< Psalms 20 >

1 To victorie, the salm of Dauid. The Lord here thee in the dai of tribulacioun; the name of God of Jacob defende thee.
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Kí Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú; kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
2 Sende he helpe to thee fro the hooli place; and fro Syon defende he thee.
Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́ kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
3 Be he myndeful of al thi sacrifice; and thi brent sacrifice be maad fat.
Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. (Sela)
4 Yyue he to thee aftir thin herte; and conferme he al thi counsel.
Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
5 We schulen be glad in thin helthe; and we schulen be magnyfied in the name of oure God.
Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa. Kí Olúwa kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.
6 The Lord fille alle thin axyngis; nowe Y haue knowe, that the Lord hath maad saaf his crist. He schal here hym fro his hooly heuene; the helthe of his riyt hond is in poweris.
Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé, Olúwa pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́. Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
7 Thes in charis, and these in horsis; but we schulen inwardli clepe in the name of oure Lord God.
Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin, ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.
8 Thei ben boundun, and felden doun; but we han rise, and ben reisid.
Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú, ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
9 Lord, make thou saaf the kyng; and here thou vs in the dai in which we inwardli clepen thee.
Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba! Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!

< Psalms 20 >