< Joshua 3 >
1 Therfor Josue roos bi nyyt, and mouede tentis; and thei yeden out of Sechym, and camen to Jordan, he and alle the sones of Israel, and dwelliden there thre daies.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, Joṣua àti gbogbo àwọn Israẹli sí kúrò ní Ṣittimu, wọ́n sì lọ sí etí odò Jordani, wọ́n sì pa ibùdó síbẹ̀ kí wọn tó kọjá.
2 And whanne tho daies weren passid, crieris yeden thorouy the myddis of tentis,
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta àwọn olórí la àárín ibùdó já.
3 and bigunnen to crie, Whanne ye seen the arke of boond of pees of youre Lord God, and the preestis of the generacioun of Leuy berynge it, also rise ye, and sue the biforgoeris;
Wọ́n sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Nígbà tí ẹ bá rí àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín, tí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi rù ú, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sí kúrò ní ipò yín, ẹ̀yin yóò sì máa tẹ̀lé e.
4 and a space of twey thousynde cubitis be bitwixe you and the arke, that ye moun se fer, and knowe bi what weie ye schulen entre, for ye `yeden not bifore bi it; and be ye war, that ye neiye not to the arke.
Ẹyin yóò lè mọ ọ̀nà tí ẹ ó gbà, torí pé ẹ̀yin kò gba ọ̀nà yìí tẹ́lẹ̀ rí. Ṣùgbọ́n àlàfo gbọdọ̀ wà ní àárín yín àti àpótí náà, tó bí ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́.”
5 And Josue seide to the puple, Be ye halewid, for to morew the Lord schal make merueilis among you.
Joṣua sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ya ara yín sí mímọ́, nítorí ní ọ̀la, Olúwa yóò ṣe ohun ìyanu ní àárín yín.”
6 And Josue seide to the preestis, Take ye the arke of the boond of pees `of the Lord, and go ye bifor the puple. Whiche filliden the heestis, and tooken the arke, and yeden bifor hem.
Joṣua sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ̀yin, ẹ gbé àpótí ẹ̀rí náà kí ẹ̀yin kí ó sì máa lọ ṣáájú àwọn ènìyàn.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé e sókè, wọ́n sì ń lọ ní iwájú u wọn.
7 And the Lord seide to Josue, To dai Y schal bigynne to enhaunse thee bifor al Israel, that thei wite, that as Y was with Moises, so Y am also with thee.
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Òní yìí ni Èmi yóò bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ọ ga ní ojú u gbogbo àwọn ará Israẹli, kí wọn lè mọ̀ pé Èmi wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí mo ṣe wà pẹ̀lú Mose.
8 Forsothe comaunde thou to preestis, that beren the arke of bond of pees, and seie thou to hem, Whanne ye han entrid in to a part of the watir of Jordan, stonde ye therynne.
Sọ fún àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà, ‘Nígbà tí ẹ bá dé etí omi Jordani, ẹ lọ kí ẹ sì dúró nínú odò náà.’”
9 And Josue seide to the sones of Israel, Neiye ye hidur, and here ye the word of youre Lord God.
Joṣua sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ súnmọ́ ibí kí ẹ̀yin kí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín.
10 And eft he seide, In this ye schulen wite that the Lord God lyuynge is in the myddis of you; and he schal distrye in youre siyt Cananey, Ethei, Euey, and Feresei, and Gergesei, and Jebusei, and Amorrei.
Èyí ni ẹ̀yin yóò fi mọ̀ pé Ọlọ́run alààyè wà ní àárín yín àti pé dájúdájú yóò lé àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, Hifi, Peresi, Girgaṣi, Amori àti Jebusi jáde níwájú u yín.
11 Lo! the arke of boond of pees of the Lord of al erthe schal go bifor you thorouy Jordan.
Àpótí májẹ̀mú Olúwa gbogbo ayé ń gòkè lọ sí Jordani ṣáájú u yín.
12 Make ye redi twelue men of the twelue lynagis of Israel, bi ech lynage o man.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
13 And whanne the preestis, that beren the arke of boond of pees of the Lord God of al erthe, han set the steppis of her feet in the watris of Jordan, the watris that ben lowere schulen renne doun, and schulen faile; forsothe the watris that comen fro aboue schulen stonde togidere in o gobet.
Bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí Olúwa, Olúwa gbogbo ayé bá ti ẹsẹ̀ bọ odò Jordani, omi tí ń ti òkè sàn wá yóò gé kúrò yóò sì gbá jọ bí òkìtì kan.”
14 Therfor the puple yede out of her tabernaclis to passe Jordan; and the preestis that baren the arke of boond of pees yeden bifor the puple.
Nígbà tí àwọn ènìyàn gbéra láti ibùdó láti kọjá nínú odò Jordani, àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà ń lọ níwájú wọn.
15 And whanne the preestis entriden in to Jordan, and her feet weren dippid in the part of watir; forsothe Jordan `hadde fillid the brynkis of his trow in the tyme of `ripe corn;
Odò Jordani sì máa ń wà ní kíkún ní gbogbo ìgbà ìkórè. Ṣùgbọ́n bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí ti dé odò Jordani tí ẹsẹ̀ wọn sì kan etí omi,
16 the watris yeden doun, and stoden in o place, and wexiden grete at the licnesse of an hil, and apperiden fer fro the citee that was clepid Edom, `til to the place of Sarthan; sotheli the watris that weren lowere yeden doun in to the see of wildirnesse, which is now clepid the deed see, `til the watris failiden outirli.
omi tí ń ti òkè sàn wá dúró. Ó sì gbá jọ bí òkìtì ní òkèèrè, ní ìlú tí a ń pè ní Adamu, tí ó wà ní tòsí Saretani; nígbà tí omi tí ń sàn lọ sínú Òkun aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀) gé kúrò pátápátá. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kọjá sí òdìkejì ní ìdojúkọ Jeriko.
17 Forsothe the puple yede thorouy Jordan; and the preestis, that baren the arke of the boond of pees of the Lord, stoden gird on the drie erthe in the myddis of Jordan, and al the puple passide thorouy the drie trow.
Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa sì dúró ṣinṣin lórí ilẹ̀ gbígbẹ ní àárín Jordani, nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ń kọjá títí gbogbo orílẹ̀-èdè náà fi rékọjá nínú odò Jordani lórí ilẹ̀ gbígbẹ.