< Jeremiah 50 >

1 The word which the Lord spak of Babiloyne, and of the lond of Caldeis, in the hond of Jeremye, the profete.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
2 Telle ye among hethene men, and make ye herd; reise ye a signe; preche ye, and nyle ye holde stille; seie ye, Babiloyne is takun, Bel is schent, Maradach is ouer comun; the grauun ymagis therof ben schent, the idols of hem ben ouer comun.
“Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
3 For a folk schal stie fro the north ayenus it, which folk schal sette the lond therof in to wildirnesse; and noon schal be that schal dwelle therynne, fro man `til to beeste; and thei ben moued, and yeden a wei.
Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
4 In tho daies, and in that tyme, seith the Lord, the sones of Israel schulen come, thei and the sones of Juda togidere, goynge and wepynge; thei schulen haaste, and seke her Lord God in Sion,
“Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
5 and thei schulen axe the weie. Hidur the faces of hem schulen come, and thei schulen be set to the Lord with boond of pees euerlastynge, which schal not be don awei by ony foryetyng.
Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
6 My puple is maad a lost floc, the scheepherdis of hem disseyueden hem, and maden to go vnstabli in hillis; thei passiden fro mounteyn in to a litil hil, thei foryaten her bed.
“Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
7 Alle men that founden, eeten hem, and the enemyes of hem seiden, We synneden not, for that thei synneden to the Lord, the fairnesse of riytfulnesse, and to the Lord, the abidyng of her fadris.
Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
8 Go ye awei fro the myddis of Babiloyne, and go ye out of the lond of Caldeis, and be ye as kydis bifore the floc.
“Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
9 For lo! Y schal reise, and brynge in to Babiloyne the gaderyng togidere of grete folkis, fro the lond of the north; and thei schulen be maad redi ayens it, and it schal be takun in the dai; the arowe therof as of a strong man a sleere, schal not turne ayen voide.
Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
10 And Caldee schal be in to prey, alle that distrien it, schulen be fillid, seith the Lord.
A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
11 For ye maken ful out ioye, and speken grete thingis, and rauyschen myn eritage; for ye ben sched out as caluys on erbe, and lowiden as bolis.
“Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
12 Youre modir is schent greetli, and sche that gendride you, is maad euene to dust; lo! sche schal be the last among folkis, and forsakun, with out weie, and drie.
Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
13 For the wraththe of the Lord it schal not be enhabitid, but it schal be dryuun al in to wildirnesse; ech that schal passe bi Babiloyne, schal wondre, and schal hisse on alle the woundis therof.
Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
14 Alle ye that beenden bowe, be maad redi ayens Babiloyne bi cumpas; ouercome ye it, spare ye not arowis, for it synnede to the Lord.
“Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
15 Crye ye ayens it, euery where it yaf hond; the foundementis therof fellen doun, and the wallis therof ben distried; for it is the veniaunce of the Lord. Take ye veniaunce of it; as it dide, do ye to it.
Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Leese ye a sowere of Babiloyne, and hym that holdith a sikil in the tyme of heruest, fro the face of swerd of the culuer; ech man schal be turned to his puple, and ech man schal flee to his lond.
Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
17 Israel is a scaterid flok, liouns castiden out it; first kyng Assur eete it, this laste Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, dide awei the bonys therof.
“Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
18 Therfor the Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Lo! Y schal visite the kyng of Babiloyne, and his lond, as Y visitide the kyng of Assur;
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
19 and Y schal brynge ayen Israel to his dwellyng place. Carmele and Baasan schal be fed, and his soule schal be fillid in the hil of Effraym, and of Galaad.
Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
20 In tho daies, and in that tyme, seith the Lord, the wickidnesse of Israel schal be souyt, and it schal not be; and the synne of Juda schal be souyt, and it schal not be foundun; for Y schal be merciful to hem, whiche Y schal forsake.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
21 Stie thou on the lond of lordis, and visite thou on the dwelleris therof; scatere thou, and sle tho thingis, that ben aftir hem, seith the Lord; and do thou bi alle thingis which Y comaundide to thee.
“Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
22 The vois of batel and greet sorewe in the lond.
Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
23 Hou is the hamer of al erthe brokun and al defoulid? hou is Babiloyne turned in to desert, among hethene men?
Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
24 Babiloyne, Y haue snarid thee, and thou art takun, and thou wistist not; thou art foundun, and takun, for thou terridist the Lord to wraththe.
Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
25 The Lord openide his tresour, and brouyte forth the vessels of his wraththe; for whi a werk is to the Lord God of oostis in the lond of Caldeis.
Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
26 Come ye to it fro the fertheste endis, opene ye, that thei go out, that schulen defoule it; take ye awei stoonys fro the weie, and dryue ye in to heepis, and sle ye it, and nothing be residue.
Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
27 Distrie ye alle the stronge men therof, go thei doun in to sleynge; wo to hem, for the dai of hem cometh, the tyme of visityng of hem.
Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
28 The vois of fleeris, and of hem that ascapiden fro the lond of Babiloyne, that thei telle in Sion the veniaunce of oure Lord God, the veniaunce of his temple.
Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
29 Telle ye ayens Babiloyne to ful many men, to alle that beenden bowe. Stonde ye togidere ayens it bi cumpas, and noon ascape; yelde ye to it aftir his werk, aftir alle thingis whiche it dide, do ye to it; for it was reisid ayens the Lord, ayens the hooli of Israel.
“Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
30 Therfor yonge men therof schulen falle doun in the stretis therof, and alle men werriours therof schulen be stille in that dai, seith the Lord.
Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
31 Lo! thou proude, Y to thee, seith the Lord God of oostis, for thi dai is comun, the tyme of thi visitacioun.
“Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
32 And the proude schal falle, and schal falle doun togidere, and noon schal be, that schal reise hym; and Y schal kyndle fier in the citees of hym, and it schal deuoure alle thingis in cumpas of it.
Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
33 The Lord of oostis seith these thingis, The sones of Israel and the sones of Juda togidere suffren fals caleng; alle that token hem, holden, thei nylen delyuere hem.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
34 The ayenbyere of hem is strong, the Lord of oostis is his name; bi dom he schal defende the cause of hem, that he make the lond aferd, and stire togidere the dwelleris of Babiloyne.
Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
35 A swerd to Caldeis, seith the Lord, and to the dwelleris of Babiloyne, and to the princes, and to the wise men therof.
“Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
36 A swerd to the false dyuynours therof, that schulen be foolis; a swerd to the stronge men therof, that schulen drede.
Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
37 Swerd to the horsis therof, and to the charis therof, and to al the comyn puple whiche is in the myddis therof, and thei schulen be as wymmen; a swerd to the tresours therof, that schulen be rauyschid.
Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
38 Drynesse schal be on the watris therof, and tho schulen be drye; for it is the lond of grauun ymagis, and hath glorie in false feynyngis.
Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
39 Therfor dragouns schulen dwelle with fonned wielde men, and ostrigis schulen dwelle therynne; and it schal no more be enhabitid `til in to with outen ende, and it schal not be bildid `til to generacioun and generacioun;
“Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
40 as the Lord distriede Sodom and Gomorre, and the niy citees therof, seith the Lord. A man schal not dwelle there, and the sone of man schal not dwelle in it.
Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
41 Lo! a puple cometh fro the north, and a greet folc, and many kyngis schulen rise togidere fro the endis of erthe.
“Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
42 Thei schulen take bowe and swerd, thei ben cruel and vnmerciful; the vois of hem schal sowne as the see, and thei schulen stie on horsis as a man maad redi to batel, ayens thee, thou douyter of Babiloyne.
Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
43 The kyng of Babiloyne herde the fame of hem, and hise hondis ben aclumsid; angwisch took hym, sorewe took hym, as a womman trauelynge of child.
Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
44 Lo! as a lioun he schal stie fro the pride of Jordan to the stronge fairnesse, for Y schal make hym to renne sudenli to it; and who schal be the chosun man, whom Y schal sette bifore him? For who is lijk me? and who schal suffre me? and who is this scheepherde, that schal ayenstonde my cheer?
Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
45 Therfore here ye the councel of the Lord, which he conseyuede in mynde ayens Babiloyne, and hise thouytis, whiche he thouyte on the lond of Caldeis, no but the litle of the flockis drawen hem doun, no but the dwellyng place of hem be destried with hem, ellis no man yyue credence to me.
Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
46 The erthe is mouyd of the vois of caitiftee of Babiloyne, and cry is herd among hethene men.
Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

< Jeremiah 50 >