< Hosea 3 >

1 And the Lord seide to me, Yit go thou, and loue a womman loued of a frend, and a womman auoutresse, as the Lord loueth the sones of Israel; and thei biholden to alien goddis, and louen the draffis of grapis.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Tun lọ fẹ́ obìnrin kan tí í ṣe olùfẹ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, àti panṣágà, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Olúwa sì àwọn ọmọ Israẹli tí ń wo àwọn ọlọ́run mìíràn, tí wọ́n sì ń fẹ́ àkàrà èso àjàrà.”
2 And Y dalf it to me bi fiftene pens, and bi a corus of barli, and bi half a corus of barli.
Nítorí náà, mo sì rà á padà ní ṣékélì fàdákà mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti homeri kan àti lẹ́tékì barle kan.
3 And Y seide to it, Bi many daies thou shalt abide me; thou schalt not do fornycacioun, and thou schalt not be with an hosebonde, but also Y schal abide thee.
Mo sì sọ fún un pé, “Ìwọ gbọdọ̀ máa gbé pẹ̀lú mi fún ọjọ́ pípẹ́, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe àgbèrè mọ́ tàbí kí o fẹ́ ọkùnrin mìíràn, èmi náà yóò sì gbé pẹ̀lú rẹ.”
4 For bi many daies the sones of Israel schulen sitte with out kyng, with out prince, and with out sacrifice, and with out auter, and with out prestis cloth, and with out terafyn, that is, ymagis.
Nítorí pé àwọn ọmọ Israẹli yóò wà fún ọjọ́ pípẹ́ láìní ọba tàbí olórí, láìsí ìrúbọ tàbí pẹpẹ mímọ́, láìsí àlùfáà tàbí òrìṣà kankan.
5 And after these thingis the sones of Israel schulen turne ayen, and schulen seke her Lord God, and Dauid, her king; and thei schulen drede at the Lord, and at the good of him, in the laste of daies.
Lẹ́yìn èyí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò padà láti wá Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi ọba wọn. Wọn yóò sì wá síwájú Olúwa pẹ̀lú ẹ̀rù, wọn ó sì jọ̀wọ́ ara wọn fún Olúwa àti ìbùkún rẹ̀ ní ọjọ́ ìkẹyìn.

< Hosea 3 >