< Isaiah 65 >

1 Thei souyten me, that axiden not bifore; thei that souyten not me, founden me. Y seide, Lo! Y, lo! Y, to hethene men that knewen not me, and that clepiden not mi name to help.
“Èmi fi ara mi hàn fún àwọn tí kò béèrè fún mi; àwọn tí kò wá mi ni wọ́n rí mi. Sí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò pe orúkọ mi, ni èmi wí pé, ‘Èmi nìyìí, Èmi nìyìí.’
2 I stretchide forth myn hondis al dai to a puple vnbileueful, that goith in a weie not good, aftir her thouytis.
Gbogbo ọjọ́ ni mo ti nawọ́ mi síta sí àwọn ènìyàn ọlọ́rùn líle, tí wọn ń rìn lọ́nà tí kò dára, tí wọ́n sì gbára lé èrò ara wọn
3 It is a puple that stirith me to wrathfulnesse, euere bifore my face; whiche offren in gardyns, and maken sacrifice on tiel stoonys;
àwọn ènìyàn tí wọ́n bí mi nínú nígbà gbogbo lójú ara mi gan an, wọ́n ń rú ẹbọ nínú ọgbà wọ́n sì ń sun tùràrí lórí i pẹpẹ bíríkì;
4 whiche dwellen in sepulcris, and slepen in the templis of idols; whiche eten swynes fleisch, and vnhooli iwisch is in the vessels of hem;
wọ́n ń jókòó láàrín ibojì wọ́n sì ń lo òru wọn nínú ìṣọ́ ìkọ̀kọ̀; tí wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀, tí ìkòkò ọbẹ̀ wọn kún fún ẹran àìmọ́;
5 whiche seien to an hethene man, Go thou awei fro me, neiy thou not to me, for thou art vncleene; these schulen be smoke in my stronge veniaunce, fier brennynge al dai.
tí ó wí pé, ‘Ẹ sún mẹ́yìn; ẹ má wá sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti jẹ́ mímọ́ jù fún un yín!’ Àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ èéfín nínú ihò imú mi iná tí ń fi gbogbo ọjọ́ jó.
6 Lo! it is writun bifore me; Y schal not be stille, but Y schal yelde, and Y schal quyte in to the bosum of hem youre wickidnessis,
“Kíyèsi i, a ti kọ ọ́ síwájú mi, Èmi kì yóò dákẹ́, ṣùgbọ́n èmi yóò san án padà lẹ́kùnrẹ́rẹ́; Èmi yóò san án padà sí àyà wọn
7 and the wickidnessis of youre fadris togidere, seith the Lord, whiche maden sacrifice on mounteyns, and diden schenschipe to me on litle hillis; and Y schal mete ayen the firste werk of hem in her bosum.
àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,” ni Olúwa wí. “Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńlá wọ́n sì ṣe ẹ̀gbin sí mi ní òkè kékeré, Èmi yóò wọ́n ọ́n sí itan wọn ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”
8 The Lord seith thes thingis, As if a grape be foundun in a clustre, and it be seid, Distrie thou not it, for it is blessyng; so Y schal do for my seruantis, that Y leese not al.
Báyìí ni Olúwa wí: “Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí oje sì tún wà nínú àpólà àjàrà tí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘Má ṣe bà á jẹ́, nítorí ìbùkún ń bẹ nínú rẹ̀,’ bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi; Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.
9 And Y schal lede out of Jacob seed, and of Juda a man hauynge in possessioun myn hooli hillis; and my chosun men schulen enherite it, and my seruauntis schulen dwelle there.
Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jakọbu, àti láti Juda àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n-ọn-nì; àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn, ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.
10 And the feeldi places schulen be into floodis of flockis, and the valei of Achar in to a restyng place of droues of neet, to my puple that souyten me.
Ṣaroni yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran, àti àfonífojì Akori yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran, fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.
11 And Y schal noumbre you in swerd, that forsoken the Lord, that foryaten myn hooli hil, whiche setten a boord to fortune, and maken sacrifice theronne,
“Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé òkè ńlá mímọ́ mi, tí ó tẹ́ tábìlì fún Gadi tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,
12 and alle ye schulen falle bi sleyng; for that that Y clepide, and ye answeriden not; Y spak, and ye herden not; and ye diden yuel bifor myn iyen, and ye chesiden tho thingis whiche Y nolde.
Èmi yóò yà ọ́ sọ́tọ̀ fún idà, àti pé ẹ̀yin yóò bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ fún àwọn tí a pa; nítorí mo pè, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò dáhùn. Mo sọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò tẹ́tí sílẹ̀. Ẹ̀yin ṣe búburú ní ojú mi ẹ sì yan ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́.”
