< Hosea 6 >

1 In her tribulacioun thei schulen rise eerli to me. Come ye, and turne we ayen to the Lord;
“Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a padà sọ́dọ̀ Olúwa ó ti fà wá ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ ṣùgbọ́n yóò mú wa láradá Ó ti pa wá lára ṣùgbọ́n yóò dí ojú ọgbẹ́ wa.
2 for he took, and schal heele vs; he schal smyte, and schal make vs hool.
Lẹ́yìn ọjọ́ méjì, yóò sọ wá jí ní ọjọ́ kẹta yóò mú wa padà bọ̀ sípò kí a ba à le wá gbé níwájú rẹ̀.
3 He schal quykene vs after twei daies, and in the thridde dai he schal reise vs, and we schulen lyue in his siyt. We schulen wite, and sue, that we knowe the Lord. His goyng out is maad redi at the morewtid, and he schal come as a reyn to vs, which is timeful and lateful to the erthe.
Ẹ jẹ́ kí a mọ Olúwa; ẹ jẹ́ kí a tẹ̀síwájú láti mọ̀ ọ́n. Gẹ́gẹ́ bí oòrùn ṣe ń yọ, yóò jáde; yóò tọ̀ wá wá bí òjò, bí òjò àkọ́rọ̀ ti ń bomirin ilẹ̀.”
4 Effraym, what schal Y do to thee? Juda, what schal Y do to thee? Youre merci is as a cloude of the morewtid, and as deew passynge forth eerli.
“Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Efraimu? Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Juda? Ìfẹ́ rẹ dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀ bí ìrì ìdájí tí ó kọjá lọ kíákíá.
5 For this thing Y hewide in profetis, Y killide hem in the wordis of my mouth;
Nítorí náà ni mo ṣe gé e yín sí wẹ́wẹ́ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, Mo pa yín pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ẹnu mi, ìdájọ́ mi tàn bí i mọ̀nàmọ́ná lórí yín.
6 and thi domes schulen go out as liyt. For Y wolde merci, and not sacrifice, and Y wolde the kunnyng of God, more than brent sacrificis.
Nítorí àánú ni mo fẹ́, kì í ṣe ẹbọ; àti ìmọ̀ Ọlọ́run ju ọrẹ ẹbọ sísun lọ.
7 But thei as Adam braken the couenaunt; there thei trespassiden ayens me.
Bí i Adamu, wọ́n da májẹ̀mú wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi níbẹ̀.
8 Galaad the citee of hem that worchen idol, is supplauntid with blood; and
Gileadi jẹ́ ìlú àwọn ènìyàn búburú tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, a sí ti fi ẹ̀ṣẹ̀ bà á jẹ́.
9 as the chekis of men `that ben theues. Partener of prestis sleynge in the weie men goynge fro Sichem, for thei wrouyten greet trespasse.
Bí adigunjalè ṣe ń ba ní bùba de àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà, ń parapọ̀; tí wọ́n sì ń pànìyàn lójú ọ̀nà tó lọ sí Ṣekemu, tí wọ́n sì ń dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ni lójú.
10 In the hous of Israel Y siy an orible thing; there the fornicaciouns of Effraym.
Mo ti rí ohun tó ba ni lẹ́rù ní ilé Israẹli. Níbẹ̀ Efraimu, fi ara rẹ̀ fún àgbèrè Israẹli sì di aláìmọ́.
11 Israel is defoulid; but also thou, Juda, sette heruest to thee, whanne Y schal turne the caitiftee of my puple.
“Àti fún ìwọ, Juda, a ti yan ọjọ́ ìkórè rẹ. “Nígbà tí mo bá fẹ́ dá ohun ìní àwọn ènìyàn mi padà,

< Hosea 6 >