< Malachi 2 >

1 And now, A! ye preestis, this maundement is to you.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin àlùfáà, òfin yìí ní fún yín.
2 If ye wolen here, and if ye `wolen not putte on the herte, that ye yyue glorie to my name, seith the Lord of oostis, Y schal sende nedynesse in to you, and Y schal curse to youre blessyngis; and Y schal curse hem, for ye han not putte on the herte.
Bí ẹ̀yin kò bá ni gbọ́, bí ẹ̀yin kò bá ní fi í sí àyà láti fi ọ̀wọ̀ fún orúkọ mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí; èmi yóò sì ran ègún sí orí yín, èmi yóò sì fi ìbùkún yín ré. Nítòótọ́ mó ti fi ré ná, nítorí pé, ẹ̀yin kò fi sí ọkàn yín láti bu ọlá fún mi.
3 Lo! Y schal caste to you the arm, and Y schal scatere on youre cheere the drit of youre solempnytees, and it schal take you with it.
“Nítorí tiyín èmí yóò ba àwọn ọmọ yín wí, èmi ó sì fi ìgbẹ́ rẹ́ yín lójú, àní àwọn ìgbẹ́ ọrẹ ọwọ́ yín wọ̀nyí, a ó sì kó yín lọ pẹ̀lú rẹ̀.
4 And ye schulen wite, that Y sente to you this maundement, that my couenaunt were with Leuy, seith the Lord of oostis.
Ẹ̀yin ó sì mọ̀ pé, èmi ni ó ti rán òfin yìí sí yín, kí májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi lè tẹ̀síwájú,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
5 My couenaunt was with hym of lijf and pees; and Y yaf to hym a drede, and he dredde me, and he dredde of face of my name.
“Májẹ̀mú mi wà pẹ̀lú rẹ̀, májẹ̀mú ti ìyè àti àlàáfíà wà pẹ̀lú rẹ̀; mo sì fi wọn fún un, nítorí bíbẹ̀rù tí ó bẹ̀rù mi, tí ẹ̀rù orúkọ mi sì bà á.
6 The lawe of trewthe was in his mouth, and wickidnesse was not foundun in hise lippis; in pees and in equite he walkide with me, and he turnede awei many men fro wickidnesse.
Òfin òtítọ́ wà ni ẹnu rẹ̀, a kò sì rí irọ́ ni ètè rẹ̀: ó ba mi rìn ní àlàáfíà àti ni ìdúró ṣinṣin, ó sì yí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
7 For the lippis of a prest kepen science, and thei schulen ayen seke the lawe of `the mouth of hym, for he is an aungel of the Lord of oostes.
“Nítorí ètè àlùfáà ní òye láti máa pa ìmọ̀ mọ́, kí àwọn ènìyàn lè máa wá ìtọ́ni ni ẹnu rẹ̀: nítorí òun ni ìránṣẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
8 But ye wenten awei fro the weie, and sclaundren ful many men in the lawe; ye maden voide the couenaunt of Leuy, seith the Lord of oostis.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yapa kúrò ní ọ̀nà náà; ẹ̀yin sì ti fi ìkọ́ni yín mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kọsẹ̀; ẹ̀yin ti ba májẹ̀mú tí mo da pẹ̀lú Lefi jẹ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
9 For which thing and Y yaf you worthi to be dispisid, and bowen to alle puplis, as ye kepten not my weies, and token a face in the lawe.
“Nítorí náà ni èmi pẹ̀lú ṣe sọ yín di ẹ̀gàn, àti ẹni àìkàsí níwájú gbogbo ènìyàn, nítorí ẹ̀yin kò tẹ̀lé ọ̀nà mi, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń ṣe ojúsàájú nínú òfin.”
10 Whether not o fadir is of alle you? whether o God made not of nouyt you? Whi therfor ech of you dispisith his brother, and defoulith the couenaunt of youre fadris?
Baba kan náà kí gbogbo wa ha ní? Ọlọ́run kan náà kọ́ ni ó dá wa bí? Nítorí kín ni àwa ha ṣe sọ májẹ̀mú àwọn baba wa di aláìmọ nípa híhu ìwà àrékérekè olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀?
