< Luke 13 >

1 And sum men weren present in that tyme, that telden to hym of the Galileis, whos blood Pilat myngide with the sacrificis of hem.
Àwọn kan sì wá ní àkókò náà tí ó sọ ti àwọn ará Galili fún un, ẹ̀jẹ̀ ẹni tí Pilatu dàpọ̀ mọ́ ẹbọ wọn.
2 And he answeride, and seide to hem, Wenen ye, that these men of Galile weren synneris more than alle Galilees, for thei suffriden siche thingis?
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ṣe bí àwọn ará Galili wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ará Galili lọ, nítorí wọ́n jẹ irú ìyà bá-wọ̀n-ọn-nì?
3 Y seie to you, nay; alle ye schulen perische in lijk manere, but ye han penaunce.
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pẹ̀lú ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
4 And as tho eiytetene, on which the toure in Siloa fel doun, and slowe hem, gessen ye, for thei weren dettouris more than alle men that dwellen in Jerusalem?
Tàbí àwọn méjìdínlógún, tí ilé ìṣọ́ ní Siloamu wó lù, tí ó sì pa wọ́n, ẹ̀yin ṣe bí wọ́n ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ ní Jerusalẹmu lọ?
5 Y seie to you, nai; but also `ye alle schulen perische, if ye doon not penaunce.
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.”
6 And he seide this liknesse, A man hadde a fige tre plauntid in his vynyerd, and he cam sekynge fruyt in it, and foond noon.
Ó sì pa òwe yìí fún wọn pé, “Ọkùnrin kan ní igi ọ̀pọ̀tọ́ kan tí a gbìn sí ọgbà àjàrà rẹ̀; ó sì dé, ó ń wá èso lórí rẹ̀, kò sì rí nǹkan.
7 And he seide to the tilier of the vynyerd, Lo! thre yeeris ben, sithen Y come sekynge fruyt in this fige tre, and Y fynde noon; therfor kitte it doun, whereto ocupieth it the erthe?
Ó sì wí fún olùṣọ́gbà rẹ̀ pé, ‘Sá à wò ó, láti ọdún mẹ́ta ni èmi ti ń wá í wo èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ yìí, èmi kò sì rí nǹkan: ké e lulẹ̀; èéṣe tí ó fi ń gbilẹ̀ lásán pẹ̀lú?’
8 And he answerynge seide to hym, Lord, suffre it also this yeer, the while Y delue aboute it, and Y schal donge it;
“Ó sì dáhùn ó wí fún un pé, ‘Olúwa, jọ̀wọ́ rẹ̀ ní ọdún yìí pẹ̀lú, títí èmi ó fi tu ilẹ̀ ìdí rẹ̀ yíká, títí èmi ó sì fi bu ìlẹ̀dú sí i.
9 if it schal make fruyt, if nay, in tyme comynge thou schalt kitte it doun.
Bí ó bá sì so èso, o dara bẹ́ẹ̀: bí kò bá sì so, ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí nì kí ìwọ kí ó ké e lulẹ̀.’”
10 And he was techinge in her synagoge in the sabatis.
Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu kan ní ọjọ́ ìsinmi.
11 And lo! a womman, that hadde a spirit of sijknesse eiytene yeeris, and was crokid, and `nethir ony maner myyte loke vpward.
Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà níbẹ̀ tí ó ní ẹ̀mí àìlera, láti ọdún méjìdínlógún wá, ẹni tí ó tẹ̀ tán, tí kò le gbé ara rẹ̀ sókè bí ó ti wù kí ó ṣe.
12 Whom whanne Jhesus hadde seyn, he clepide to hym, and seide to hir, Womman, thou art delyuerid of thi sijknesse.
Nígbà tí Jesu rí i, ó pè é sí ọ̀dọ̀, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, a tú ọ sílẹ̀ lọ́wọ́ àìlera rẹ.”
13 And he settide on hir his hoondis, and anoon sche stood upriyt, and glorifiede God.
Ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ lé e, Lójúkan náà a sì ti sọ ọ́ di títọ́, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo.
