< Joshua 15 >
1 Therfor this was the part of the sones of Juda, bi her kynredis; fro the terme of Edom `til to deseert of Syn ayens the south, and `til to the laste part of the south coost,
Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
2 the bigynnyng therof fro the hiynesse of the saltist see, and fro the arm therof, that biholdith to the south.
Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
3 And it goith out ayens the stiyng of Scorpioun, and passith in to Syna; and it stieth in to Cades Barne, and cometh in to Ephron, and it stieth to Daran, and cumpassith Cariacaa;
ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
4 and fro thennus it passith in to Asemona, and cometh to the stronde of Egipt; and the termes therof schulen be the greet see; this schal be the ende of the south coost.
Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
5 Sotheli fro the eest the bigynnyng schal be the saltiste see, `til to the laste partis of Jordan, and tho partis, that biholden the north, fro the arm of the see `til to the same flood of Jordan.
Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
6 And the terme stieth in to Bethaegla, and passith fro the north in to Betharaba; and it stieth to the stoon of Boen,
ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
7 sone of Ruben, and goith `til to the termes of Debera, fro the valei of Achar ayens the north; and it biholdith Galgala, which is `on the contrarie part of the stiyng of Adomyn, fro the south part of the stronde; and it passith the watris, that ben clepid the welle of the sunne; and the outgoyngis therof schulen be to the welle of Rogel.
Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
8 And it stieth bi the valei of the sone of Ennon, bi the side of Jebusei, at the south; this is Jerusalem; and fro thennus it reisith it silf to the cop of the hil, which is ayens Jehennon at the west, in the hiynesse of the valei of Raphaym, ayens the north;
Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
9 and it passith fro the `cop of the hil til to the wel of the watir Nepthoa, and cometh `til to the tounes of the hil of Ephron; and it is bowid in to Baala, which is Cariathiarym, that is, the citee of woodis;
Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
10 and it cumpassith fro Baala ayens the west, `til to the hil of Seir, and it passith bi the side of the hil Jarym to the north in Selbon, and goith doun in to Bethsamys; and it passith in to Thanna,
Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
11 and cometh ayens the partis of the north bi the side of Accaron; and it is bowid to Secrona, and passith the hil of Baala; and it cometh in to Gebneel, and it is closid with the ende of the grete see, ayens the west.
Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
12 These ben the termes of the sones of Juda, bi cumpas in her meynees.
Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
13 Sotheli Josue yaf to Caleph, sone of Jephone, part in the myddis of the sones of Juda, as the Lord comaundide to hym, Cariatharbe, of the fadir of Enach; thilke is Ebron.
Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
14 And Caleph dide awei fro it thre sones of Enach, Sisai, and Achyman, and Tholmai, of the generacioun of Enach.
Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
15 And Caleph stiede fro thennus, and cam to the dwelleris of Dabir, that was clepid bifore Cariathsepher, that is, the citee of lettris.
Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
16 And Caleph seide, Y schal yyue Axa, my douyter, wijf to hym that schal smyte Cariathsepher, and schal take it.
Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
17 And Othynyel, sone of Ceneth, the yongere brother of Caleph, took that citee; and Caleph yaf Axa, his douytir, wijf to hym.
Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
18 And whanne `sche yede togidere, hir hosebonde counseilide hir, that sche schulde axe of hir fadir a feeld; and sche siyyide, as sche sat on the asse;
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
19 `to whom Caleph seide, What hast thou? And sche answeride, Yyue thou blessyng to me; thou hast youe to me the south lond and drye; ioyne thou also the moist lond. And Caleph yaf to hir the moist lond, aboue and bynethe.
Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
20 This is the possessioun of the lynage of the sones of Juda, bi her meynees.
Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
21 And the citees weren fro the laste partis of the sones of Juda, bisidis the termes of Edom, fro the south; Capsahel, and Edel, and Jagur, Ectyna,
Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
24 and Jethnan, and Ipheth, and Thelon,
Sifi, Telemu, Bealoti,
25 and Balaoth, and Asor, Nobua, and Cariath, Effron;
Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
26 this is Asseromam; Same,
Amamu, Ṣema, Molada,
27 and Molida, and Aser, Gabda, and Assemoth,
Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
28 Bethfelech, and Asertual, and Bersabee,
Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
29 and Baiohia, and Baala, and Hymesen,
Baalahi, Limu, Esemu,
30 and Betholad, and Exul, and Herma,
Eltoladi, Kesili, Horma,
31 and Sichelech, and Meacdemana, and Sensena,
Siklagi, Madmana, Sansanna,
32 Lebeoth, and Selymetem Remmoth; alle `the citees, nyn and thretti, and the townes `of tho.
Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
33 Sotheli in the feeldi places, Escoal, and Sama,
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
34 and Asena, and Azanoe, and Engannem, and Taphua,
Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
35 and Enaym, and Jecemoth, Adulam, Socco, and Azecha, and Sarym,
Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
36 Adytaym, and Gedam, and Giderothaym; fourtene citees, and `the townes of tho;
Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
37 Sanam, and Aseba, and Magdalgad,
Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
38 Delen, and Melcha, Bethel, Lachis,
Dileani, Mispa, Jokteeli,
39 and Baschat, and Esglon,
Lakiṣi, Boskati, Egloni,
Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
41 and Cethlis, and Gideroth, and Bethdagon, and Neuma, and Maceda; sixtene citees, and `the townes of tho; `Jambane,
Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
44 and Nesib, and Ceila, and Azib, and Mareza, nyn citees, and `the townes of tho;
Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
45 `Accaron with hise townes and vilagis;
Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
46 fro Accaron til to the see, alle thingis that gon to Azotus, and the townes therof;
ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
47 Azotus with hise townes and vilagis; Gaza with hise townes and villagis, til to the stronde of Egipt; and the grete see is the terme therof;
Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
48 and in the hil, Samyr,
Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
49 and Jeccher, and Socco, and Edema, Cariath Senna;
Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
50 this is Dabir; Anab, and Ischemo,
Anabu, Eṣitemo, Animu,
51 and Ammygosen, and Olom, and Gilo, enleuene `citees, and the townes of tho;
Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
54 and Bethfasua, and Afecha, Ammacha, and Cariatharbe; this is Ebron; and Sior, nyn citees, and `the townes of tho;
Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
55 `Maon, and Hermen, and Ziph, and Jothae,
Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
56 Zerahel, and Zocadamer, and Anoe, and Chaym,
Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
57 Gabaa, and Kanna, ten citees, and `the citees of tho;
Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
59 and Jodor, Mareth, and Bethanoth, and Bethecen, sixe citees, and the townes of tho;
Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
60 Cariathbaal; this is Cariathiarym, the citee of woodis; and Rebda, twei citees, and `the townes of tho;
Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
61 in deseert, `Betharaba, Medyn, and Siriacha, Nepsan,
Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
62 and the citee of salt, and Engaddi, sixe citees, and `the townes of tho; `the citees weren togidere an hundrid and fiftene.
Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
63 Sotheli the sones of Juda myyten not do awei Jebusei, the dwellere of Jerusalem; and Jebusei dwellide with the sones of Juda in Jerusalem `til in to present day.
Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.