< Micah 7 >

1 Wo to me, for Y am maad as he that gaderith in heruest rasyns of grapis; there is no clustre for to ete; my soule desiride figis ripe bifore othere.
Ègbé ni fún mi! Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ, ìpèsè ọgbà àjàrà; kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ, kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
2 The hooli perischide fro erthe, and riytful is not in men; alle aspien, ether setten tresoun, in blood, a man huntith his brother to deth.
Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà, kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́; gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀, olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
3 The yuel of her hondis thei seien good; the prince axith, and the domesman is in yeldyng; and a greet man spak the desir of his soule, and thei sturbliden togidere it.
Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú; àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn, àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́, gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
4 He that is best in hem, is as a paluyre; and he that is riytful, is as a thorn of hegge. The dai of thi biholdyng, thi visityng cometh, now schal be distriyng of hem.
Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún, ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ. Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé, àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò. Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
5 Nyle ye bileue to a frend, and nyle ye truste in a duyk; fro hir that slepith in thi bosum, kepe thou closyngis of thi mouth.
Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́; ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan. Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
6 For the sone doith wrong to the fadir, and the douyter schal rise ayens hir modir, and the wijf of the sone ayens the modir of hir hosebonde; the enemyes of a man ben the homeli, ether houshold meynee, of hym.
Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀, aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀, ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
7 Forsothe Y schal biholde to the Lord, Y schal abide God my sauyour; the Lord my God schal here me.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa, èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi; Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
8 Thou, myn enemye, be not glad on me, for Y felle doun, Y schal rise; whanne Y sitte in derknessis, the Lord is my liyt.
Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi. Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde. Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
9 Y schal bere wraththe of the Lord, for Y haue synned to hym, til he deme my cause, and make my doom; he schal lede out me in to liyt, Y schal se riytwisnesse of hym.
Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i, èmi yóò faradà ìbínú Olúwa, títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò, tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi. Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀; èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
10 And myn enemye schal biholde me, and sche schal be hilid with confusioun, which seith to me, Where is thi Lord God? Myn iyen schulen se hir, now sche schal be in to defoulyng, as clei of stretis.
Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé, “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?” Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀; nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ òpópó.
11 Dai schal come, that thi wallis be bildid; in that dai lawe schal be maad afer.
Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé, ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
12 In that dai and Assur schal come til to thee, and `til to stronge citees, and fro stronge citees til to flood; and to see fro see, and to hil fro hil.
Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti àní láti Ejibiti dé Eufurate láti Òkun dé Òkun àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
13 And erthe schal be in to desolacioun for her dwelleris, and for fruyt of the thouytis of hem.
Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀, nítorí èso ìwà wọn.
14 Fede thou thi puple in thi yerde, the floc of thin eritage, that dwellen aloone in wielde wode; in the myddil of Carmel thei schulen be fed of Basan and of Galaad,
Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ, èyí tí ó ń dágbé nínú igbó ní àárín Karmeli. Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi bí ọjọ́ ìgbàanì.
15 bi elde daies, bi daies of thi goyng out of the lond of Egipt. Y schal schewe to hym wondurful thingis;
“Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá, ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
16 hethene men schulen se, and thei schulen be confoundid on al her strengthe; thei schulen putte hondis on her mouth, the eris of hem schulen be deef;
Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n, nínú gbogbo agbára wọn. Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn, etí wọn yóò sì di.
17 thei schulen licke dust as a serpent; as crepynge thingis of erthe thei schulen be disturblid of her housis; thei schulen not desire oure Lord God, and thei schulen drede thee.
Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò, wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló. Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
18 God, who is lijk thee, that doist awei wickidnesse, and berist ouer the synne of relifs of thin eritage? He shal no more sende in his stronge veniaunce, for he is willynge merci; he schal turne ayen,
Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀, ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì, tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀? Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
19 and haue merci on vs. He schal put doun oure wickidnessis, and schal caste fer in to depnesse of the see alle oure synnes.
Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa; òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀, yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
20 Thou schalt yyue treuthe to Jacob, merci to Abraham, whiche thou sworist to oure fadris fro elde daies.
Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu, bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa láti ọjọ́ ìgbàanì.

< Micah 7 >