14 And the prince of the synagoge answerde, hauynge dedeyn for Jhesus hadde heelid in the sabat; and he seide to the puple, Ther ben sixe dayes, in whiche it bihoueth to worche; therfor come ye in these, and `be ye heelid, and not in the daie of sabat.
Olórí Sinagọgu sì kún fún ìrunú, nítorí tí Jesu mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pé, ọjọ́ mẹ́fà ní ń bẹ tí a fi í ṣiṣẹ́, nínú wọn ni kí ẹ̀yin kí ó wá kí á ṣe dídá ara yín, kí ó má ṣe ní ọjọ́ ìsinmi.
15 But the Lord answeride to hym, and seide, Ypocrite, whether ech of you vntieth not in the sabat his oxe, or asse, fro the cratche, and ledith to watir?
Nígbà náà ni Olúwa dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, olúkúlùkù yín kì í tú màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ kúrò ní ibùso, kì í sì í fà á lọ mu omi ní ọjọ́ ìsinmi.
16 Bihofte it not this douytir of Abraham, whom Satanas hath boundun, lo! eiytetene yeeris, to be vnboundun of this boond in the dai of the sabat?
Kò sì yẹ kí a tú obìnrin yìí tí í ṣe ọmọbìnrin Abrahamu sílẹ̀ ní ìdè yìí ní ọjọ́ ìsinmi, ẹni tí Satani ti dè, sá à wò ó láti ọdún méjìdínlógún yìí wá?”
17 And whanne he seide these thingis, alle hise aduersaries weren aschamed, and al the puple ioiede in alle thingis, that weren gloriousli don of hym.
Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí, ojú ti gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn sì yọ̀ fún ohun ìyanu gbogbo tí ó ṣe.
18 Therfor he seide, To what thing is the kyngdom of God lijk? and to what thing schal Y gesse it to be lijk?
Ó sì wí pé, “Kín ni ìjọba Ọlọ́run jọ? Kín ni èmi ó sì fiwé?
19 It is lijk to a corn of seneuey, which a man took, and cast in to his yerd; and it wax, and was maad in to a greet tree, and foulis of the eire restiden in the braunchis therof.
Ó dàbí hóró musitadi, tí ọkùnrin kan mú, tí ó sì sọ sínú ọgbà rẹ̀; tí ó sì hù, ó sì di igi ńlá; àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé orí ẹ̀ka rẹ̀.”
20 And eft soone he seide, To what thing schal Y gesse the kyngdom of God lijk?
Ó sì tún wí pé, “Kín ni èmi ìbá fi ìjọba Ọlọ́run wé?
21 It is lijk to sourdouy, that a womman took, and hidde it `in to thre mesuris of mele, til al were sourid.
Ó dàbí ìwúkàrà, tí obìnrin kan mú, tí ó fi sínú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun mẹ́ta, títí gbogbo rẹ̀ ó fi di wíwú.”
22 And he wente bi citees and castels, techynge and makynge a iourney in to Jerusalem.
Ó sì ń la àárín ìlú àti ìletò lọ, ó ń kọ́ni, ó sì ń rìn lọ sí Jerusalẹmu.
23 And a man seide to hym, Lord, if there ben fewe, that ben saued? And he seide to hem,
Ẹnìkan sì bi í pé, Olúwa, díẹ̀ ha kọ ni àwọn tí a ó gbàlà? Ó sì wí fún wọn pé,
24 Stryue ye to entre bi the streite yate; for Y seie to you, many seken to entre, and thei schulen not mowe.
“Ẹ làkàkà láti gba ojú ọ̀nà tóóró wọlé, nítorí mo wí fún yín, ènìyàn púpọ̀ ni yóò wá ọ̀nà láti wọ̀ ọ́, wọn kì yóò sì lè wọlé.
25 For whanne the hosebonde man is entrid, and the dore is closid, ye schulen bigynne to stonde with out forth, and knocke at the dore, and seie, Lord, opyn to vs. And he schal answere, and seie to you, Y knowe you not, of whennus ye ben.