13 For these thingis, the Lord God seith these thingis, Lo! my seruauntis schulen ete, and ye schulen haue hungur; lo! my seruauntis schulen drynke, and ye schulen be thirsti;
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun; ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin, àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu, ṣùgbọ́n òǹgbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin; àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀, ṣùgbọ́n a ó dójútì yin.
14 lo! my seruauntis schulen be glad, and ye schulen be aschamed; lo! my seruauntis schulen herie, for the ful ioie of herte, and ye schulen crie, for the sorewe of herte, and ye schulen yelle, for desolacioun of spirit.
Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrin láti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókè láti inú ìrora ọkàn yín àti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.
15 And ye schulen leeue youre name in to an ooth to my chosun men; and the Lord God schal sle thee, and he schal clepe hise seruauntis bi another name.
Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀ fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún; Olúwa Olódùmarè yóò sì pa yín, ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òun yóò fún ní orúkọ mìíràn.
16 In which he that is blessid on erthe, schal be blessid in God amen; and he that swerith in erthe, shal swere in God feithfuli; for the formere angwischis ben youun to foryetyng, and for tho ben hid fro youre iyen.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náà yóò ṣe é nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́; Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náà yóò búra nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́. Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbé yóò sì fi ara sin kúrò lójú mi.
17 For lo! Y make newe heuenes and a newe erthe, and the formere thingis schulen not be in mynde, and schulen not stie on the herte.
“Kíyèsi i, Èmi yóò dá àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun. A kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́, tàbí kí wọn wá sí ọkàn.
18 But ye schulen haue ioie, and make ful out ioiyng til in to with outen ende, in these thingis whiche Y make; for lo! Y make Jerusalem ful out ioiynge, and the puple therof ioie.
Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láé nínú ohun tí èmi yóò dá, nítorí èmi yóò dá Jerusalẹmu láti jẹ́ ohun ìdùnnú àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.
19 And Y schal make ful out ioiyng in Jerusalem, and Y schal haue ioie in my puple; and the vois of weping and the vois of cry schal no more be herd ther ynne.
Èmi yóò ṣe àjọyọ̀ lórí Jerusalẹmu n ó sì ní inú dídùn nínú àwọn ènìyàn mi; ariwo ẹkún àti igbe ni a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ mọ́.
20 A yong child of daies schal no more be there, and an eld man that fillith not hise daies; for whi a child of an hundrid yeer schal die, and a synnere of an hundrid yeer schal be cursid.
“Títí láé a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ ọmọ ọwọ́ tí yóò gbé fún ọjọ́ díẹ̀, tàbí àgbàlagbà tí kì yóò lo ọjọ́ ayé rẹ̀ tán; ẹni tí ó bá kú ní ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún ni a ó pè ní ọ̀dọ́mọdé; ẹni tí kò ba le pé ọgọ́rùn-ún kan ni a ó pè ní ẹni ìfibú.
21 And thei schulen bilde housis, and schulen enhabite hem, and thei schulen plaunte vynes, and schulen ete the fruytis of tho.
Wọn yó ò kọ́ ilé, wọn yóò sì gbé nínú wọn wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì jẹ èso wọn.
22 Thei schulen not bilde housis, and an othir schal enhabite hem, thei schulen not plaunte, and an othir schal ete; for whi the daies of my puple schulen be after the daies of the tree, and the werkis of
Wọn kì yóò kọ́ ilé fún ẹlòmíràn láti gbé, tàbí kí wọn gbìn fún ẹlòmíràn láti jẹ. Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí igi kan, bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ àwọn ènìyàn mi yóò rí; àwọn àyànfẹ́ mi yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́ wọn fún ìgbà pípẹ́.
23 her hondis schulen be elde to my chosun men. Thei schulen not trauele in veyn, nether thei schulen gendre in disturblyng; for it is the seed of hem that ben blessid of the Lord, and the cosyns of hem ben with hem.
Wọn kì yóò ṣe iṣẹ́ lásán, wọn kí yóò bímọ fún wàhálà; nítorí wọn yóò jẹ́ àwọn ènìyàn ti Olúwa bùkún fún, àwọn àti àwọn ìrandíran wọn pẹ̀lú wọn.
24 And it schal be, bifor that thei crien, Y schal here; yit while thei speken, Y schal here.
Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn; nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.
25 A wolf and a lomb schulen be fed togidere, and a lioun and an oxe schulen ete stree, and to a serpent dust schal be his breed; thei schulen not anoie, nether schulen sle, in al myn hooli hil, seith the Lord.
Ìkookò àti ọ̀dọ́-àgùntàn yóò jẹun pọ̀, kìnnìún yóò sì jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù, ṣùgbọ́n erùpẹ̀ ni yóò jẹ́ oúnjẹ ejò. Wọn kì yóò pa ni lára tàbí pa ni run ní gbogbo òkè mímọ́ mi,” ni Olúwa wí.

< Isaiah 65 >