< Isaiah 19 >

1 The birthun of Egipt. Lo! the Lord schal stie on a liyt cloude, and he schal entre in to Egipt; and the symilacris of Egipt schulen be mouyd fro his face, and the herte of Egipt schal faile in the myddis therof.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Ejibiti. Kíyèsi i, Olúwa gun àwọsánmọ̀ tí ó yára lẹ́ṣin ó sì ń bọ̀ wá sí Ejibiti. Àwọn ère òrìṣà Ejibiti wárìrì níwájú rẹ̀, ọkàn àwọn ará Ejibiti sì ti domi nínú wọn.
2 And Y schal make Egipcians to renne togidere ayens Egipcians, and a man schal fiyte ayens his brother, and a man ayens his frend, a citee ayens a citee, and a rewme ayens a rewme.
“Èmi yóò rú àwọn ará Ejibiti sókè sí ara wọn arákùnrin yóò bá arákùnrin rẹ̀ jà, aládùúgbò yóò dìde sí aládùúgbò rẹ̀, ìlú yóò dìde sí ìlú, ilẹ̀ ọba sí ilẹ̀ ọba.
3 And the spirit of Egipt schal be brokun in the entrailis therof, and Y schal caste doun the councel therof; and thei schulen axe her symylacris, and her false diuinouris, and her men that han vncleene spiritis spekinge in the wombe, and her dyuynouris bi sacrifices maad on auteris to feendis.
Àwọn ará Ejibiti yóò sọ ìrètí nù, èmi yóò sì sọ èrò wọn gbogbo di òfo; wọn yóò bá àwọn òrìṣà àti ẹ̀mí àwọn òkú sọ̀rọ̀, àwọn awoṣẹ́ àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀.
4 And Y schal bitake Egipt in to the hond of cruel lordis, and a strong kyng schal be lord of hem, seith the Lord God of oostis.
Èmi yóò fi Ejibiti lé agbára àwọn ìkà amúnisìn lọ́wọ́, ọba aláìláàánú ni yóò jẹ ọba lé wọn lórí,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
5 And watir of the see schal wexe drie, and the flood schal be desolat, and schal be dried.
Gbogbo omi inú odò ni yóò gbẹ, gbogbo ilẹ̀ àyíká odò ni yóò gbẹ tí yóò sì sáàpá.
6 And the floodis schulen faile, and the strondis of the feeldis schulen be maad thynne, and schulen be dried; a rehed and spier schal fade.
Adágún omi yóò sì di rírùn; àwọn odò ilẹ̀ Ejibiti yóò máa dínkù wọn yóò sì gbẹ. Àwọn koríko odò àti ìrẹ̀tẹ̀ yóò gbẹ,
7 The botme of watir schal be maad nakid, and stremys fro her welle; and the moiste place of al seed schal be dried, schal waxe drie, and schal not be.
àwọn igi ipadò Naili pẹ̀lú, tí ó wà ní orísun odò, gbogbo oko tí a dá sí ipadò Naili yóò gbẹ dànù tí yóò sì fẹ́ dànù tí kò sì ní sí mọ́.
8 And fischeris schulen morne, and alle that casten hook in to the flood, schulen weile; and thei that spreden abrood a net on the face of watris, schulen fade.
Àwọn apẹja yóò sọkún kíkorò, àti gbogbo àwọn tí ó ń ju ìwọ̀ sínú odò; odò náà yóò sì máa rùn.
9 Thei schulen be schent, that wrouyten flex, foldynge and ordeynynge sutil thingis.
Àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ọ̀gbọ̀ yóò kọminú àwọn ahunṣọ ọ̀gbọ̀ yóò sọ ìrètí nù.
10 And the watir places therof schulen be drye; alle that maden poondis to take fischis, schulen be schent.
Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ aṣọ yóò rẹ̀wẹ̀sì, gbogbo àwọn oníṣẹ́ oṣù ni àìsàn ọkàn yóò ṣe.
11 The fonned princes of Tafnys, the wise counselouris of Farao, yauen vnwise counsel; hou schulen ye seie to Farao, Y am the sone of wise men, the sone of elde kyngis?
Àwọn oníṣẹ́ Ṣoani ti di aláìgbọ́n, àwọn ọlọ́gbọ́n olùdámọ̀ràn Farao ń mú ìmọ̀ràn àìgbọ́n wá. Báwo ló ṣe lè sọ fún Farao pé, “Mo jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àwọn ọba àtijọ́.”
12 Where ben now thi wise men? Telle thei to thee, and schewe thei, what the Lord of oostis thouyte on Egipt.
Níbo ni àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn rẹ wà báyìí? Jẹ́ kí wọn fihàn ọ́ kí wọn sì sọ ọ́ di mí mọ̀ ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pinnu lórí Ejibiti.
13 The princes of Tafnys ben maad foolis; the princes of Memphis fadiden; thei disseyueden Egipt, a corner of the puplis therof.
