< Jeremiah 7 >

1 The word that was maad of the Lord to Jeremye,
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
2 and seide, Stonde thou in the yate of the hous of the Lord, and preche there this word, and seie, Al Juda, that entren bi these yatis for to worschipe the Lord, here ye the word of the Lord.
“Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
3 The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Make ye good youre weies, and youre studies, and Y schal dwelle with you in this place.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
4 Nyle ye triste in the wordis of leesyng, and seie, The temple of the Lord, the temple of the Lord, the temple of the Lord is.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
5 For if ye blessen youre weies, and your studies; if ye doon doom bitwixe a man and his neiybore;
Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
6 if ye maken not fals caleng to a comelyng, and to a fadirles child, and to a widewe; nether scheden out innocent blood in this place, and goen not after alien goddis, in to yuel to you silf,
Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
7 Y schal dwelle with you in this place, in the lond which Y yaf to youre fadris, fro the world and til in to the world.
Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
8 Lo! ye trusten to you in the wordis of leesyng, that shulen not profite to you;
Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
9 to stele, to sle, to do auowtrie, to swere falsli, to make sacrifice to Baalym, and to go aftir alien goddys, whiche ye knowen not.
“‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
10 And ye camen, and stoden bifor me in this hous, in which my name is clepid to help; and ye seiden, We ben delyuered, for we han do alle these abhomynaciouns.
Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
11 Whether therfor this hous, wherynne my name is clepid to help bifore youre iyen, is maad a denne of theues? I, Y am, Y siy, seith the Lord.
Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
12 Go ye to my place in Silo, where my name dwellide at the bigynnyng, and se ye what thingis Y dide to it, for the malice of my puple Israel.
“‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
13 And now, for ye han do alle these werkis, seith the Lord, and Y spak to you, and roos eerli, and Y spak, and ye herden not, and Y clepide you, and ye answeriden not;
Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
14 Y schal do to this hous, wherynne my name is clepid to help, and in which hous ye han trist, and to the place which Y yaf to you and to youre fadris, as Y dide to Silo.
Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
15 And Y schal caste you forth fro my face, as Y castide forth alle youre britheren, al the seed of Effraym.
Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
16 Therfor nyl thou preie for this puple, nether take thou heriyng and preier for hem; and ayenstonde thou not me, for Y schal not here thee.
“Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
17 Whether thou seest not, what these men don in the citees of Juda, and in the stretis of Jerusalem?
Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
18 The sones gaderen stickis, and the fadris kyndlen a fier; and wymmen sprengen togidere ynnere fatnesse, to make kakis to the queen of heuene, to make sacrifice to alien goddis, and to terre me to wrathfulnesse.
Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
19 Whether thei stiren me to wrathfulnesse? seith the Lord; whether thei stiren not hem silf in to schenschip of her cheer?
Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
20 Therfor the Lord God seith these thingis, Lo! my strong veniaunce and myn indignacioun is wellid togidere on this place, on men, and on beestis, and on the tree of the cuntrei, and on the fruitis of erthe; and it schal be kyndlid, and it schal not be quenchid.
“‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
21 The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Heepe ye youre brent sacrifices to youre slayn sacrifices, and ete ye fleischis.
“‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
22 For Y spak not with youre fadris, and Y comaundide not to hem of the word of brent sacrifices, and of slayn sacrifices, in the dai in which Y ledde hem out of the lond of Egipt.
Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
23 But Y comaundide this word to hem, and Y seide, Here ye my vois, and Y schal be God to you, and ye schulen be a puple to me; and go ye in al the weie which Y comaundide to you, that it be wel to you.
Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
24 And thei herden not, nether bowiden doun her eere, but thei yeden in her lustis, and in the schrewidnesse of her yuel herte; and thei ben put bihynde, and not bifore,
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
25 fro the dai in which her fadris yeden out of the lond of Egipt til to this dai. And Y sente to you alle my seruauntis profetis, and Y roos eerli bi the dai, and Y sente.
Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
26 And thei herden not me, nether bowiden doun her eere; but thei maden hard her nol, and wrouyten worse than the fadris of hem.
Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
27 And thou schalt speke to hem alle these wordis, and thei schulen not heere thee; and thou schalt clepe hem, and thei schul not answere to thee.
“Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
28 And thou schalt seie to hem, This is the folc, that herde not the vois of her Lord God, nether resseyuede chastysyng; feith perischide, and is takun awei fro the mouth of hem.
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
29 Clippe thin heer, and cast awei, and take thou weilyng streiytli; for the Lord hath cast awei, and hath forsake the generacioun of his strong veniaunce.
“‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
30 For the sones of Juda han do yuel bifor myn iyen, seith the Lord; thei han set her offendyngis in the hous, in which my name is clepid to help, that thei schulden defoule that hous;
“‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
31 and thei bildiden hiye thingis in Tophet, which is in the valei of the sone of Ennon, that thei schulden brenne her sones and her douytris bi fier, whiche thingis Y comaundide not, nether thouyte in myn herte.
Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
32 Therfor lo! daies comen, seith the Lord, and it schal no more be seid Tophet, and the valei of the sone of Ennon, but the valey of sleyng; and thei schulen birie in Tophet, for ther is no place.
Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
33 And the deed careyn of this puple schal be in to mete to the briddis of heuene, and to the beestis of erthe; and noon schal be that schal dryue awei.
Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
34 And Y schal make to ceesse the vois of ioye, and the vois of gladnesse, and the vois of spouse, and the vois of spousesse fro the citees of Juda, and fro the stretis of Jerusalem; for the lond schal be in desolacioun.
Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.

< Jeremiah 7 >