< Joshua 13 >

1 Josue was eld and of greet age; and the Lord seide to him, Thou hast woxe eld, and art of long tyme; and largeste lond is left, which is not yit departid bi lot;
Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
2 that is, al Galile, Filistiym, and al Gessuri,
“Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: “gbogbo àwọn agbègbè àwọn Filistini, àti ti ara Geṣuri:
3 fro the troblid flood that moistith Egipt, `til to the termes of Acaron ayenus the north; the lond of Chanaan, which is departid `in to fyue litle kyngis of Filistym, of Gaza, and of Azotus, of Ascolon, of Geth, and of Accaron.
láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni; ti àwọn ará Affimu);
4 Forsothe at the south ben Eueis, al the lond of Canaan, and Maara of Sidonyes, `til to Affetha, and to the termes of Amorrei, and the coostis of hym;
láti gúúsù; gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kenaani, láti Arah ti àwọn ará Sidoni títí ó fi dé Afeki, agbègbè àwọn ará Amori,
5 and the cuntrei of Liban ayens the eest, fro Baalgath, vndur the hil of Hermon, til thou entrist into Emath,
àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali; àti gbogbo àwọn Lebanoni dé ìlà-oòrùn, láti Baali-Gadi ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni dé Lebo-Hamati.
6 of alle men that dwelliden in the hil, fro the Liban `til to the watris of Masserephoth, and alle men of Sidon; Y am, that schal do awei hem fro the face of the sones of Israel; therfor come it in to the part of eritage of Israel, as Y comaundide to thee.
“Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
7 And thou now departe the lond in to possessioun to the nyne lynagis, and to the half lynage of Manasses,
pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
8 with which lynage Ruben and Gad weldiden the lond, which lond Moises, the `seruaunt of the Lord, yaf to hem biyende the flowyngis of Jordan, at the eest coost;
Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
9 fro Aroer, which is set in the brynke of the stronde of Arnon, in the middis of the valei, and alle the feeldi places of Medaba,
Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
10 `til to Dibon, and alle the citees of Seon, kyng of Amorreis, that regnyde in Esebon, `til to the termes of the sones of Amon,
Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
11 and of Galaad, and to the termes of Gessuri, and of Machati, and al the hil of Hermon, and al Basan, `til to Salecha;
Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
12 al the rewme of Og in Basan, that regnede in Astoroth, and in Edraym; `he was of the relikis of Rafaym, `that is, of giauntis; and Moises smoot hem and dide awey hem.
ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
13 And the sones of Israel nolden destrye Gessurri and Machati; and thei dwelliden in the myddis of Israel, `til in to present dai.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
14 Sotheli he yaf not possessioun to the lynage of Leuy, but sacrifices, and slayn sacrifices of the Lord God of Israel; that is `his eritage, as God spak to hym.
Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
15 Therfor Moises yaf possessioun to the lynage of the sones of Ruben, bi her kynredis;
Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
16 and `the term of hem was fro Aroer, which is set in the brenke of the stronde of Arnon, and in the myddil valei of the same stronde, al the pleyn that ledith to Medaba,
láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
17 and Esebon, and alle the townes of tho, that ben in the feeldi places; and Dibon, and Baal Bamoth, and the citee of Baal Meon,
sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
18 and Gesa, and Sedymoth, and Mephe,
Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
19 and Cariathaym, and Sabana, and Sarathaphar, in the hil of the valey of Betheroeth,
Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
20 and of Asedoch, Phasca, and Bethaissymoth;
Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
21 alle the feeldi citees, and alle the rewmes of Seon, kyng of Amorrey, that regnede in Esebon, whom Moyses smoot, with hise princes, Madian, Euey and Recten, and Sur, and Hur, and Rebee, duykis of Seon, enhabiters of the lond.
gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
22 And the sones of Israel killiden bi swerd Balaam, the fals diuynour, the sone of Beor, with othere men slayn.
Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
23 And the terme of the sones of Ruben was maad the flood of Jordan; this is the possessioun of Rubenytis bi her kynredis of citees and of townes.
Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
24 And Moises yaf to the lynage of Gad, and to the sones therof, bi her kynredis, possessioun, of which this is departyng;
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
25 he yaf the termes of Jazer, and alle the citees of Galaad, and the half part of the lond of the sones of Amon, `til to Aroer which is ayens Tabba;
Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
26 and fro Esebon `til to Ramoth of Masphe, and Bethamyn, and Manayn, `til to the termes of Dabir;
àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
27 and in the valei he yaf Betharan, and Bethneuar, and Socoth, and Saphan, the tother part of the rewme of Seon, kyng of Esebon; and the ende of this is Jordan, `til to the laste part of the see of Cenereth ouer Jordan, at the eest coost.
àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
28 This is the possessioun of the sones of Gad, bi her meynees, the citees and townes of tho.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
29 He yaf also possessioun to the half lynage of Manasses, and to hise sones, bi her kynredis,
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
30 of which possessioun this is the bigynnyng; he yaf Ammaym, and al Basan, and alle the rewmes of Og, kyng of Basan, and alle the townes of Jair, that ben in Basan, sixti citees;
Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
31 and half the part of Galaad, and Astoroth, and Edray, the citees of the rewme of Og, kyng of Basan; to the sones of Machir, sones of Manasses, and to half the part of the sones of Machir, bi her kynredis.
ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani). Èyí ni fún irú àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase fún ààbọ̀ àwọn ọmọ Makiri, ní agbo ilé ní agbo ilé.
32 Moises departide this possessioun in the feeldi placis of Moab ouer Jordan, ayens Jericho, at the eest coost.
Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
33 Forsothe he yaf not possessioun to the lynage of Leuy; for the Lord God himself of Israel is the possessioun of Leuy, as the Lord spak to hym.
Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.

< Joshua 13 >