< Ruth 1 >

1 In the daies of o iuge, whanne iugis weren souereynes, hungur was maad in the lond; and a man of Bethleem of Juda yede to be a pylgrym in the cuntrei of Moab, with his wijf and twey fre sones.
Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
2 He was clepid Elymelech, and his wijf Noemy, and the twey sones, `the oon was clepid Maalon, and the tother Chelion, Effrateis of Bethleem of Juda; and thei entriden in to the cuntrey of Moab, and dwelliden there.
Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
3 And Elymelech, the hosebonde of Noemy, diede, and sche lefte with the sones;
Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
4 and thei token wyues of Moab, of whiche wyues oon was clepid Orpha, the tother Ruth. And the sones dwelliden there ten yeer,
Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
5 and bothe dieden, that is, Maalon and Chelion; and the womman lefte, and was maad bare of twey fre sones, and hosebonde.
Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
6 And sche roos to go with euer eithir wijf of hir sones in to hir cuntrey fro the cuntrey of Moab; for sche hadde herd, that the Lord hadde biholde his puple, and hadde youe `metis to hem.
Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
7 Therfor sche yede out of the place of hir pilgrymage with euer either wijf of hir sones; and now sche was set in the weie of turnyng ayen in to the lond of Juda,
Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
8 and sche seide to hem, Go ye in to `the hows of youre modir; the Lord do mercy with you, as ye diden with the deed men, and with me;
Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
9 the Lord yyue to you to fynde reste in the howsis of hosebondis, whiche ye schulen take. And sche kiste hem. Whiche bigunnen to wepe with `vois reisid,
Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
10 and to seie, We schulen go with thee to thi puple.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
11 To whiche sche answeride, My douytris, turne ye ayen, whi comen ye with me? Y haue no more sones in my wombe, that ye moun hope hosebondis of me; my douytris of Moab, turne ye ayen, and go;
Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
12 for now Y am maad eeld, and Y am not able to boond of mariage; yhe, thouy Y myyte conseyue in this nyyt,
Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
13 and bere sones, if ye wolen abide til thei wexen, and fillen the yeris of mariage, `ye schulen sunner be eld wymmen than ye schulen be weddid; I biseche, `nyle ye, my douytris, for youre angwische oppressith me more, and the hond of the Lord yede out ayens me.
ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
14 Therfor, whanne the vois was reisid, eft thei bigunnen to wepe. Orpha kisside `the modir of hir hosebonde, and turnede ayen, and Ruth `cleuyde to `the modir of hir hosebonde.
Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
15 To whom Noemy seide, Lo! thi kyneswomman turnede ayen to hir puple, and to hir goddis; go thou with hir.
Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
16 And sche answeride, Be thou not `aduersarye to me, that Y forsake thee, and go awei; whidur euer thou schalt go, Y schal go, and where thou schalt dwelle, and Y schal dwelle togidere; thi puple is my puple, and thi God is my God;
Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
17 what lond schal resseyue thee diynge, Y schal die ther ynne, and there Y schal take place of biriyng; God do to me these thingis, and adde these thingis, if deeth aloone schal not departe me and thee.
Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
18 Therfor Noemy siy, that Ruth hadde demyde with stidefast soule to go with hir, and sche nolde be ayens hir, nether counseile ferthere turnynge ayen `to her cuntrei men.
Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
19 And thei yeden forth togidere, and camen in to Bethleem; and whanne thei entriden in to the citee, swift fame roos anentis alle men, and wymmen seiden, This is thilke Noemy.
Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
20 To whiche sche seide, Clepe ye not me Noemy, that is, fair, but `clepe ye me Mara, that is, bittere; for Almyyti God hath fillid me greetli with bitternesse.
Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
21 Y yede out ful, and the Lord ledde me ayen voide; whi therfor clepen ye me Noemy, whom the Lord hath `maad low, and Almyyti God hath turmentid?
Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
22 Therfor Noemy cam with Ruth of Moab, `the wijf of hir sone, fro the lond of hir pilgrimage, and turnede ayen in to Bethleem, whanne barli was ropun first.
Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.

< Ruth 1 >