Nígbà tí baálé ilé bá dìde lẹ́ẹ̀kan fùú, tí ó bá sí ti ìlẹ̀kùn, ẹ̀yin ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í dúró lóde, tí ẹ ó máa kan ìlẹ̀kùn, wí pé, ‘Olúwa, Olúwa, ṣí i fún wa!’ “Òun ó sì dáhùn wí fún yín pé, ‘Èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mọ̀ yín.
26 Thanne ye schulen bigynne to seye, We han etun bifor thee and drunkun, and in oure streetis thou hast tauyt.
“Nígbà náà ni ẹ̀yin ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, ‘Àwa ti jẹ, àwa sì ti mu níwájú rẹ, ìwọ sì kọ́ni ní ìgboro ìlú wa.’
27 And he schal seie to you, Y know you not, of whennus ye ben; go awei fro me, alle ye worcheris of wickidnesse.
“Òun ó sì wí pé, ‘Èmi wí fún yín èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá; ẹ lọ kúrò lọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.’
28 There schal be wepyng and gruntyng of teeth, whanne ye schulen se Abraham, and Isaac, and Jacob, and alle the prophetis in the kyngdom of God; and you to be put out.
“Níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà, nígbà tí ẹ̀yin ó rí Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, àti gbogbo àwọn wòlíì, ní ìjọba Ọlọ́run, tí a ó sì ti ẹ̀yin sóde.
29 And thei schulen come fro the eest and west, and fro the north and south, and schulen sitte `at the mete in the rewme of God.
Wọn ó sì ti ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti ìwọ̀-oòrùn wá, àti láti àríwá, àti gúúsù wá, wọn ó sì jókòó ní ìjọba Ọlọ́run.
30 And lo! thei that weren the firste, ben the laste; and thei that weren the laste, ben the firste.
Sì wò ó, àwọn ẹni ẹ̀yìn ń bẹ tí yóò di ẹni iwájú, àwọn ẹni iwájú ń bẹ tí yóò di ẹni ẹ̀yìn.”
31 In that day sum of the Farisees camen nyy, and seiden to hym, Go out, and go fro hennus, for Eroude wole sle thee.
Ní wákàtí kan náà, díẹ̀ nínú àwọn Farisi tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Jáde, kí ìwọ sì lọ kúrò níhìn-ín yìí: nítorí Herodu ń fẹ́ pa ọ́.”
32 And he seide to hem, Go ye, and seie to that foxe, Lo! Y caste out feendis, and Y make perfitli heelthis, to dai and to morew, and the thridde dai Y am endid.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ, kí ẹ̀yin sì sọ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ náà pé, ‘Kíyèsi i, èmi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, èmi ń ṣe ìmúláradá lónìí àti lọ́la, àti ní ọjọ́ mẹ́ta èmi ó ṣe àṣepé.’
33 Netheles it bihoueth me to dai, and to morewe, and the dai that sueth, to walke; for it fallith not a profete to perische out of Jerusalem.
Ṣùgbọ́n èmi kò jẹ́ má rìn lónìí, àti lọ́la, àti ní ọ̀túnla: dájúdájú wòlíì kan ki yóò ṣègbé lẹ́yìn odi Jerusalẹmu.
34 Jerusalem, Jerusalem, that sleest profetis, and stonest hem that ben sent to thee, hou ofte wolde Y gadre togider thi sones, as a brid gaderith his nest vndur fethris, and thou woldist not.
“Jerusalẹmu, Jerusalẹmu, ìwọ tí o pa àwọn wòlíì, tí o sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí ọ pa; nígbà mélòó ni èmi ń fẹ́ ràgà bo àwọn ọmọ rẹ, bí àgbébọ̀ adìyẹ ti í ràgà bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ apá rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́!
35 Lo! youre hous schal be left to you desert. And Y seie to you, that ye schulen not se me, til it come, whanne ye schulen seie, Blessid is he, that cometh in the name of the Lord.
Sá wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro. Lóòtítọ́ ni mo sì wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi títí yóò fi di àkókò tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.’”

< Luke 13 >