< Isaiah 39 >

1 In that tyme Marodach Baladan, the sone of Baladam, the kyng of Babiloyne, sente bookis and yiftis to Ezechie; for he hadde herd, that Ezechie hadde be sijk, and was rekyuerid.
Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli fi ìwé àti ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí Hesekiah, nítorí ó gbọ́ pé ó ṣàìsàn ó sì gbádùn.
2 Forsothe Ezechie was glad on hem, and schewide to hem the selle of swete smellynge spices, and of siluer, and of gold, and of smellynge thingis, and of best oynement, and alle the schoppis of his purtenaunce of houshold, and alle thingis that weren foundun in hise tresours; no word was, which Ezechie schewide not to hem in his hous, and in al his power.
Hesekiah gba àwọn ikọ̀ yìí tayọ̀tayọ̀, ó sì fi àwọn nǹkan tí ó wà nínú yàrá ìkẹ́rù sí mọ́ hàn wọ́n—fàdákà, wúrà, ohun olóòórùn dídùn, òróró dídára, gbogbo nǹkan ogun rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìṣúra rẹ̀ kò sí ohunkóhun tí ó wà nínú ààfin rẹ̀ tàbí ní ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò fihàn wọ́n.
3 Sotheli Ysaie, the prophete, entride to kyng Ezechie, and seide to hym, What seiden thes men, and fro whennus camen thei to thee? And Ezechie seide, Fro a fer lond thei camen to me, fro Babiloyne.
Lẹ́yìn náà wòlíì Isaiah lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah ọba ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí, níbo ni wọ́n sì ti wá?” “Láti ilẹ̀ jíjìnnà,” ni èsì Hesekiah. “Wọ́n wá sọ́dọ̀ mi láti Babeli.”
4 And Ysaie seide, What siyen thei in thin hous? And Ezechie seide, Thei sien alle thingis that ben in myn hous; no thing was in my tresours, which Y schewide not to hem.
Wòlíì náà sì béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí nínú ààfin rẹ?” Hesekiah si dáhùn pe, “Wọ́n rí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin mi. Kò sí ohun kankan nínú ìṣúra mi tí èmi kò fihàn wọ́n.”
5 And Ysaie seide to Ezechie, Here thou the word of the Lord of oostis.
Lẹ́yìn náà ni Isaiah sọ fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
6 Lo! daies schulen come, and alle thingis that ben in thin hous, and whiche thingis thi fadris tresoriden til to this dai, schulen be takun awei in to Babiloyne; not ony thing schal be left, seith the Lord.
Àsìkò ń bọ̀ nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà nínú ààfin rẹ, àti ohun gbogbo tí àwọn baba rẹ ti kójọ títí di ọjọ́ òní yóò di kíkó lọ sí Babeli. Ohun kankan kò ní ṣẹ́kù ni Olúwa wí.
7 And thei schulen take of thi sones, that schulen go out of thee, whiche thou schalt gendre; and thei schulen be onest seruauntis and chast in the paleis of the kyng of Babiloyne.
Àti díẹ̀ nínú àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ, àwọn ẹ̀jẹ̀ àti ẹran-ara rẹ tí a ó bí fún ọ ni a ó kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà nínú ààfin ọba Babeli.”
8 And Ezechie seide to Ysaie, The word of the Lord is good, which he spak. And Ezechie seide, Pees and treuthe be maad oneli in my daies.
Hesekiah wí fún Isaiah pé, “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Àlàáfíà àti ààbò yóò wà ní ìgbà ayé tèmi.”

< Isaiah 39 >