< Nehemiah 6 >

1 Forsothe it was doon, whanne Sanaballath hadde herd, and Tobie, and Gosem of Arabie, and oure other enemyes, that Y hadde bildide the wal, and nomore brekyng was therynne; sotheli `til to that tyme Y hadde not set leeuys of schittyng in the yatis;
Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
2 Sanaballath, and Tobie, and Gosem of Arabie senten to me, and seiden, Come thou, and smyte we boond of pees in calues, `in o feeld; forsothe thei thouyten for to do yuel to me.
Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé, “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.” Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi;
3 Therfor Y sente messangeris to hem, and Y seide, Y make a greet werk, and Y mai not go doun, lest perauenture it be doon retchelesli, whanne Y come, and go doun to you.
bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé, “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
4 Sotheli thei senten to me `bi this word bi foure tymes, and Y answeride to hem by the formere word.
Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
5 And Sanaballath sente to me the fyuethe tyme bi the formere word his child; and he hadde in his hond a pistle writun in this maner;
Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀
6 It is herd among hethene men, and Gosem seide, that thou and the Jewis thenken for to rebelle, and therfor ye bilden, and thou wolt `reise thee king on hem;
tí a kọ sínú un rẹ̀ pé, “A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn
7 for which cause also thou hast set profetis, that prechen of thee in Jerusalem, and seien, A king is in Jerusalem; the king schal here these wordis; therfor come thou now, that we take counsel togidere.
àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘Ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”
8 And Y sente to hem, and seide, It is not doon bi these wordis whiche thou spekist; for of thin herte thou makist these thingis.
Mo dá èsì yìí padà sí i pé, “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”
9 Alle these men maden vs aferd, and thouyten that oure hondis schulden ceesse fro werkis, that we schulden reste; for which cause Y coumfortide more myn hond.
Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.” Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”
10 And Y entride priueli in to the hows of Samaie, sone of Dalie, the sone of Methabehel, which seide, Trete we with vs silf in the hows of God, in the myddis of the temple, and close we the yatis of the hows; for thei schulen come to sle thee, `and thei schulen come `bi niyt to sle thee.
Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”
11 And Y seide, Whether ony man lijk me fledde, and who as Y schal entre in to the temple, and schal lyue?
Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!”
12 Y schal not entre. And Y vndurstood that God `hadde not sent hym, but `he spak as profesiynge to me; and Tobie and Sanaballath `hadden hirid hym for meede.
Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.
13 For he hadde take prijs, that Y schulde be aferd, and do, and that Y schulde do synne; and thei schulden haue yuel, which thei schulden putte to me with schenschip.
Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.
14 Lord, haue mynde of me, for Tobye and Sanaballath, bi siche werkis `of hem; but also of Noadie, the profete, and of othere profetis, that maden me aferd.
A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí.
15 Forsothe the wal was fillid in the fyue and twentithe dai of the monethe Ebul, in two and fifti daies.
Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli, láàrín ọjọ́ méjìléláàádọ́ta.
16 Sotheli it was doon, whanne alle oure enemyes hadden herd, that alle hethene men dredden, that weren in oure cumpas, and thei felden doun with ynne hem silf, and wiste, that this work was maad of God.
Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.
17 But also in tho daies many pistlis of the principal men of Jewis weren sent to Tobie, and camen fro Tobie to hem.
Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.
18 For many men weren in Judee, and hadden his ooth; for he hadde weddid the douyter of Sechenye, the sone of Rotel; and Johannam, his sone, hadde take the douyter of Mosallam, sone of Barachie.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah.
19 But also thei preisiden hym bifor me, and telden my wordis to hym; and Tobie sente lettris, for to make me aferd.
Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.

< Nehemiah 6 >