Nadab: Seled, and Appaim; and Seled dieth without sons.
Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
31 And sons of Appaim: Ishi. And sons of Ishi: Sheshan. And sons of Sheshan: Ahlai.
Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
32 And sons of Jada, brother of Shammai: Jether, and Jonathan: and Jether dieth without sons.
Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
33 And sons of Jonathan: Peleth, and Zaza. These were sons of Jerahmeel.
Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
34 And Sheshan had no sons, but daughters, and Sheshan hath a servant, an Egyptian, and his name [is] Jarha,
Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
35 and Sheshan giveth his daughter to Jarha his servant for a wife, and she beareth to him Attai;
Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
36 and Attai begat Nathan, and Nathan begat Zabad,
Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
37 and Zabad begat Ephlal, and Ephlal begat Obed,
Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
38 and Obed begat Jehu,
Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
39 and Jehu begat Azariah, and Azariah begat Helez, and Helez begat Eleasah,
Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
40 and Eleasah begat Sismai, and Sismai begat Shallum,
Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
41 and Shallum begat Jekamiah, and Jekamiah begat Elishama.
Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
42 And sons of Caleb brother of Jerahmeel: Mesha his first-born, he [is] father of Ziph; and sons of Mareshah: Abi-Hebron.
Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
43 And sons of Hebron: Korah, and Tappuah, and Rekem, and Shema.
Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
44 And Shema begat Raham father of Jorkoam, and Rekem begat Shammai.
Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
45 And a son of Shammai [is] Maon, and Maon [is] father of Beth-Zur.
Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
46 And Ephah concubine of Caleb bare Haran, and Moza, and Gazez; and Haran begat Gazez.
Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
47 And sons of Jahdai: Regem, and Jotham, and Geshem, and Pelet, and Ephah, and Shaaph.
Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
48 The concubine of Caleb, Maachah, bare Sheber and Tirhanah;
Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
49 and she beareth Shaaph father of Madmannah, Sheva father of Machbenah, and father of Gibea; and a daughter of Caleb [is] Achsa.
Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
50 These were sons of Caleb son of Hur, first-born of Ephrathah: Shobal father of Kirjath-Jearim,
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
51 Salma father of Beth-Lehem, Hareph father of Beth-Gader.
Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
52 And there are sons to Shobal father of Kirjath-Jearim: Haroeh, half of the Menuhothite;
Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
53 and the families of Kirjath-Jearim: the Ithrite, and the Puhite, and the Shumathite, and the Mishraite: from these went out the Zareathite, and the Eshtaulite.
Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
54 Sons of Salma: Beth-Lehem, and the Netophathite, Atroth, Beth-Joab, and half of the Menuhothite, the Zorite;
Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
55 and the families of the scribes the inhabitants of Jabez: Tirathites, Shimeathites, Suchathites. They [are] the Kenites, those coming of Hammath father of the house of Rechab.
àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.

< 1 Chronicles 2 >