< Psalms 66 >

1 To the victorie, the song of salm.
Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
2 Al the erthe, make ye ioie hertli to God, seie ye salm to his name; yyue ye glorie to his heriyng.
Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
3 Seie ye to God, Lord, thi werkis ben dredeful; in the multitude of thi vertu thin enemyes schulen lie to thee.
Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
4 God, al the erthe worschipe thee, and synge to thee; seie it salm to thi name.
Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
5 Come ye and se ye the werkis of God; ferdful in counseils on the sones of men.
Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
6 Which turnede the see in to drie lond; in the flood thei schulen passe with foot, there we schulen be glad in hym.
Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
7 Which is Lord in his vertu withouten ende, hise iyen biholden on folkis; thei that maken scharp be not enhaunsid in hem silf.
Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
8 Ye hethen men, blesse oure God; and make ye herd the vois of his preising.
Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
9 That hath set my soule to lijf, and yaf not my feet in to stiryng.
Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
10 For thou, God, hast preued vs; thou hast examyned vs bi fier, as siluer is examyned.
Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
11 Thou leddist vs in to a snare, thou puttidist tribulaciouns in oure bak;
Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
12 thou settidist men on oure heedis. We passiden bi fier and water; and thou leddist vs out in to refreschyng.
Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
13 I schal entre in to thin hous in brent sacrifices; Y schal yelde to thee my vowis,
Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
14 which my lippis spaken distinctly. And my mouth spake in my tribulacioun;
ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
15 Y shal offre to thee brent sacrificis ful of merowy, with the brennyng of rammes; Y schal offre to thee oxis with buckis of geet.
Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
16 Alle ye that dreden God, come and here, and Y schal telle; hou grete thingis he hath do to my soule.
Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
17 I criede to hym with my mouth; and Y ioyede fulli vndir my tunge.
Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
18 If Y bihelde wickidnesse in myn herte; the Lord schal not here.
Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
19 Therfor God herde; and perseyuede the vois of my bisechyng.
ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
20 Blessid be God; that remeued not my preyer, and `took not awei his merci fro me.
Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!

< Psalms 66 >