< Lamentations 2 >

1 Aleph. Hou hath the Lord hilid the douyter of Sion with derknesse in his strong veniaunce? he hath caste doun fro heuene in to erthe the noble citee of Israel; and bithouyte not on the stool of hise feet, in the dai of his strong veniaunce.
Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀! Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀, láti ọ̀run sí ayé; kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀ ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
2 Beth. The Lord castide doun, and sparide not alle the faire thingis of Jacob; he distried in his strong veniaunce the strengthis of the virgyn of Juda, and castide doun in to erthe; he defoulide the rewme, and the princes therof.
Láìní àánú ni Olúwa gbé ibùgbé Jakọbu mì; nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀. Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.
3 Gymel. He brak in the ire of his strong veniaunce al the horn of Israel; he turnede a bak his riyt hond fro the face of the enemy; and he kyndlide in Jacob, as fier of flawme deuowrynge in cumpas.
Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké gbogbo ìwo Israẹli. Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò nígbà tí àwọn ọ̀tá dé. Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.
4 Deleth. He as an enemye bente his bouwe, he as an aduersarie made stidfast his riyt hond; and he killide al thing that was fair in siyt in the tabernacle of the douytir of Sion; he schedde out his indignacioun as fier.
Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra. Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.
5 He. The Lord is maad as an enemy; he castide doun Israel, he castide doun alle the wallis therof; he destriede the strengthis therof, and fillide in the douyter of Juda a man maad low, and a womman maad low.
Olúwa dàbí ọ̀tá; ó gbé Israẹli mì. Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì ó pa ibi gíga rẹ̀ run. Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀ fún àwọn ọmọbìnrin Juda.
6 Vau. And he scateride his tent as a gardyn, he distried his tabernacle; the Lord yaf to foryetyng in Sion a feeste dai, and sabat; and the kyng and prest in to schenschipe, and in to the indignacioun of his strong veniaunce.
Ó mú ìparun bá ibi mímọ́, ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run. Olúwa ti mú Sioni gbàgbé àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn; nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run ọba àti olórí àlùfáà.
7 Zai. The Lord puttide awei his auter, he curside his halewyng; he bitook in to the hondis of enemy the wallis of the touris therof; thei yauen vois in the hous of the Lord, as in a solempne dai.
Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀ ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀. Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́ àwọn odi ààfin rẹ̀; wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.
8 Heth. The Lord thouyte to distrie the wal of the douyter of Sion; he stretchide forth his coorde, and turnede not awei his hond fro perdicioun; the forwal, ether the outerward, mourenyde, and the wal was distried togidere.
Olúwa pinnu láti fa ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya. Ó gbé wọn sórí òsùwọ̀n, kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn. Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀ wọ́n ṣòfò papọ̀.
9 Teth. The yatis therof ben piyt in the erthe, he loste and al to-brak the barris therof; the kyng therof and the princes therof among hethene men; the lawe is not, and the profetis therof founden not of the Lord a visioun.
Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀; òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́. Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, kò sí òfin mọ́, àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.
10 Joth. Thei saten in erthe, the elde men of the douytir of Sion weren stille; thei bispreynten her heedis with aische, the eldere men of Juda ben girt with hairis; the virgyns of Juda castiden doun to erthe her heedis.
Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́; wọ́n da eruku sí orí wọn wọ́n sì wọ aṣọ àkísà. Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.
11 Caph. Myn iyen failiden for teeris, myn entrails weren disturblid; my mawe was sched out in erthe on the sorewe of the douyter of my puple; whanne a litil child and soukynge failide in the stretis of the citee.
Ojú mi kọ̀ láti sọkún, mo ń jẹ ìrora nínú mi, mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀ nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run, nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú ní òpópó ìlú.
12 Lameth. Thei seiden to her modris, Where is wheete, and wyn? whanne thei failiden as woundid men in the stretis of the citee; whanne thei senten out her soulis in the bosum of her modris.
Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn, “Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe ní àwọn òpópónà ìlú, bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò láti ọwọ́ ìyá wọn.
13 Men. To whom schal Y comparisoun thee? ether to whom schal Y licne thee, thou douyter of Jerusalem? to whom schal Y make thee euene, and schal Y coumforte thee, thou virgyn, the douyter of Sion? for whi thi sorewe is greet as the see; who schal do medicyn to thee?
Kí ni mo le sọ fún ọ? Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu? Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé, kí n lè tù ọ́ nínú, ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni? Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun. Ta ni yóò wò ọ́ sàn?
14 Nun. Thi profetis sien to thee false thingis, and fonned; and openyden not thi wickidnesse, that thei schulden stire thee to penaunce; but thei sien to thee false takyngis, and castyngis out.
Ìran àwọn wòlíì rẹ jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n; wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ. Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.
15 Sameth. Alle men passynge on the weie flappiden with hondis on thee; thei hissiden, and mouyden her heed on the douyter of Jerusalem; and seiden, This is the citee of perfit fairnesse, the ioie of al erthe.
Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí; wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu: “Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní àṣepé ẹwà, ìdùnnú gbogbo ayé?”
16 Ayn. Alle thin enemyes openyden her mouth on thee; thei hissiden, and gnaistiden with her teeth, and seiden, We schulen deuoure; lo! this is the dai which we abididen, we founden, we sien.
Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn gbòòrò sí ọ; wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán. Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí; tí a sì wá láti rí.”
17 Phe. The Lord dide tho thingis whiche he thouyte, he fillide hise word which he hadde comaundid fro elde daies; he distriede, and sparide not; and made glad the enemy on thee, and enhaunside the horn of thin enemyes.
Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu; ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ, tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́. Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú, ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ, ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.
18 Sade. The herte of hem criede to the Lord, on the wallis of the douyter of Syon; leede thou forth teeris as a stronde, bi dai and niyt; yyue thou not reste to thee, nether the appil of thin iye be stille.
Ọkàn àwọn ènìyàn kígbe jáde sí Olúwa. Odi ọmọbìnrin Sioni, jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò ní ọ̀sán àti òru; má ṣe fi ara rẹ fún ìtura, ojú rẹ fún ìsinmi.
19 Coph. Rise thou togidere, herie thou in the nyyt, in the begynnyng of wakyngis; schede out thin herte as watir, bifore the siyt of the Lord; reise thin hondis to hym for the soulis of thi litle children, that failiden for hungur in the heed of alle meetyngis of weies.
Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́, bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀ tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi níwájú Olúwa. Gbé ọwọ́ yín sókè sí i nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀ tí ó ń kú lọ nítorí ebi ní gbogbo oríta òpópó.
20 Res. Se thou, Lord, and byholde, whom thou hast maad so bare; therfor whether wymmen schulen ete her fruyt, litle children at the mesure of an hond? for a prest and profete is slayn in the seyntuarie of the Lord.
“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó. Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí. Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún? Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì ní ibi mímọ́ Olúwa?
21 Syn. A child and an elde man laien on the erthe withoutforth; my virgyns and my yonge men fellen doun bi swerd; thou hast slayn hem in the dai of thi strong veniaunce, thou smotist `and didist no merci.
“Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀ sínú eruku àwọn òpópó; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ti ṣègbé nípa idà. Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ, Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.
22 Thau. Thou clepidist, as to a solempne dai, hem that maden me aferd of cumpas; and noon was that ascapide in the dai of the strong veniaunce of the Lord, and was left; myn enemy wastide hem, whiche Y fedde, and nurschide up.
“Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè, bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi. Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè; àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn, ni ọ̀tá mi parun.”

< Lamentations 2 >