< Jeremiah 27 >

1 In the bigynnyng of the rewme of Joachym, the sone of Josie, kyng of Juda, this word was maad of the Lord to Jeremye, and seide,
Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
2 The Lord seith these thingis to me, Make thou to thee boondis and chaynes, and thou schalt putte tho in thi necke;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
3 and thou schalt sende tho to the kyng of Edom, and to the kyng of Moab, and to the kyng of the sones of Amon, and to the kyng of Tyre, and to the kyng of Sidon, bi the hond of messangeris that camen to Jerusalem, and to Sedechie, kyng of Juda.
Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
4 And thou schalt comaunde to hem, that thei speke to her lordis, The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Ye schulen seie these thingis to youre lordis,
Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
5 Y made erthe, and man, and beestis that ben on the face of al erthe, in my greet strengthe, and in myn arm holdun forth; and Y yaf it to hym that plesyde bifore myn iyen.
Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
6 And now therfor Y yaf alle these londis in the hond of Nabugodonosor, my seruaunt, the kyng of Babiloyne; ferthermore and Y yaf to hym the beestis of the feeld, that thei serue hym.
Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
7 And alle folkis schulen serue hym, and his sone, and the sone of his sone, til the tyme of his lond and of hym come; and many folkis and grete kyngis schulen serue hym.
Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
8 Forsothe the folk and rewme that serueth not Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, and whoeuer bowith not his necke vndur the yok of the kyng of Babiloyne, Y schal visite on that folk in swerd, and hungur, and pestilence, seith the Lord, til Y waaste hem in his hond.
“‘“Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
9 Therfor nyle ye here youre profetis, and false dyuynouris, and dremeris, and dyuyneris bi chiteryng and fleyng of briddis, and witchis, that seien to you, Ye schulen not serue the kyng of Babiloyne;
Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
10 for thei profesien a lessyng to you, that thei make you fer fro youre lond, and caste out you, and ye perische.
Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
11 Certis the folk that makith suget her nol vndur the yok of the kyng of Babiloyne, and serueth hym, Y schal dismytte it in his lond, seith the Lord; and it schal tile that lond, and schal dwelle therynne.
Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.”’”
12 And Y spak bi alle these wordis to Sedechie, kyng of Juda, and Y seide, Make ye suget youre neckis vndur the yok of the kyng of Babiloyne, and serue ye hym, and his puple, and ye schulen lyue.
Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
13 Whi schulen ye die, thou and thi puple, bi swerd, and hungur, and pestilence, as the Lord spak to the folk, that nolde serue to the kyng of Babiloyne?
Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
14 Nyle ye here the wordis of profetis seiynge to you, Ye schulen not serue the kyng of Babiloyne; for thei speken leesyng to you, for Y sente not hem, seith the Lord;
Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
15 and thei profesien falsly in my name, that thei caste out you, and that ye perische, bothe ye and the profetis that profesien to you.
‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’”
16 And Y spak to the preestis, and to this puple, and Y seide, The Lord God seith these thingis, Nyle ye here the wordis of youre profetis, that profesien to you, and seien, Lo! the vessels of the Lord schulen turne ayen now soone fro Babiloyne; for thei profesien a leesyng to you.
Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
17 Therfor nyle ye here hem, but serue ye to the kyng of Babiloyne, that ye lyue; whi is this citee youun in to wildirnesse?
Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
18 And if thei ben profetis, and if the word of God is in hem, renne thei to the Lord of oostis, that the vessels whiche weren left in the hous of the Lord, and in the hous of the kyng of Juda, and in Jerusalem, come not in to Babiloyne.
Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
19 For the Lord of oostis seith these thingis to the pilers, and to the see, that is, a greet waischyng vessel, and to the foundementis, and to the remenauntis of vessels, that weren left in this citee,
Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
20 whiche Nabugodonosor, king of Babiloyne, took not, whanne he translatide Jeconye, the sone of Joachim, king of Juda, fro Jerusalem in to Babiloyne, and alle the principal men of Juda and of Jerusalem.
Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
21 For the Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis to the vessels that ben left in the hous of the Lord, and in the hous of the king of Juda, and in Jerusalem, Tho schulen be translatid in to Babiloyne,
Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
22 and schulen be there `til to the dai of her visitacioun, seith the Lord; and Y schal make tho to be brouyt, and to be restorid in this place.
‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’”

< Jeremiah 27 >