< Numbers 23 >

1 And Balaam seide to Balaach, Bilde thou here to me seuene auteris, and make redi so many caluys, and rammes of the same noumbre.
Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.”
2 And whanne he hadde do bi the word of Balaam, thei puttiden a calf and a ram to gidere on the auter.
Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
3 And Balaam seide to Balaach, Stond thou a litil while bisidis thi brent sacrifice, while Y go, if in hap the Lord meete me; and Y schal `speke to thee what euer thing he schal comaunde.
Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.
4 And whanne he hadde go swiftli, God cam to hym; and Balaam spak to hym, and seide, Y reiside seuene auteris, and Y puttide a calf and a ram aboue.
Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”
5 Forsothe the Lord `puttide a word in his mouth, and seide, Turne ayen to Balaach, and thou schalt speke these thingis.
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”
6 He turnede ayen, and fond Balach stondynge bisidis his brent sacrifice, and alle the princes of Moabitis.
Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu.
7 And whanne his parable `was takun, he seide, Balaach, the kyng of Moabitis, brouyte me fro Aran, fro the `hillis of the eest; and he seide, Come thou and curse Jacob; haaste thou, and greetli curse thou Israel.
Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé, “Balaki mú mi láti Aramu wá, ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi; wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
8 How schal Y curse whom God cursid not? bi what resoun schal Y `haue abhomynable whom God `hath not abhomynable?
Báwo ní èmi ó ṣe fi bú àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú? Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí àwọn tí Olúwa kò bá wí?
9 Fro the hiyeste flyntis Y schal se hym, and fro litle hillis Y schal biholde hym; the puple schal dwelle aloone, and it schal not be arettid among hethene men.
Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn, láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n. Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀ wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
10 Who may noumbre the dust, that is, kynrede, of Jacob, and knowe the noumbre of the generacioun of Israel? My lijf die in the deeth of iust men, and my laste thingis be maad lijk hem!
Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli? Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo, kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”
11 And Balaach seide to Balaam, What is this that thou doist? Y clepide thee, that thou schuldist curse myn enemyes, and ayenward thou blessist hem.
Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan, ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
12 To whom Balaam answeride, Whether Y may speke othir thing no but that that the Lord comaundith?
Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”
13 Therfor Balaach seide to Balaam, Come with me in to anothir place, fro whennus thou se a part of Israel, and mayst not se al; fro thennus curse thou hym.
Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.”
14 And whanne he hadde led Balaam in to an hiy place, on the cop of the hil of Phasga, he bildide seuene auteris to Balaam, and whanne calues and rammes weren put aboue,
Ó sì lọ sí pápá Sofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
15 he seide to Balaach, Stonde here bisidis thi brent sacrifice, while Y go.
Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”
16 And whanne the Lord hadde `come to him, and hadde put `a word in his mouth, he seide, Turne ayen to Balach, and thou schalt seie these thingis to hym.
Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”
17 He turnyde ayen, and foond Balach stondynge bisidis his brent sacrifice, and the princis of Moabitis with hym. To whom Balach seide, What spak the Lord?
Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
18 And whanne his parable `was takun, he seide, Stonde, Balach, and herkene; here, thou sone of Sephor. God is not `as a man,
Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ, “Dìde, Balaki; kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
19 that he lye, nethir he is as the sone of a man, that he be chaungid; therfor he seide, and schal he not do? he spak, and schal he not fulfille?
Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà. Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é? Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
20 Y am brouyt to blesse, Y may not forbede blessyng.
Èmi gba àṣẹ láti bùkún; Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
21 Noon idol is in Jacob, nethir symylacre is seyn in Israel; his Lord God is with hym, and the sown of victorie of kyng is in hym.
“Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu, kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn. Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
22 The Lord God ledde hym out of Egipt, whos strengthe is lijk an vnicorn;
Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
23 fals tellyng bi chiteryng of bryddis, `ethir idolatrie, is not in Jacob, nethir fals dyuynyng is in Israel. In his tymes it schal be seide to Jacob and Israel, What the Lord hath wrought!
Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu, tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli. Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
24 Lo! the puple schal rise to gidere as a lionesse, and schal be reisid as a lioun; the lioun schal not reste, til he deuoure prey, and drynke the blood of hem that ben slayn.
Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún; wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”
25 And Balach seide to Balaam, Nether curse thou, nether blesse thou hym.
Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”
26 And he seide, Whether Y seide not to thee, that what euer thing that God comaundide to me, Y wolde do this?
Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”
27 And Balach seide to hym, Come, and Y schal lede thee to an other place, if in hap it plesith God that fro thennus thou curse hym.
Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.”
28 And whanne Balaach hadde led hym out on the `cop of the hil of Phegor, that biholdith the wildirnesse,
Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.
29 Balaam seide to hym, Bilde here seuene auteris to me, and make redi so many caluys, and rammes of the same noumbre.
Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.”
30 Balaach dide as Balaam seide, and he puttide caluys and rammes, bi alle auteris.
Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.

< Numbers 23 >