< Psalms 38 >
1 `The salm of Dauid, to bythenke on the sabat. Lord, repreue thou not me in thi strong veniaunce; nether chastice thou me in thin ire.
Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
2 For thin arowis ben fitchid in me; and thou hast confermed thin hond on me.
Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin, ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
3 Noon helthe is in my fleisch fro the face of thin ire; no pees is to my boonys fro the face of my synnes.
Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ; kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
4 For my wickidnessis ben goon ouer myn heed; as an heuy birthun, tho ben maad heuy on me.
Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀; wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
5 Myn heelid woundis weren rotun, and ben brokun; fro the face of myn vnwisdom.
Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́ nítorí òmùgọ̀ mi.
6 I am maad a wretche, and Y am bowid doun til in to the ende; al dai Y entride sorewful.
Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
7 For my leendis ben fillid with scornyngis; and helthe is not in my fleisch.
Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
8 I am turmentid, and maad low ful greetli; Y roride for the weilyng of myn herte.
Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ; mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
9 Lord, al my desire is bifor thee; and my weilyng is not hid fro thee.
Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ; ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
10 Myn herte is disturblid in me, my vertu forsook me; and the liyt of myn iyen `forsook me, and it is not with me.
Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀; bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
11 My frendis and my neiyboris neiyiden; and stoden ayens me. And thei that weren bisidis me stoden afer;
Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi, àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
12 and thei diden violence, that souyten my lijf. And thei that souyten yuels to me, spaken vanytees; and thouyten gilis al dai.
Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi; àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun, wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
13 But Y as a deef man herde not; and as a doumb man not openynge his mouth.
Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀; àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
14 And Y am maad as a man not herynge; and not hauynge repreuyngis in his mouth.
Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀, àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
15 For, Lord, Y hopide in thee; my Lord God, thou schalt here me.
Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè; ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
16 For Y seide, Lest ony tyme myn enemyes haue ioye on me; and the while my feet ben mouyd, thei spaken grete thingis on me.
Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí; nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
17 For Y am redi to betyngis; and my sorewe is euere in my siyt.
Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú, ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
18 For Y schal telle my wickidnesse; and Y schal thenke for my synne.
Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi; àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
19 But myn enemyes lyuen, and ben confermed on me; and thei ben multiplyed, that haten me wickidli.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
20 Thei that yelden yuels for goodis, backbitiden me; for Y suede goodnesse.
Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi àwọn ni ọ̀tá mi nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
21 My Lord God, forsake thou not me; go thou not awei fro me.
Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa! Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
22 Lord God of myn helthe; biholde thou in to myn help.
Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa, Olùgbàlà mi.