11 Judas trespasside, and abhomynacioun is maad in Israel, and in Jerusalem; for Judas defoulide the halewyng of the Lord, which he louyde, and he hadde the douyter of an alien god.
Juda ti ń hùwà àrékérekè, a sì ti hùwà ìríra ní Israẹli àti ni Jerusalẹmu: nítorí Juda tí sọ ìwà mímọ́ Olúwa di aláìmọ́, èyí tí ó fẹ́, nípa gbígbé ọmọbìnrin ọlọ́run àjèjì ni ìyàwó.
12 The Lord schal distrie the man that dide this thing, the maister and disciple, fro the tabernacle of Jacob, and him that offrith a yifte to the Lord of oostis.
Ní ti ẹni tí ó ṣe èyí, ẹni tí ó wù kí ó jẹ, kí Olúwa kí ó gé e kúrò nínú àgọ́ Jakọbu, bí ó tilẹ̀ mú ẹbọ ọrẹ wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
13 And eftsoone ye diden this thing; ye hiliden with teeris the auter of the Lord, with wepyng and mourenyng; so that Y biholde no more to sacrifice, nether resseyue ony thing plesaunt of youre hond.
Èyí ni ohun mìíràn tí ẹ̀yin sì túnṣe. Ẹ̀yin fi omijé bo pẹpẹ Olúwa mọ́lẹ̀. Ẹ̀yin sọkún, ẹ̀yin sì ba ara jẹ́ nítorí tì Òun kò ka ọrẹ yín sí mọ́, tàbí kí ó fi inú dídùn gba nǹkan yìí lọ́wọ́ yín.
14 And ye seiden, For what cause? For the Lord witnesside bitwixe thee and the wijf of thi `puberte, that is, tyme of mariage, which thou dispisidist, and this is thi felowe, and wijf of thi couenaunt.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, “Nítorí kín ní?” Nítorí Olúwa ti ṣe ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti láàrín aya èwe rẹ, ẹni tí ìwọ ti ń hùwà ẹ̀tàn sí i: bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkejì rẹ ni òun jẹ́, àti aya májẹ̀mú rẹ.
15 Whether oon made not, and residue of spirit is his? and what sekith oon, no but the seed of God? Therfore kepe ye youre spirit, and nyle thou dispise the wijf of thi yongthe;
Ọlọ́run kò ha ti ṣe wọ́n ní ọ̀kan? Ni ara àti ni ẹ̀mí tirẹ̀ ni. Èéṣe tí Ọlọ́run da yín lọ́kàn? Kí òun bá à lè wá irú-ọmọ bí ti Ọlọ́run. Nítorí náà, ẹ tọ́jú ẹ̀mí yín, ẹ má sì ṣe hùwà ẹ̀tàn sí aya èwe yín.
16 whanne thou hatist hir, leue thou hir, seith the Lord God of Israel. Forsothe wickidnesse schal kyuere the closyng of hym, seith the Lord of oostis; kepe ye youre spirit, and nyle ye dispise.
“Ọkùnrin tí ó bá kórìíra, tí ó sì kọ ìyàwó rẹ̀,” se ìwà ipá sí ẹni tí ó yẹ kí ó dá ààbò bò, ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Nítorí náà, ẹ ṣọ́ ẹ̀mí yín, kí ẹ má ṣe hùwà ẹ̀tàn.
17 Ye maden the Lord for to trauele in youre wordis, and ye seiden, Wherynne maden we hym for to trauele? In that that ye seien, Ech man that doith yuel, is good in the siyt of the Lord, and siche plesen to hym; ether certis where is the God of doom?
Ẹ̀yin ti fi ọ̀rọ̀ yín dá Olúwa ní agara. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, “Nínú kín ni àwa fi dá a ní agara?” Nígbà tí ẹ̀yìn wí pé, “Gbogbo ẹni tí ó ṣe ibi, rere ni níwájú Olúwa, inú rẹ̀ sì dùn sí wọn,” tàbí “Níbo ni Ọlọ́run ìdájọ́ gbé wà?”

< Malachi 2 >