Àwọn ọmọ-aládé Ṣoani ti di aṣiwèrè, a ti tan àwọn ọmọ-aládé Memfisi jẹ; àwọn òkúta igun ilé tí í ṣe ti ẹ̀yà rẹ ti ṣi Ejibiti lọ́nà.
14 The Lord meddlid a spirit of errour in the myddis therof; and thei maden Egipt for to erre in al his werk, as a drunkun man and spuynge errith.
Olúwa ti da ẹ̀mí òòyì sínú wọn; wọ́n mú Ejibiti ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú ohun gbogbo tí ó ń ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọ̀mùtí ti í ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú èébì rẹ̀.
15 And werk schal not be to Egipt, that it make an heed and tail bowynge and refreynynge.
Kò sí ohun tí Ejibiti le ṣe— orí tàbí ìrù, ọ̀wá ọ̀pẹ tàbí koríko odò.
16 In that dai Egipt schal be as wymmen, and thei schulen be astonyed, and schulen drede of the face of the mouynge of the hoond of the Lord of oostis, which he mouede on it.
Ní ọjọ́ náà ni àwọn ará Ejibiti yóò dàbí obìnrin. Wọn yóò gbọ̀n jìnnìjìnnì pẹ̀lú ẹ̀rù nítorí ọwọ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí a gbé sókè sí wọn.
17 And the lond of Juda schal be to Egipt in to drede; ech that schal thenke on it, schal drede of the face of the counsel of the Lord of oostis, whiche he thouyte on it.
Ilẹ̀ Juda yóò sì di ẹ̀rù fún Ejibiti; gbogbo àwọn tí a bá ti dárúkọ Juda létí wọn ni yóò wárìrì, nítorí ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbèrò láti ṣe sí wọn.
18 In that dai fyue citees schulen be in the lond of Egipt, and schulen speke with the tunge of Canaan, and schulen swere bi the Lord of oostis; the citee of the sunne schal be clepid oon.
Ní ọjọ́ náà ìlú márùn-ún ní ilẹ̀ Ejibiti yóò sọ èdè àwọn ará Kenaani, wọn yóò sì búra àtìlẹ́yìn fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Ọ̀kan nínú wọn ni a ó sì máa pè ní ìlú ìparun.
19 In that dai the auter of the Lord schal be in the myddis of the lond of Egipt, and the title of the Lord schal be bisidis the ende therof;
Ní ọjọ́ náà pẹpẹ kan yóò wà fún Olúwa ní àárín gbùngbùn Ejibiti, àti ọ̀wọ́n kan fún Olúwa ní etí bodè rẹ̀.
20 and it schal be in to a signe and witnessyng to the Lord of oostis, in the lond of Egipt. For thei schulen crie to the Lord fro the face of the troblere, and he schal sende a sauyour to hem, and a forfiytere, that schal delyuere hem.
Yóò sì jẹ́ àmì àti ẹ̀rí sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ilẹ̀ Ejibiti. Nígbà tí wọ́n bá ké pe Olúwa nítorí àwọn aninilára wọn, yóò rán olùgbàlà àti olùgbèjà kan sí wọn tí yóò sì gbà wọ́n sílẹ̀.
21 And the Lord schal be knowun of Egipt, and Egipcians schulen knowe the Lord in that dai; and thei schulen worschipe hym in sacrifices and yiftis, and thei schulen make vowis to the Lord, and thei schulen paie.
Báyìí ni Olúwa yóò sọ ara rẹ̀ di mí mọ̀ fún àwọn ará Ejibiti àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò gba Olúwa gbọ́. Wọn yóò sìn ín pẹ̀lú ẹbọ ọrẹ ìyẹ̀fun, wọn yóò jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa wọn yóò sì mú un ṣẹ.
22 And the Lord schal smyte Egipt with a wounde, and schal make it hool; and Egipcians schulen turne ayen to the Lord, and he schal be plesid in hem, and he schal make hem hool.
Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn kan bá Ejibiti jà; yóò bá wọn jà yóò sì tún wò wọ́n sàn. Wọn yóò yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn yóò sì wò wọ́n sàn.
23 In that dai a wei schal be fro Egipt in to Assiriens, and Egipcians schulen serue Assur; and Assur schal entre in to Egipt, and Egipt in to Assiriens.
Ní ọjọ́ náà òpópónà kan yóò wá láti Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Asiria yóò lọ sí Ejibiti àti àwọn ará Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Ejibiti àti ará Asiria yóò jọ́sìn papọ̀.
24 In that dai Israel schal be the thridde to Egipt and to Assur, the blessyng in the myddil of erthe;
Ní ọjọ́ náà Israẹli yóò di ẹ̀kẹta pẹ̀lú Ejibiti àti Asiria, àní orísun ìbùkún ní ilẹ̀ ayé.
25 whom the Lord of oostis blesside, seiynge, Blessid be my puple of Egipt, and the werk of myn hondis be to Assiriens; but myne eritage be to Israel.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò bùkún wọn yóò wí pé, “Ìbùkún ni fún Ejibiti ènìyàn mi, Asiria iṣẹ́ ọwọ́ mi, àti Israẹli ìní mi.”

< Isaiah 19 >